< Isaiah 22 >

1 Kolrhawk ham olrhuh, na imphu tom ah na yoeng thil na taengkah olphong te melae?
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ àfonífojì ìran. Kí ni ó ń dààmú yín báyìí, tí gbogbo yín fi gun orí òrùlé lọ?
2 Pang ol loh khopuei ah a bae la khorha te hue a sak thil. Na rhok neh aka yalpo te cunghang kah a ngawn pawt tih caemtloek kah a duek sak moenih a?
Ìwọ ìlú tí ó kún fún rúkèrúdò, ìwọ ìlú àìtòrò òun rògbòdìyàn a kò fi idà pa àwọn òkú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kú ní ojú ogun.
3 Na rhalboei rhoek te lii om kolla rhenten boeih yong uh coeng. Nang aka hmu rhoek te boeih a khih uh coeng. Khohla kah aka yong rhoek te rhenten a khih uh coeng.
Gbogbo àwọn olórí i yín ti jùmọ̀ sálọ; a ti kó wọn nígbèkùn láìlo ọfà. Ẹ̀yin tí a mú ni a ti kó lẹ́rú papọ̀, lẹ́yìn tí ẹ ti sá nígbà tí ọ̀tá ṣì wà lọ́nà jíjìn réré.
4 Te dongah, “Kai taeng lamloh mangthong uh laeh. Rhah nen khaw ka phaep uh mai eh. Ka pilnam tanu kah rhoelrhanah dongah kai hloep hamla taholh uh thae boeh.
Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi: jẹ́ kí n sọkún kíkorò. Má ṣe gbìyànjú àti tù mí nínú nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.”
5 Ka Boeipa caempuei Yahovah taengkah soekloeknah, tilnoinah neh tingtongnah khohnin, kolrhawk kah olphong dongah tah pangbueng te a phuet tih tlang te a o.
Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan tí rúkèrúdò àti rògbòdìyàn àti ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ ní àfonífojì ìmọ̀, ọjọ́ tí a ń wó ògiri lulẹ̀ àti sísun ẹkún lọ sí àwọn orí òkè.
6 Elam loh liva neh marhang caem hlang leng hang khuen tih Kir loh photling a dul.
Elamu mú apó-ọfà lọ́wọ́, pẹ̀lú àwọn agun-kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹṣin, Kiri yọ àpáta rẹ̀ síta.
7 Na tuikol hmuennaep aka om khaw leng loh a baetawt thil marhang caem loh vongka ah tawn la tawn uh coeng.
Àyànfẹ́ àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́ ogun, àwọn ẹlẹ́ṣin ni a gbá jọ sí ẹnu-bodè ìlú.
8 Judah kah himbaiyan te a lim coeng. Tekah khohnin ah duup im kah lungpok haica te na paelki coeng.
Gbogbo ààbò Juda ni a ti ká kúrò. Ìwọ sì gbójú sókè ní ọjọ́ náà sí àwọn ohun ìjà ní ààfin ti inú aginjù.
9 David khopuei kah a ueth hma na hmuh te yet coeng dae tuibuem dang kah tui te na coi.
Ìwọ rí i pé ìlú u Dafidi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ààyè níbi ààbò rẹ̀, ìwọ ti tọ́jú omi sínú adágún ti ìsàlẹ̀.
10 Jerusalem kah im te khaw na tae uh tih vongtung na tuung ham im te na phil uh.
Ìwọ ka àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu ó sì wó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé lulẹ̀ láti fún ògiri lágbára.
11 Tuibuem rhuem kah tui ham te vongtung laklo ah tui-im na saii uh. Tedae te aka saii te na paelki uh pawh. Te aka hlinsai daengrhae te na hmu uh pawh.
Ìwọ mọ agbemi sí àárín ògiri méjì fún omi inú adágún àtijọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò wo ẹni tí ó ṣe é tẹ́lẹ̀ tàbí kí o kọbi ara sí ẹni tí ó gbèrò rẹ̀ ní ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.
12 Rhah ham neh rhaengsae ham khaw, lungawng la tlamhni yil ham khaw tekah khohnin ah ka Boeipa caempuei Yahovah a khue coeng.
Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun, pè ọ́ ní ọjọ́ náà láti sọkún kí o sì pohùnréré, kí o tu irun rẹ dànù kí o sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora.
13 Saelhung top ham neh boiva ngawn ham, maeh caak ham neh misurtui ok ham tah omngaihnah neh kohoenah la, “Ca sih lamtah o sih, thangvuen kah ham tah n'duek uh hae pawn ni he,” na tiuh.
Ṣùgbọ́n wò ó, ayọ̀ àti ayẹyẹ wà; màlúù pípa àti àgùntàn pípa, ẹran jíjẹ àti ọtí wáìnì mímu! Ẹ̀yin wí pé, “Jẹ́ kí a jẹ kí a mu, nítorí pé lọ́la àwa ó kú!”
14 caempuei BOEIPA loh ka hna dongah han dueh coeng. Nangmih kah thaesainah he na duek uh duela han dawth mahpawh. Ka Boeipa caempuei Yahovah loh a thui coeng.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ èyí di mí mọ̀ létí ì mi: “Títí di ọjọ́ ikú yín a kò ní ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yìí,” ni Olúwa wí, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
15 Ka Boeipa caempuei Yahovah loh he ni a thui. Cet lamtah im kah hmaiben lah Shebna te paan laeh.
Èyí ni ohun tí Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Lọ, sọ fún ìríjú yìí pé, fún Ṣebna, ẹni tí ààfin wà ní ìkáwọ́ rẹ̀.
16 Nang taengkah he balae? Na taengkah he u bang nim? Namah ham tah he ah he phuel na vueh tih, anih kah phuel tah hmuensang ah na vueh pah aih. Anih ham tah pohmuen khaw thaelpang dongah na tarhit pah.
Kí ni ohun tí ò ń ṣe níhìn-ín yìí àti pé ta ni ó sì fún ọ ní àṣẹ láti gbẹ́ ibojì kan fún ara rẹ níhìn-ín yìí, tí ó gbẹ́ ibojì ní ibi gíga tí ó sì gbẹ́ ibi ìsinmi rẹ nínú àpáta?
17 BOEIPA tah nang aka hut tih hlang aka hlak neh nang aka buem la aka buem ham om coeng.
“Kíyèsára, Olúwa fẹ́ gbá ọ mú gírígírí kí ó sì jù ọ́ nù, ìwọ ọkùnrin alágbára.
18 Nang te palung hluem bangla n'kolong la, n'kolong ni. Khohmuen kah khocaeh dangka ah hnap na duek vetih na thangpomnah leng neh na boeipa kah im te yahpohnah om ni.
Òun yóò ká ọ rúgúdù bí i òkìtì yóò sì sọ ọ́ sí orílẹ̀-èdè ńlá kan. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí àti níbẹ̀ pẹ̀lú ni àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àràmọ̀ǹdà rẹ yóò wà— ìwọ di ìtìjú sí ilé ọ̀gá rẹ!
19 Nang te na rhaltawt hmuen lamloh kan thaek vetih na ngolhmuen lamloh nang kan koengloeng ni.
Èmi yóò yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ, a ó sì lé ọ kúrò ní ipò rẹ.
20 Tekah khohnin a pha vaengah Hilkiah capa Eliakim te ka sal la ka khue ni.
“Ní ọjọ́ náà. Èmi yóò ké sí ọmọ ọ̀dọ̀ mi, Eliakimu ọmọ Hilkiah.
21 Na angkidung te anih ka bai sak vetih na lamko neh anih ka talong ni. Na khohung te anih kut dongah ka paek vetih Jerusalem kah khosa ham neh Judah imkhui kah a napa la om ni.
Èmi yóò fi aṣọ rẹ wọ̀ ọ́, n ó sì so ẹ̀wọ̀n rẹ mọ́ ọn ní ọrùn, èmi ó sì gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́. Òun yó sì jẹ́ baba fún gbogbo olùgbé e Jerusalẹmu àti fún ilé e Juda.
22 David im kah cabi te anih kah laengpang dongah ka paek ni. A ong vetih kalh voel mahpawh, a khaih coeng te tah ong uh mahpawh.
Èmi yóò sì fi kọ́kọ́rọ́ ilé e Dafidi lé e ní èjìká; ohunkóhun tí ó bá ṣí, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ti, ohunkóhun tí ó bá sì tì, ẹnikẹ́ni kì yóò le è ṣí.
23 Anih te hmuen cak ah ciphuem neh ka khing vetih a napa im ham thangpomnah ngolkhoel la om ni.
Èmi yóò sì kàn mọ́lẹ̀ bí èèkàn tí ó dúró gírígírí ní ààyè e rẹ̀; òun yóò sì jẹ́ ibùjókòó ọlá fún ilé baba rẹ̀.
24 A napa im kah thangpomnah boeih, cadil cahma neh a rhuirhong, hnopai a dikhnawn boeih, baeldung neh umam, tuitang neh baelyak boeih te anih a oi sak ni.
Gbogbo ògo ìdílé rẹ̀ ni wọn yóò sì fi kọ ní ọrùn: ìran rẹ̀ àti àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀, gbogbo ohun èlò ife, títí dé orí ago ọtí.
25 Te khohnin ah caempuei BOEIPA kah olphong loh, amah hmuen ah khak a khing hlingcong tah phoek pawn ni. Tlawt bal vetih colh pawn ni. Te vaengah a pum dongkah hnorhih a hal ni. BOEIPA loh a thui ngawn coeng.
“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gírígírí ní ààyè e rẹ̀ yóò yẹrí, yóò dẹ̀gbẹ́ yóò sì fẹ̀gbẹ́ lélẹ̀ àti ẹrù tí ó létéńté lórí i rẹ̀ ni a ó gé lulẹ̀.” Olúwa ni ó ti sọ ọ́.

< Isaiah 22 >