< Hosea 9 >
1 Israel te na Pathen taeng lamloh na cukhalh uh cangpai cangtilhmuen tom ah a paang na lungnah uh dongah ni pilnam bangla omngaihnah la na ko a hoe uh pawh.
Má ṣe yọ̀, ìwọ Israẹli; má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù. Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìṣòótọ́ si Ọlọ́run yín. Ẹ fẹ́ràn láti gba owó iṣẹ́ àgbèrè ní gbogbo ilẹ̀ ìpakà.
2 Cangtilhmuen neh va-am loh amih te luem puei pawt vetih a khuiah misur thai loh a vaitah ni.
Àwọn ilẹ̀ ìpakà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹ wáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀.
3 BOEIPA kah khohmuen ah kho a sak uh pawt vaengah tah Ephraim te Egypt la mael vetih Assyria ah rhalawt hno a caak uh ni.
Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé Olúwa Efraimu yóò padà sí Ejibiti, yóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ́ ní Asiria.
4 BOEIPA taengah misurtui bueih uh pawt vetih a taengah a lungtui uh mahpawh. Amih kah hmueih te amamih taengah tamsa buh bangla om ni. A hinglu te BOEIPA im la a kun pawt dongah aka ca boeih khaw a buh neh poeih uh ni.
Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn. Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀. Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́. Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnra wọn kò ní wá sí orí tẹmpili Olúwa.
5 Tingtunnah hnin neh BOEIPA kah khotue hnin ah balae na saii uh eh?
Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn ní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?
6 rhoelrhanah lamloh cet uh mai cakhaw ne, amih te Egypt loh a coi vetih Memphis loh amah la a up ni. Amih kah cak te dohui loh a nulnah uh vetih amamih khaw a dap khuiah ni mutlo hling loh a huet eh.
Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparun Ejibiti yóò kó wọn jọ, Memfisi yóò sì sin wọ́n. Ibi ìsọjọ̀ fàdákà wọn ni ẹ̀gún yóò jogún, Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn. Ẹ̀gún yóò sì bo gbogbo àgọ́ wọn.
7 Cawhnah hnin a pha coeng, sahnah hnin a pha coeng. Tonghma ang neh mueihla hlang kah a pavai Israel loh ming saeh. Namah thaesainah loh cungkuem tih na muennah khaw yet.
Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀; àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti dé. Jẹ́ kí Israẹli mọ èyí. Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni. A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀, a ka ẹni ìmísí sí asínwín.
8 Ka Pathen neh Ephraim aka tawt tonghma khaw a longpuei boeih ah sayuep kah pael a om pah tih a Pathen im ah muennah om.
Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run, ni olùṣọ́ ọ Efraimu. Síbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀.
9 Gibeah tue bangla muelh paci uh amih kah tholhnah a cawh pah vaengah amamih kathaesainah a poek bitni.
Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́ gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ Gibeah Ọlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
10 Israel khaw khosoek kah misur bangla ka hmuh. Thaibu dongkah thaihloe a moe vaengkah bangla ka hmuh. Na pa rhoek khaw Baalpeor la a caeh uh dongah ni yahpohnah dongah a cue uh akhaw sarhingkoi te a lungnah bangla om uh.
“Mo rí Israẹli bí èso àjàrà ní aginjù. Mo rí àwọn baba yín, bí àkọ́pọ́n nínú igi ọ̀pọ̀tọ́ ní àkọ́so rẹ̀. Ṣùgbọ́n wọ́n tọ Baali-Peori lọ, wọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá ni, ohun ìríra wọn sì rí gẹ́gẹ́ bí wọn ti fẹ́.
11 Ephraim loh amih kah thangpomnah te cacun khui lamloh, bungko lamloh, rhumpum lamloh vaa bangla a ding puei ni.
Ògo Efraimu yóò fò lọ bí ẹyẹ kò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.
12 A ca rhoek te pantai uh mai bal cakhaw hlang te a pum la ka cakol sak ni. Amih taeng lamloh ka nong vaengah amih aih te anunae!
Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà. Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọn. Ègbé ni fún wọn, nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!
13 Ephraim te Tyre taengah tolkhoeng dongkah a phung bangla ka hmuh dae Ephraim he a ca rhoek aka ngawn pah taengah khuen ham om.
Mo rí Efraimu bí ìlú Tire tí a tẹ̀dó sí ibi dáradára ṣùgbọ́n Efraimu yóò kó àwọn ọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”
14 Aw BOEIPA amih te pae dae. Balae tih amih te cakol bung neh rhangsuk aka rhae te a paek khaw na paek eh?
Fún wọn, Olúwa! Kí ni ìwọ yóò fún wọn? Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́ àti ọyàn gbígbẹ.
15 Amih kah boethae loh Gilgal ah khaw cungkuem coeng. Amih kah khoboe thaenah dongah ni amih te hnap ka thiinah. Amih te ka im lamloh ka haek vetih amih lungnah ham ka khoep mahpawh. A mangpa boeih khaw a thinthah uh.
“Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní Gilgali, Mo kórìíra wọn níbẹ̀, nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé mi, Èmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́ ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.
16 Ephraim te a ngawn tih a yung a koh dongah a thaih a cuen kolla om mahpawt nim? Amih bungko kah ngailaemnah te cun uh mai sitoe cakhaw ka duek sak ni.
Efraimu ti rẹ̀ dànù gbogbo rẹ̀ sì ti rọ, kò sì so èso. Bí wọ́n tilẹ̀ bímọ. Èmi ó pa àwọn ọmọ wọn tí wọ́n fẹ́ràn jùlọ.”
17 A ol te a hnatun uh pawt dongah amih te ka Pathen loh a hnawt vetih namtom taengah aka poeng la om uh ni.
Ọlọ́run mi yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí pé wọn kò gbọ́rọ̀ sí i; wọn yóò sì di alárìnkiri láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.