< Ezekiel 4 >

1 Nang hlang capa namah loh laiboeng lo lamtah namah mikhmuh ah tloeng laeh. A soah Jerusalem khopuei te tarhit laeh.
“Nísinsin yìí, ìwọ ọmọ ènìyàn, mú amọ̀ ṣíṣù kan, gbé e sí iwájú rẹ, kí o sì ya àwòrán ìlú Jerusalẹmu sí orí rẹ̀.
2 A taengah vong khueh pah lamtah a taengah buep khueh pah. A taengah tanglung khueng lamtah a taengah rhaehhmuen khueh. A kaepvai te maehdoelh khueh pah.
Kí o sì dó tì í, kí o sì mọ ilé ìṣọ́ tì í, kí o sì mọ odi tì í, kí o sì gbé ogun sí i, kí o sì to òòlù yí i ká.
3 Te phoeiah namah loh thi thiphael te namah ham lo lamtah namah laklo neh khopuei laklo ah thi pangbueng la khueh. Te vaengah na maelhmai te a taengla hoi pah. Vongup ah a om bangla la khopuei te na dum bitni. He miknoek he Israel imkhui ham ni.
Kí o sì fi àwo irin kan ṣe ògiri láàrín rẹ̀ àti ìlú yìí, kí o sì kọjú sí i, a ó sì dó tì í, ìwọ yóò sì dó tì í. Èyí yóò jẹ́ àmì fún ilé Israẹli.
4 Te phoeiah nang te banvoei kah na vae neh yalh lamtah Israel imkhui kathaesainah te a soah tloeng pah. A soah na yalh khohnin tarhing ah amih kathaesainah te na phueih ni.
“Lẹ́yìn èyí, lọ fi ẹ̀gbẹ́ òsì dùbúlẹ̀, kí o sì gbé ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli lé orí ara rẹ. Iye ọjọ́ tí ìwọ bá fi sùn náà ni ìwọ yóò fi ru ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
5 Amih kathaesainah kum tarhing bangla nang te kan tueih tih khohnin ya thum neh hnin sawmko ah Israel imkhui kathaesainah te na phueih van ni.
Nítorí mo fi iye ọdún tí wọ́n fi ṣẹ̀ fún ọ gẹ́gẹ́ bí iye ọjọ́ tí ìwọ yóò lò. Nítorí náà, ìwọ yóò ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
6 Te rhoek te na coeng van neh na vae bantang dongah yalh lamtah Judah imkhui kathaesainah te khohnin la hnin sawmli phueih pah. A kum la kum ham te hnin at ni nang kan tueih.
“Tí o bá parí èyí, tún fi ẹ̀gbẹ́ ọ̀tún dùbúlẹ̀ kí o sì ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Juda fún ogójì ọjọ́, nítorí pé ọjọ́ kan ló dúró fún ọdún kan.
7 Te phoeiah Jerusalem vong la na maelhmai hooi lamtah na ban te khawn lamtah, a taengah tonghma pah.
Ìwọ dojúkọ ìgbógunti Jerusalẹmu, na ọwọ́ rẹ sí i, kí o sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìlú náà.
8 Te vaengah nang dongah rhuivaeh kang khih ni ne. Te dongah na vongup kah khohnin na poeng hill na vae khat ben lamloh na vae khat ben duela na hoi uh thai mahpawh.
Èmi yóò dè ọ́ ní okùn dé bi pé ìwọ kò ní í le yírapadà láti ìhà ọ̀tún sí ìhà òsì títí tí ọjọ́ ìgbóguntì rẹ yóò fi pé.
9 Te phoeiah namah loh namah ham cang neh cangtun, maidawn neh rhacik, malket neh cangkuem khaw lo ne. Te te amrhaeng pakhat dongah pae uh lamtah na vae neh na yalh khohnin tarhing ah na buh la te te khueh. Khohnin ya thum sawmko khuiah te te ca.
“Mú alikama, ọkà bàbà àti barle, erèé àti lẹntili, jéró àti ẹwẹ; fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe àkàrà tí ìwọ yóò máa jẹ nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀ fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
10 Na caak te khaw a khiing la shekel pakul mah ca. A khohnin ham te a tue, a tue vaengah ca.
Wọn òsùwọ̀n ogún ṣékélì oúnjẹ tí ìwọ yóò máa jẹ lójoojúmọ́ kí o sì máa jẹ ẹ́ ní àkókò tí a ti yà sọ́tọ̀.
11 Tui khaw khoe dongah bunang parhuk o lamtah a tue a tue vaengah o.
Bákan náà, wọn ìdámẹ́fà omi, kí ìwọ ó sì máa mú ní àkókò tí a yà sọ́tọ̀.
12 Cangtun buh te na caak vaengah hlang kah natcaeh aek neh amih mikhmuh ah hai.
Ìwọ yóò sì jẹ ẹ́ bí àkàrà barle; dín in ní ojú àwọn ènìyàn, ìgbẹ́ ènìyàn ni kí o fi dáná rẹ.”
13 Te dongah BOEIPA loh, “Israel ca he tlam ni a buh rhalawt te a caak uh eh. Amih tenamtom taengah pahoi ka heh ni,” a ti.
Olúwa sọ pé, “Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò jẹ oúnjẹ àìmọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí èmi yóò lé wọn lọ.”
14 Tedae, “Ka Boeipa Yahovah aw, ka hinglu he maehrhok saha neh a poeih vai moenih ne. Ka camoe lamloh tahae hil ka ca vai pawt tih maeh khaw ka ka ah dikyik dikyak ka a kun moenih,” ka ti nah.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Kò rí bẹ́ẹ̀ Olúwa Olódùmarè! Láti ìgbà èwe mi di ìsinsin yìí èmi kò tí ì sọ ara mi di aláìmọ́ rí. Èmi kò tí ì jẹ ohun tó kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí tí ẹranko búburú fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Bẹ́ẹ̀ ni ẹran àìmọ́ kan kò tí ì wọ ẹnu mi rí.”
15 Te vaengah kai te “Ana so, hlang aek yueng la vaito aek ni nang taengah aek la kam paek vetih na buh te a soah tawn,” a ti.
Nígbà náà ló wí fún mi pé, “Wò ó, Èmi ó fún ọ ní ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn. Èmi yóò mú ki ó dín àkàrà rẹ lórí ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn.”
16 Te phoeiah kai te, “Hlang capa aw, Jerusalem kah thahuelnah buh te ka bawt pah coeng. Te dongah buh te amah tarhing ah mawnnah neh a caak uh vetih tui te khoe dongah a maehmanah neh a ok uh ni.
Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èmi yóò dáwọ́ ìpèsè oúnjẹ dúró ní Jerusalẹmu. Ní pípín ni àwọn ènìyàn yóò máa pín oúnjẹ jẹ pẹ̀lú ìfọkànsọ́nà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wọn yóò máa mu omi pẹ̀lú ìdààmú,
17 Buh neh tui a vaitah vetih hlang neh a manuca pong ni. Te vaengah amamih kathaesainah dongah muei uh ni.
nítorí pé oúnjẹ àti omi yóò wọ́n. Wọn yóò máa wo ara wọn pẹ̀lú ìyanu, èmi yóò sì jẹ́ kí wọ́n ṣọ̀fọ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

< Ezekiel 4 >