< Ezekiel 11 >

1 Mueihla loh kai m'phoh tih khothoeng la aka mang yan BOEIPA im vongka la kai ng'khuen. Te vaengah hlang pakul panga tevongka thohka ah lawt ana om. Amih lakli ah pilnam kah mangpa Azzur capa Jaazaniah neh Benaiah capa Pelatiah ka hmuh.
Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
2 Te phoeiah kai taengah, “Hlang capa, hlang rhoek long he boethae a moeh uh tih he khopuei ah a thae cilsuep ni a uen uh.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
3 Im sak ham yoei hlan, mamih tah he am dongkah maeh ni, ' a ti uh.
Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
4 Te dongah amih taengah tonghma pah, hlang capa aw tonghma pah,” a ti.
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
5 BOEIPA kah mueihla te kai soah ha cu tih kai te m'voek. “BOEIPA loh a thui he Israel imkhui ah thui pah. Tedae na mueihla kah tangtlaeng khaw ka ming.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
6 Nangmih rhok te he khopuei ah hmoeng tih a tollong khaw rhok neh bae,” a ti.
Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
7 Te dongah ka Boeipa Yahovah loh he ni a thui. Na rhok te a khui ah maeh la na khueh coeng tih khopuei he am la poeh coeng. Tedae nanmih te a khui lamloh n'hoep ni.
“Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
8 cunghang na rhih uh dongah nangmih taengla cunghang kang khuen ni. He tah ka Boeipa Yahovah kah olphong ni.
Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Nangmih te a khui lamloh kang khuen vetih kholong kut ah kan tloeng ni. Te vaengah tholhphu te nangmih soah ka saii ni.
Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
10 Israel khorhi ah cunghang neh na cungku uh tih nangmih soah lai ka tloek vaengah BOEIPA kamah te nan ming uh bitni.
Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
11 He he nangmih ham tah am la om pawt vetih nangmih te a khui ah maeh la na om uh mahpawh. Nangmih te Israel khorhi ah lai kan tloek ni.
Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
12 Te vaengah BOEIPA kamah te nan ming uh bitni. Ka oltlueh dongah na pongpa uh pawt tih ka laitloeknah na rhoi uh moenih. Tedae na kaepvai namtom kah laitloeknah bangla na saii uh.
Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
13 Ka tonghma li vaengah Benaiah capa Pelatiah te duek. Te dongah ka maelhmai neh ka bakop tih ol ue la ka pang. Te vaengah, 'Ka Boeipa Yahovah aw, na khawknah hil ah Israel kah a meet te na saii aih,’ ka ti.
Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
14 BOEIPA ol te kai taengla ha pawk.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
15 Te vaengah, “Hlang capa aw, na manuca khuikah na manuca, na hlang tlannah neh Israel imkhui pum loh a pum la amih Jerusalem khosa rhoek te, 'BOEIPA taeng lamloh a lakhla uh dongah ni khohmuen he kaimih taengah khoh la m'paek,’ a ti nauh.
“Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
16 Te dongah ka Boeipa Yahovah loh athui he thui. Amih te namtom taengah ka lakhla sak tih diklai ah amih ka taek ka yak sitoe cakhaw a pha uh khohmuen ah amih ham rhokso la rhaih ka om pahoi coeng.
“Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
17 Te dongah ka Boeipa Yahovah loh a thui he thui pah. Nangmih te pilnam taeng lamloh kan coi vetih nangmih te diklai lamloh kan coi ni. Amih taengah kan taek kan yak cakhaw Israel khohmuen he nangmih taengah ni kam paek eh.
“Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
18 Te la ha pawk uh vaengah a sarhingkoi cungkuem neh a tueilaehkoi cungkuem te anih lamloh a khoe uh ni.
“Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
19 Amih te lungbuei pakhat la ka khueh pah vetih nangmih kotak ah mueihla thai kam paek. Te vaengah amih saa lamkah lungto lungbuei ka kuel pah vetih amih te ngansen lungbuei te ka paek ni.
Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
20 Te daengah ni ka khosing dongah pongpa uh vetih ka laitloeknah te a tuem uh eh. Te te a saii uh daengah ni kai taengah pilnam la om uh vetih kai khaw amih taengah Pathen la ka om eh.
Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
21 Tedae amih kah sarhingkoi lungbuei neh a lungbuei kah a tueilaehkoi longpuei ah a pongpa uh te amih lu ah ka tloeng pah ni. He tah ka Boeipa Yahovah kah olphong ni,” a ti.
Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
22 Te vaengah cherubim rhoek loh a phae te a voeivang kah lengkho neh a phuel tih Israel Pathen kah thangpomnah tah amih sokah a so duela om.
Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
23 BOEIPA kah thangpomnah khaw khopuei khui lamloh cet tih khopuei khothoeng kah tlang ah duem.
Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
24 Mueihla loh kai ng'khuen tih Pathen mueihla kah mueimae neh Khalden ah vangsawn la kai n'thak. Te phoeiah a mueimae ka hmuh te kai taeng lamloh cet.
Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
25 vangsawn taengah ka thui ol boeih he BOEIPA loh kai n'tueng coeng.
mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.

< Ezekiel 11 >