< Jeremiah 23 >

1 Anunae ka rhamtlim kah boiva a dawn vaengah aka milh sak tih aka taekyak aih te, he tah BOEIPA kah olphong ni.
“Ègbé ni fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń tú agbo ẹran mi ká tí ó sì ń pa wọ́n run!” ni Olúwa wí.
2 Te dongah Israel Pathen BOEIPA loh he ni a. thui. Ka pilnam aka dawn tih aka luem puei nang loh ka boiva te na taekyak. Amih te na heh tih amih te na hip moenih. Na khoboe thaenah te namah soah kan cawh he khaw BOEIPA kah olphong coeng ni.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ ní ti àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń darí àwọn ènìyàn mi: “Nítorí tí ẹ̀yin tú agbo ẹran mi ká, tí ẹ lé wọn dànù tí ẹ̀yin kò sì bẹ̀ wọ́n wò. Èmi yóò jẹ yín ní yà nítorí nǹkan búburú tí ẹ ti ṣe,” ni Olúwa wí.
3 Te dongah diklai pum lamkah ka boiva kah a meet te ka coi ni. Amih te te la ka heh hnap mai cakhaw a tolkhoeng la ka mael puei ni. Te vaengah pungtai uh vetih ping uh ni.
“Èmi Olúwa tìkára mi yóò kó ìyókù agbo ẹran mi jọ láti inú gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti lé wọn, Èmi yóò mú wọn padà sínú pápá oko wọn, níbẹ̀ ni wọn ó ti bí sí i, tí wọn ó sì pọ̀ sí i.
4 Amih aka dawn te ka thoh thil vetih amih te luem uh ni. Te vaengah rhih uh voel pawt vetih, rhihyawp uh pawt vetih hal uh mahpawh. He tah BOEIPA kah olphong ni.
Èmi ó wá olùṣọ́-àgùntàn fún wọn, tí yóò darí wọn, wọn kì yóò bẹ̀rù tàbí dààmú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan kì yóò sọnù,” ni Olúwa wí.
5 BOEIPA kah olphong khohnin ha pawk coeng ke. Te vaengah thingdawn dueng te David ham ka thoh pah tih manghai la manghai pawn ni. Te dongah tiktamnah neh duengnah te diklai ah a saii vetih a cangbam ni.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi, ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.
6 Anih tue vaengah Judah te daem vetih Israel ngaikhuek la kho a sak ni. A ming te khaw BOEIPA tah mamih kah duengnah la a khue ni.
Ní ọjọ́ rẹ̀ ni a ó gba Juda là, Israẹli yóò sì máa gbé ní aláìléwu. Èyí ni orúkọ tí a ó fi máa pè é: Olúwa Òdodo wa.
7 Te dongah BOEIPA kah olphong hnin tah ha pawk coeng ke. Te vaengah Egypt kho lamloh Israel ca aka khuen hingnah BOEIPA te koep thui uh mahpawh.
Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí ènìyàn kì yóò tún wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.’
8 Tedae hingnah BOEIPA amah lat loh Israel imkhui kah tiingan te tlangpuei kho lamkah neh diklai pum lamloh hang khuen tih ham pawk puei. Te ah te amih heh mai cakhaw amamih khohmuen ah kho a sak uh ni.
Ṣùgbọ́n wọn yóò máa wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa ń bẹ tí ó mú irú-ọmọ ilé Israẹli wá láti ilẹ̀ àríwá àti láti àwọn ilẹ̀ ibi tí mo tí lé wọn lọ,’ wọn ó sì gbé inú ilẹ̀ wọn.”
9 Tonghma kawng dongah ka kotak khuikah ka lungbuei paeng coeng. Ka rhuh he boeih hinghlawk tih yurhui hlang bangla ka om. BOEIPA kah mikhmuh neh amah kah ol cim hmai ah misurtui loh a puem hlang bangla tui ka yuka.
Nípa ti àwọn wòlíì èké. Ọkàn mi ti bàjẹ́ nínú mi, gbogbo egungun mi ni ó wárìrì. Èmi dàbí ọ̀mùtí ènìyàn, bí ọkùnrin tí ọtí wáìnì ń pa; nítorí Olúwa àti àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
10 Diklai he samphaih neh hah coeng tih thaephoeinah hmai ah ni diklai he a nguekcoi uh. Khosoek toitlim ngawn koh uh coeng tih a yongnah khaw yoethae la a poeh pah dongah a thayung thamal om tangloeng pawh.
Ilẹ̀ náà kún fún panṣágà ènìyàn; nítorí ègún, ilẹ̀ náà gbẹ, àwọn koríko orí aṣálẹ̀ ilẹ̀ náà rọ. Àwọn wòlíì tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọ́n sì ń lo agbára wọn lọ́nà àìtọ́.
11 Tonghma neh khosoih khaw poeih uh coeng tih ka im khuiah pataeng amih kah boethae ka hmuh. He tah BOEIPA kah olphong ni.
“Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run; kódà nínú tẹmpili mi ni mo rí ìwà búburú wọn,” ni Olúwa wí.
12 Te dongah amih taengah a longpuei te longhnal la poeh ni. Khohmuep khuila bung uh vetih a khuiah cungku uh ni. Amih cawhnah kum kah boethae te amih soah ka thoeng sak ni. He tah BOEIPA kah olphong ni.
“Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́, a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn; níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú. Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn, ní ọdún tí a jẹ wọ́n ní ìyà,” ni Olúwa wí.
13 Samaria tonghma rhoek taengah khaw a hohap ni ka hmuh. Baal rhangneh tonghma uh tih ka pilnam Israel te khohmang la a khuehuh.
“Láàrín àwọn wòlíì Samaria, Èmi rí ohun tí ń lé ni sá. Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Baali wọ́n sì mú Israẹli ènìyàn mi ṣìnà.
14 Jerusalem tonghma rhoek taengah khaw a samphaih rhih om te ka hmuh. A honghi neh pongpa uh tih thaehuet ham kut a hluem uh. Hlang he a boethae lamloh a mael uh pawt dongah kai taengah tah amamih te Sodom bangla, a khuikah khosa rhoek khaw Gomorrah bangla boeih om uh coeng.
Àti láàrín àwọn wòlíì Jerusalẹmu, èmi ti rí ohun búburú. Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké. Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára, tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀. Gbogbo wọn dàbí Sodomu níwájú mi, àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gomorra.”
15 Te dongah caempuei BOEIPA loh he ni a. thui. Amih tonghma rhoek te pantong ni ka cah coeng he. Jerusalem tonghma taeng lamloh diklai pum ah a rhonging a coe dongah amih te anrhat tui ni ka tul eh.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí ní ti àwọn wòlíì: “Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò, wọn yóò mu omi májèlé nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerusalẹmu ni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”
16 Caempuei BOEIPA loh he ni a. thui. Nangmih taengah aka tonghma, tonghma rhoek ol te hnatun uh boeh. Amih te amamih lungbuei kah mangthui neh nangmih taengah hoemdawk uh tih BOEIPA kah ka lamloh aka thoeng te a thui uh moenih.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ má ṣe fi etí sí àsọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín. Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán. Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn, kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.
17 Kai yahbai ham aka thui la aka thui nangmih taengah BOEIPA ngaimongnah om saeh a ti lahko. Te dongah nim a lungbuei kah thinthahnah dongah aka pongpa boeih loh, 'Nangmih taengah yoethae ha pawk mahpawh,” a ti uh.
Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé, ‘Olúwa ti wí pé, ẹ̀yin ó ní àlàáfíà.’ Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé, ‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’
18 Tedae BOEIPA kah baecenol dongah pai tih aka hmu coeng neh a ol aka ya te unim? A ol te a ol bangla aka hnatung tih aka ya te unim?
Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúró nínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí i tàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?
19 BOEIPA kah kosi hlipuei ha thoeng pawn ni ke. Te vaengah hlipuei te kilkul vetih halang kah a lu te a kilkul thil ni.
Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jáde pẹ̀lú ìbínú à fẹ́ yíká ìjì yóò fẹ́ sí orí àwọn olùṣe búburú.
20 Anih loh a saii tih a lungbuei kah thuepnah a thoh duela BOEIPA kah thintoek tah mael mahpawh. Te te hmailong tue vaengah yakmingnah neh na yakming uh bitni.
Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀ títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ, ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.
21 Tonghma rhoek te ka tueih pawt dae amamih yong uh. Amih te ka uen pawt dae amamih tonghma uh.
Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyí síbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn. Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
22 Tedae kai kah baecenol dongah pai uh tih ka pilnam te kai ol yaak sak uh koinih a longpuei thae neh a khoboe thaenah lamloh amih mael uh ni.
Ṣùgbọ́n ì bà ṣe pé wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi, wọn ìbá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi. Wọn ìbá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi fun àwọn ènìyàn wọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nà àti ìṣe búburú wọn.
23 He tah BOEIPA kah olphong ni. Kai neh a yoei kah Pathen la om tih a hla ah tah a Pathen moenih a?
“Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?” ni Olúwa wí, “kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jíjìn.
24 Hlang he a huephael ah thuh uh cakhaw kai loh anih te ka hmuh moenih a? He tah BOEIPA kah olphong ni. Vaan neh diklai he ka tluek moenih a? He tah BOEIPA kah olphong ni.
Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan, kí èmi má ba a rí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi kò ha a kún ọ̀run àti ayé bí?” ni Olúwa wí.
25 Tonghma rhoek loh kai ming neh ka tonghma a ti uh tih a laithae neh mang ka man rhoe ka man coeng a ti uh te ka yaak.
“Mo ti gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’
26 Me hil nim laithae la aka tonghma tonghma rhoek neh a lungbuei aka huep tonghma rhoek kah lungbuei khuiah a koe aih ve.
Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀síwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìtànjẹ ọkàn wọn?
27 A mang dongah ni ka pilnam loh ka ming he hnilh ham a moeh uh. A napa rhoek loh Baal kongah kai ming a hnilh uh vanbangla hlang loh a hui taengah ana thui te.
Wọ́n rò wí pé àlá tí wọ́n ń sọ fún ara wọn yóò mú kí àwọn ènìyàn mi gbàgbé orúkọ mi, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé orúkọ mi nípa sí sin òrìṣà Baali.
28 Amah taengah mueimang aka om tonghma te tah a mueimang khaw thui saeh. Tedae a taengah kai ol aka dang long tah ka ol oltak he thui saeh. He tah BOEIPA kah olphong ni, cangpai neh cangkong te metlam a vai uh eh?
Jẹ́ kí wòlíì tí ó bá lá àlá sọ àlá rẹ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mí sọ ọ́ ní òtítọ́. Kí ni koríko gbígbẹ ní í ṣe nínú ọkà?” ni Olúwa wí.
29 He tah BOEIPA kah olphong coeng ni. Ka ol he hmai bangla, thaelpang aka taekyak kilung bangla a om moenih a?
“Ọ̀rọ̀ mi kò ha a dàbí iná?” ni Olúwa wí, “àti bí òòlù irin tí ń fọ́ àpáta túútúú?
30 Te dongah a hui taeng lamloh ka ol aka huen hlang neh tonghma rhoek te ka pai thil coeng ne. He tah BOEIPA kah olphong coeng ni.
“Nítorí náà, èmi lòdì sí àwọn wòlíì ni,” Olúwa wí, “Tí ń jí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ó ti ọ̀dọ̀ mi wá lò lọ́dọ̀ ara wọn.
31 He tah BOEIPA kah olphong ni. Olphong te a phong lalah amih kah ol loh kongah tonghma rhoek te ka pai thil coeng ne.
Bẹ́ẹ̀,” ni Olúwa wí, “Èmi lòdì sí àwọn wòlíì tí wọ́n lo ahọ́n wọn káàkiri, síbẹ̀ tí wọ́n ń sọ wí pé, ‘Olúwa wí.’
32 He tah BOEIPA kah olphong coeng ni. A honghi kah mang neh aka tonghma rhoek khaw ka pai thil coeng ne. A thui uh vaengah ka pilnam he a honghi neh, a hohap neh khohmang la a khuehuh. Tedae amih te ka tueih pawt tih amih ka uen van pawt dongah a hoeikhang ham akhaw pilnam ham a hoeikhang moenih. He tah BOEIPA kah olphong coeng ni.
Nítòótọ́, mo lòdì sí àwọn tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àlá èké,” ni Olúwa wí. “Wọ́n ń sọ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà nípa onírúurú èké wọn, síbẹ̀ èmi kò rán wọn tàbí yàn wọ́n. Wọn kò sì ran àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ́wọ́ bí ó ti wù kí ó kéré mọ,” ni Olúwa wí.
33 He pilnam long khaw, tonghma long khaw, khosoih long khaw nang n'dawt atah BOEIPA kah olrhuh te thui pah. Te vaengah amih taengah nangmih kam phap ham olrhuh te amih taengah thui pah. He tah BOEIPA kah olphong coeng ni.
“Nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, tàbí wòlíì tàbí àlùfáà bá bi ọ́ léèrè wí pé, ‘Kí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa?’ Sọ fún wọn wí pé, ‘Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ wo? Èmi yóò pa yín tì ni Olúwa wí.’
34 Te dongah tonghma khaw, khosoih khaw, pilnam khaw BOEIPA kah olrhuh aka phoei tah tekah hlang te khaw a im te ka cawh pah ni.
Bí wòlíì tàbí àlùfáà tàbí ẹnikẹ́ni bá sì gbà wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’ Èmi yóò fi ìyà jẹ ọkùnrin náà àti gbogbo agbo ilé rẹ̀.
35 BOEIPA loh metla a doo tih BOEIPA loh metla a voek khaw hlang neh a hui taengah khaw hlang neh a manuca taengah khaw thui pah tangloeng.
Èyí ni ohun tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ọ̀rẹ́ àti ará ilé rẹ̀: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa sọ?’
36 A ol he hlang taengah olrhuh la om dae BOEIPA kah olrhuh te koep na poek uh moenih. Te dongah ni caempuei BOEIPA mamih kah Pathen, hingnah Pathen kah ol he na maelh uh.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run wa padà.
37 BOEIPA loh nang metla n'doo tih BOEIPA loh metla m'voek khaw tonghma taengah thui pah van.
Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’
38 BOEIPA kah olrhuh na ti van atah BOEIPA loh a thui he thui van tangloeng. He ol he BOEIPA kah olrhuh la na thui. Tedae Thui hamla nang te kan tueih vaengah BOEIPA kah olrhuh ni na ti hae moenih.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ, Ẹ̀yin ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe lò ó mọ́, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’
39 Te dongah kai loh nangmih te kan hnilh rhoe kan hnilh pawn ni he. Nangmih taeng neh na pa rhoek taengah kam paek khopuei neh ka mikhmuh khui lamloh nangmih te kam phap ni.
Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn ìlú tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.
40 Kumhal kah kokhahnah neh kumhal kah yahpohnah te nangmih soah kang khueh vetih hnilh tlaih mahpawh.
Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”

< Jeremiah 23 >