< Lampahnah 6 >
1 BOEIPA loh Moses te a voek tih,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 “Israel ca rhoek te voek lamtah amih te tongpa khaw huta khaw thui pah. Hlangcoelh kah olcaeng dongah caeng ham neh BOEIPA taengah cue uh ham a rhaisang atah,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ pàtàkì, ẹ̀jẹ́ ìyara-ẹni-sọ́tọ̀ sí Olúwa nípa àìgé irun orí (Nasiri),
3 Misurtui neh yu dong lamloh cue uh saeh lamtah misurtui a thuui neh yu a thuui khaw o boel saeh, misur thaihtui boeih tah o boel saeh lamtah misur he a thingsup khaw, a rhae khaw ca boel saeh.
irú ẹni bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ yàgò fún wáìnì tàbí ọtí líle, ọtí wáìnì kíkan àti àwọn ohun mímu mìíràn tó bá kan. Kò gbọdọ̀ mu èso àjàrà tàbí kí ó jẹ èso àjàrà tútù tàbí gbígbẹ.
4 A rhuisam kah a tue khuiah tah misur misurtui neh a muu lamloh a saii boeih khaw, a kok pataeng khaw ca boel saeh.
Níwọ́n ìgbà tí ó sì jẹ́ Nasiri, ní kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi èso àjàrà ṣe, ìbá à ṣe kóró tàbí èèpo rẹ̀.
5 A rhuisam dongkah olcaeng tue khuiah tah paihat loh anih lu te paan boel saeh. BOEIPA taengah a cue uh khohnin a cup hil a cim la om saeh lamtah a lu dongkah sammuei sam sai saeh.
“‘Ní gbogbo ìgbà ẹ̀jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, kí abẹ kankan má ṣe kàn án ní orí. Ó gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ títí tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa yóò fi pé; ó gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí rẹ̀ gùn.
6 BOEIPA ham a cue uh tue khuiah aka duek hinglu taengla mop boel saeh.
“‘Ní gbogbo àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa kò gbọdọ̀ súnmọ́ òkú ènìyàn.
7 A napa ham neh a manu ham khaw, a pacaboeina ham neh a tanu ham khaw, amih dongah poeih uh boel saeh. Amih te a duek atah a Pathen kah rhuisam kongah anih lu dongah tla saeh.
Ìbá à ṣe òkú baba, àti ìyá rẹ̀, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin tàbí àbúrò rẹ̀, kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí wọn, nítorí pé àmì ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run wà ní orí rẹ̀.
8 A rhuisam kah khohnin khuiah tah anih te BOEIPA taengah cim saeh.
Ní gbogbo àsìkò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
9 Aka duek khaw anih taengah bangrhuet la pahoi a duek atah a rhuisam lu a poeih coeng. Te dongah a lu te vo saeh lamtah a ciimnah khohnin dongkah a rhih hnin ah vo saeh.
“‘Bí ẹnìkan bá kú ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òjijì, tí ó sì ba irun rẹ̀ tó yà sọ́tọ̀ jẹ́; ó gbọdọ̀ gé irun rẹ̀ ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe ọjọ́ keje.
10 A rhet nah hnin ah vahu phiknit mai khaw, vahui ca phiknit mai khaw tingtunnah dap thohka kah khosoih taengla la khuen saeh.
Ní ọjọ́ kẹjọ, yóò mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé méjì wá sọ́dọ̀ àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
11 Khosoih loh phikat te boirhaem la, phikat te hmueihhlutnah la nawn saeh. A hinglu kah tholh kongah anih ham dawth pah saeh lamtah amah khhnin ah a lu te ciim pah saeh.
Àlùfáà yóò fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun láti fi ṣe ètùtù fún un nítorí pé ó ti ṣẹ̀ nípa wíwà níbi tí òkú ènìyàn wà. Yóò sì ya orí rẹ̀ sí mímọ́ ní ọjọ́ náà gan an.
12 A rhuisam kah khohnin ah BOEIPA taengah cue uh saeh lamtah hmaithennah la tu kum khat ca te khuen saeh. Tedae lamhma khohnin kah bangla a rhuisam poeih ham cungku uh ve.
Ó gbọdọ̀ ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ sí Olúwa fún àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀, ó sì gbọdọ̀ mú akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀bi. Kò sì ní í ka àwọn ọjọ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀ nítorí pé ó tí ba ara rẹ̀ jẹ́ ní àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀.
13 He he hlangcoelh kah olkhueng coeng ni. A rhuisam khohnin a cup khohnin ah anih te tingtunnah dap thohka la khuen saeh.
“‘Èyí ni òfin fún Nasiri nígbà tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ bá pé. Wọn ó mu wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
14 Te vaengah BOEIPA taengah a nawnnah tah kum khat tu a tal pakhat a hmabuet te hmueihhlutnah la, boirhaem la tumanu kum khat ca a hmabut pumat, rhoepnah ham tutal a hmabuet pakhat khuen saeh.
Níbẹ̀ ni yóò ti mú ọrẹ wá fún Olúwa, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí kò ní àbùkù fún ẹbọ sísun àti ẹgbọrọ-àgùntàn ọlọ́dún kan, tí kò ní àbùkù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àgbò kan tí kò ní àbùkù fún ọrẹ àlàáfíà,
15 Vaidamding kodawn pakhat te vaidam laep vaidam la situi neh nom saeh lamtah vaidamding vaidamrhawm khaw situi neh koelh saeh. Te phoeiah a khocang neh a tuisi la khuen saeh.
pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu, apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí a kò fi ìwúkàrà ṣe, àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun dáradára pò mọ́ òróró àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a fi òróró sọjọ̀ lé lórí.
16 Te phoeiah khosoih loh BOEIPA mikhmuh ah khuen saeh lamtah anih kah boirhaem neh a hmueihhlutnah te saii pah saeh.
“‘Àlùfáà yóò gbé gbogbo rẹ̀ wá síwájú Olúwa, yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun.
17 Tutal te BOEIPA taengah rhoepnah hmueih la vaidamding kodawn khat neh nawn saeh. Te phoeiah khosoih loh anih kah khocang neh a tuisi te saii pah saeh.
Àlùfáà yóò fi àgbò náà rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa, pẹ̀lú apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà; yóò rú ẹbọ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu.
18 Tingtunnah dap thohka kah Hlangcoelh loh a rhuisam lu te vo saeh. Te phoeiah a rhuisam lu dongkah sam te lo saeh lamtah rhoepnah hmueih dang kah hmai dongah phum saeh.
“‘Nígbà náà ni Nasiri náà yóò fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Yóò fi irun náà sínú iná tó wà lábẹ́ ẹbọ àlàáfíà.
19 Te phoeiah khosoih loh tutal kah a laeng a hmin neh kodawn dongkah vaidamding laep at, vaidamding dongkah vaidam rhawm pakhat te lo saeh. A rhuisam te a vok phoeiah tah hlangcoelh kut ah pae saeh.
“‘Lẹ́yìn tí Nasiri bá ti fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ tan, àlùfáà yóò mú apá àgbò bíbọ̀, àkàrà aláìwú kan àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí kò ní ìwúkàrà láti inú apẹ̀rẹ̀ yóò sì kó gbogbo rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Te rhoek te khosoih loh BOEIPA mikhmuh ah thueng hmueih la thueng saeh. Khosoih ham thueng hmueih kah a rhang neh khosaa kah a laeng te a cim phoeiah tah hlangcoelh loh misurtui khaw o mai saeh.
Àlùfáà yóò fi gbogbo rẹ̀ níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì, wọ́n jẹ́ mímọ́, wọ́n sì jẹ́ ti àlùfáà pẹ̀lú igẹ̀ tí a fì àti itan tí wọ́n mú wá. Lẹ́yìn èyí, Nasiri náà lè mu wáìnì.
21 He tah BOEIPA taengah amah nawnnah la aka caeng hlangcoelh kah olkhueng ni. A kut loh a pha voel lamloh amah kah rhuisam dongah a olcaeng ol bangla a caeng coeng. Te dongah amah kah rhuisam olkhueng bangla saii saeh,” a ti.
“‘Èyí ni òfin Nasiri tó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ rẹ̀ sí Olúwa, yóò wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Nasiri, ní àfikún sí àwọn ohun mìíràn tó lágbára láti mú wá. Ó gbọdọ̀ mú ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin Nasiri.’”
22 Te phoeiah BOEIPA loh Moses te a voek tih,
Olúwa sọ fún Mose pé,
23 “Aaron taeng neh anih koca rhoek taengah thui pah lamtah Israel ca rhoek te, 'Na yoethen uh tangloeng,’ ti nah.
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, ‘Báyìí ni kí ẹ ṣe máa súre fún àwọn ọmọ Israẹli. Ẹ sọ fún wọn pé,
24 “BOEIPA loh nang yoethen m'pae saeh lamtah nang n'dawndah saeh.
“‘“Kí Olúwa bùkún un yín, kí ó sì pa yín mọ́.
25 BOEIPA loh nang soah a maelhmai han sae sak saeh lamtah nang n'rhen saeh.
Kí Olúwa kí o mú ojú rẹ̀ kí ó mọ́lẹ̀ sí i yín lára. Kí ó sì ṣàánú fún un yín.
26 BOEIPA loh nang taengah a maelhmai han hoi saeh lamtah nang taengah ngaimongnah hang khueh saeh,’ ti nah.
Kí Olúwa bojú wò yín, kí ó sì fún un yín ní àlàáfíà.”’
27 Kai ming he Israel ca rhoek soah khueh uh pai saeh lamtah kai loh amih yoethen ka pae pai eh,” a ti nah.
“Báyìí ni wọn ó ṣe fi orúkọ mi sára àwọn ọmọ Israẹli, Èmi ó sì bùkún wọn.”