< Lampahnah 2 >

1 BOEIPA loh Moses neh Aaron te a voek tih,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 “Hlang he a napa imko kah miknoek neh a hnitai hmuiah rhaeh uh saeh. Israel ca rhoek te tingtunnah dap taengah a hla la pin rhaeh uh saeh.
“Kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn yí àgọ́ ìpàdé ká, kí wọ́n jẹ́ kí àgọ́ wọn jìnnà sí i díẹ̀, oníkálùkù lábẹ́ ọ̀págun pẹ̀lú àsíá ìdílé wọn.”
3 Khothoeng khocuk la Judah lambong kah hnitai te amah kah caempuei neh rhaeh saeh. Te vaengah Amminadab capa Nahshon te Judah koca rhoek kah khoboei saeh.
Ní ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ àtiyọ oòrùn: ni kí ìpín ti Juda pa ibùdó wọn sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Juda ni Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
4 A caempuei khaw thawng sawmrhih thawng li neh ya rhuk la a soep.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
5 A hmatoeng ah aka rhaeh Issakhar koca neh Issakhar ca rhoek kah khoboei tah Zuar capa Nethanel saeh.
Ẹ̀yà Isakari ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Isakari ni Netaneli ọmọ Suari.
6 A caempuei khaw thawng sawmnga thawng li neh ya li la soep saeh.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
7 Zebulun koca neh Zebulun ca rhoek kah khoboei tah Helon capa Eliab saeh.
Ẹ̀yà Sebuluni ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Sebuluni ni Eliabu ọmọ Heloni.
8 A caempuei khaw thawng sawmnga thawng rhih neh ya li la a soep uh.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
9 Judah rhaehhmuen kah boeih te thawng yakhat neh thawng sawmrhet neh thawng rhuk ya li la soep uh. Amih kah caempuei te a pacuek ah cet saeh.
Gbogbo àwọn tí a yàn sí ibùdó Juda, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàléláàdọ́rùn-ún ó lé irinwó. Àwọn ni yóò kọ́kọ́ ṣáájú.
10 Reuben rhaehhmuen kah hnitai tah tuithim ah amah caempuei neh om tih Shedeur capa Elizur te Reuben koca kah khoboei saeh.
Ní ìhà gúúsù: ni ìpín ti Reubeni pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Reubeni ni Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
11 A caempuei neh anih te thawng sawmli thawng rhuk neh ya nga la soep uh.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
12 A hmatoeng ah aka rhaeh Simeon koca neh Simeon ca rhoek kah khoboei tah Zurishaddai capa Shelumiel saeh.
Ẹ̀yà Simeoni ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Simoni ni Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
13 A caempuei neh amih te thawng sawmnga thawng ko neh ya thum la soep saeh.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbéje.
14 Gad koca neh Gad ca rhoek kah khoboei tah Reuel capa Eliasaph saeh.
Ẹ̀yà Gadi ló tẹ̀lé wọn. Olórí Gadi ni Eliasafu ọmọ Deueli.
15 A caempuei neh amih te thawng sawmli thawng nga neh ya rhuk sawmnga la soep saeh.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
16 Reuben rhaehhmuen kah boeih te thawng yakhat neh thawng sawmnga thawng khat neh ya li sawmnga la soep saeh. Amih kah caempuei te a pabae ah cet saeh.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Reubeni, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá márùndínlọ́gọ́rin ó lé àádọ́talélégbèje. Àwọn ni yóò jáde sìkéjì.
17 Te vaengah Levi rhaehhmuen kah tingtunnah dap lambong laklung ah cet saeh. A rhaeh uh vanbangla hlang he amah hnitai hmuikah amah kah hmuen ah cet tangloeng saeh.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi àti àgọ́ ìpàdé yóò tẹ̀síwájú láàrín ibùdó àwọn ènìyàn, wọn yóò tẹ̀síwájú ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe pa ibùdó, olúkúlùkù láààyè rẹ̀, àti lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀.
18 Ephraim caem kah hnitai a caempuei neh khotlak ah om saeh lamtah Ephraim ca rhoek kah khoboei tah Ammihud capa Elishama saeh.
Ní ìhà ìlà-oòrùn: ni ìpín Efraimu yóò pa ibùdó rẹ̀ sí lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀. Olórí Efraimu ni Eliṣama ọmọ Ammihudu.
19 A caempuei neh amih te thawng sawmli neh ya nga soep saeh.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì lé ó lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
20 A hmatoeng te Manasseh koca saeh lamtah Manasseh ca rhoek kah khoboei tah Pedahzur capa Gamaliel saeh.
Ẹ̀yà Manase ni yóò tẹ̀lé wọn. Olórí Manase ni Gamalieli ọmọ Pedasuri.
21 A caempuei neh amih te thawng sawmthum thawng hnih ya hnih la soep saeh.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé igba.
22 Benjamin koca neh Benjamin ca rhoek kah khoboei tah Gideoni capa Abidan saeh.
Ẹ̀yà Benjamini ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Benjamini ni Abidani ọmọ Gideoni.
23 A caempuei neh amih te thawng sawmthum thawng nga neh ya li la soep uh.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
24 Ephraim caem te thawng yakhat phoeiah thawng rhet neh ya khat la boeih soep saeh. Amih kah caempuei te a pathum ah cet saeh.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Efraimu, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnléláàádọ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún. Àwọn ni yóò jáde sìkẹ́ta.
25 Dan caem kah hnitai tah a caempuei neh tlangpuei ah om saeh lamtah Dan ca rhoek kah khoboei tah Ammishaddai capa Ahiezer saeh.
Ní ìhà àríwá: ni ìpín Dani yóò pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Dani ni Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
26 A caempuei neh amih te thawng sawmrhuk thawng hnih neh ya rhih la soep saeh.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
27 A hmatoeng kah aka rhaeh Asher koca neh Asher ca rhoek kah khoboei tah Okran capa Pagiel saeh.
Ẹ̀yà Aṣeri ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Aṣeri ni Pagieli ọmọ Okanri.
28 A caempuei neh amih te thawng sawmli thawng khat ya nga soep saeh.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
29 Naphtali koca neh Naphtali ca rhoek kah khoboei tah Enan capa Ahira saeh.
Ẹ̀yà Naftali ni yóò kàn lẹ́yìn wọn. Olórí Naftali ni Ahira ọmọ Enani.
30 A caempuei neh amih te thawng sawmnga thawng thum neh ya li soep saeh.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé egbèje.
31 Dan caem khuikah boeih he thawng yakhat neh thawng sawmnga thawng rhih ya rhuk la soep uh tih a hnukkhoem la a hnitai neh cet uh saeh.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Dani jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gọ̀rin ó lé ẹgbẹ̀jọ. Àwọn ni yóò jáde kẹ́yìn lábẹ́ ọ̀págun wọn.
32 Israel ca rhoek te a napa rhoek imkhui neh a soep tih a caempuei lamloh a caem te boeih a soep vaengah thawng ya rhuk neh thawng thum ya nga sawmnga lo,” a ti nah.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n kà nípa ìdílé wọn. Gbogbo àwọn tó wà ní ibùdó, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, wọ́n jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
33 Tedae Levi rhoek tah BOEIPA loh Moses a uen vanbangla Israel ca khui ah soep uh thil pawh.
Ṣùgbọ́n a kò ka àwọn ọmọ Lefi papọ̀ mọ́ àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
34 BOEIPA loh Moses a uen bangla a cungkuem te Israel ca rhoek loh a saii uh. A hnitai hmuiah rhaeh uh tih hlang he amah koca ah a napa imkhui neh cet uh.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose, báyìí ni wọ́n ṣe pa ibùdó lábẹ́ ọ̀págun wọn, bẹ́ẹ̀ náà sì ni wọ́n ṣe jáde, oníkálùkù pẹ̀lú ẹbí àti ìdílé rẹ̀.

< Lampahnah 2 >