< 1 Manghai 21 >
1 He hno he a om phoeiah, Jezreel kah Samaria manghai Ahab bawkim taengah Jezreel Naboth kah misurdum om.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
2 Te dongah Ahab loh Naboth te, “Na misurdum te kai taengah m'pae lamtah, ka im neh a yoei ah kai ham toi-an dum la om saeh. Te yueng la nang taengah te lakah aka then misurdum khaw na mik ah aka then kam paek bitni. A phu la nang te tangka khaw kam paek bitni,” a ti nah.
Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
3 Naboth loh Ahab te, “A pa rhoek kah rho nang taengla kam paek ham he, kamah lamkah neh BOEIPA lamlong khaw savisava,” a ti nah.
Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
4 Jezreel Naboth loh anih te a voek tih, “A pa rhoek kah rho he nang taengla kam pae mahpawh,” a ti nah ol dongah Ahab khaw a im te rhihnun cukduk neh thintoek la a pha. A baiphaih dongah a yalh neh a maelhmai a bueng tih buh khaw ca pawh.
Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
5 A yuu Jezebel te a taengla a pawk pah vaengah tah anih te, “Na mueihla he metlam a rhihnun cukduk tih buh na caak pawh,” a ti nah.
Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
6 Jezebel te, “Jezreel Naboth te ka voek tih amah taengah, 'Na misurdum te kai taengah tangka la han yoi mai. Na huem mak atah a yueng misurdum khaw nang te kam paek bitni,’ ka ti nah. Tedae, 'Ka misurdum te nang taengah kam pae mahpawh,’ a ti,” a ti nah.
Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
7 Te dongah anih te a yuu Jezebel loh, “Nang he Israel soah mangpa khaw na bi coeng ta. Thoo, buh ca lamtah na lungbuei voelphoeng sak. Kai loh Jezreel Naboth kah misurdum te nang ham kang khueh bitni,” a ti nah.
Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
8 Te phoeiah Ahab ming neh cabu a daek tih a kutbuen neh a daeng thil. Cabu dongkah ca te a ham rhoek taengah neh a khopuei kah Naboth taengah kho aka sa hlangcoelh taengla a pat.
Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
9 Cabu khuikah a daek dongah, “Yaehnah te khue uh lamtah Naboth te pilnam kah a lu la ngol saeh.
Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
10 Anih hmai ah aka muen ca rhoi hlang panit ngol saeh. Te vaengah anih te hih saeh lamtah, 'Pathen neh manghai yoethen pae nawn,'ti nah saeh lamtah khuen saeh. Te phoeiah anih te dae lamtah duek saeh,” a ti nah.
Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
11 A khopuei hlang a hamca rhoek neh a khopuei khuikah khosa hlangcoelh rhoek long khaw Jezebel loh amih ham cabu neh a daek tih amih taegla a pat dongkah a uen bangla a saii uh.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
12 Yaehnah te a hoe uh tih Naboth te pilnam kah a lu la a ngol sakuh.
Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
13 Te vaengah hlang muen ca rhoi te ha pawk tih anih hmai ah ngol rhoi van. Hlang muen rhoi loh Naboth te pilnam hmai ah a laipai thil rhoi tih, “Naboth loh Pathen neh manghai yoethen a paek oe,” a ti rhoi. Te phoeiah tah khopuei vongvoel la a khuen uh tih lungto neh a dae uh dongah Naboth te duek.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
14 Te phoeiah Jezebel taengla a tueih uh tih, “Naboth a dae uh tih duek coeng,” a ti nah.
Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
15 Naboth a dae uh tih a duek te Jezebel loh a yaak van neh Jezebel long khaw Ahab taengah, “Thoo, Jezreel Naboth kah misurdum te pang laeh. Nang taengah tangka la paek ham khaw a aal dongah Naboth hing pawt tih duek coeng,” a ti nah.
Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
16 Naboth a duek te Ahab loh a yaak neh Ahab mah khaw thoo tih Jezreel Naboth kah misurdum te pang ham suntla.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
17 Te vaengah BOEIPA ol te Tishbi Elijah taengla pawk tih,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
18 “Thoo, Samaria kah Israel manghai Ahab doe la suntla laeh. Naboth kah misurdum pang hamla suntla lako ke.
“Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
19 Anih te thui pah lamtah, 'BOEIPA loh he ni a thui. Na ngawn tih na pang bal nama?' ti nah. Te phoeiah anih te thui pah lamtah, 'BOEIPA loh he ni a thui. Naboth thii ui loh a laeh nah hmuen ah nang khaw na thii te ui loh a laeh van ni,'ti nah,” a ti nah.
Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
20 Ahab loh Elijah te, “Kai he 'Ka thunkha ' la nan hmuh nama?” a ti nah. Te dongah, “BOEIPA mik ah boethae saii ham namah na yoih uh dongah kam hmuh mah ta.
Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
21 Kai loh nang soah boethae kang khuen rhoe kang khuen coeng he. Namah hnukah kan dom sak vetih pangbueng aka yun thil khaw, Israel khuikah a khoh neh a hnoo khaw Ahab taeng lamloh ka saii ni.
‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
22 Israel te konoinah ham na veet tih na tholh sak dongah nang imkhui te Nebat capa Jeroboam imkhui bangla, Ahijah capa Baasha imkhui bangla kang khueh ni.
Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
23 BOEIPA loh Jezebel kawng khaw a thui tih, “Jezebel te Jezreel rhalmahvong ah ui loh a sok ni, ' a ti.
“Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
24 Ahab lamkah he khopuei ah aka duek te ui loh a caak vetih kohong ah aka duek te vaan kah vaa loh a caak ni.
“Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
25 BOEIPA mik ah boethae saii ham amah aka yoi uh Ahab bang he a om moenih. Anih he a yuu Jezebel loh a vueh bal.
(Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
26 BOEIPA loh Israel ca rhoek mikhmuh lamkah a haek Amori loh a cungkuem la a saii mueirhol hnukah a pongpa te bahoeng a tuei,” a ti nah.
Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
27 Ahab loh he ol he a yaak van neh a himbai te a phen tih a pumsa dongah tlamhni a bai, a yaeh neh tlamhni dongah yalh tih yuepyuep cet.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
28 Te vaengah Tishbi Elijah taengah BOEIPA ol ha pawk tih,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
29 “Ka mikhmuh ah Ahab a kunyun ke na hmuh nama? Ka mikhmuh ah a kunyun bangla amah tue ah yoethae ka khuen rhoe ka khuen pah mahpawh. A capa tue vaengah tah a imkhui ah yoethae ka khuen pah ni,” a ti nah.
“Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”