< Suencuek 49 >
1 Te phoeiah Jakob loh a ca rhoek te a khue tih, “Tun ngol uh lamtah, vuenvai ah nangmih taengah aka thoeng ham te nangmih taengah ka puen pawn ni,
Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
2 Jakob ca rhoek loh a yaak uh tih a coi uh thae vaengah, “Na pa Israel kah ol te ya uh van lah.
“Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
3 Reuben nang he ka caming tih, ka thadueng neh, ka thahuem cuek, hlangrhuel boeimang, hlangtlung hlangrhuel la na om dae,
“Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
4 Na pa kah tih thingkong sola na yoeng tih, ka rhaenghmuen te na poeih phoeiah, tui bangla na soetaenah dongah caknoi khaw na khueh mahpawh.
Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
5 Simeon neh Levi boeina, amih rhoi kah tubael tah kuthlahnah tumca ni.
“Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
6 Amih rhoi kah tingtunnah dongah ka hinglu naepkhap pawh. Amah rhoi kah thintoek dongah hlang a ngawn rhoi tih vaito kaprhui haih ham te amih rhoi kah kolonah la a om dongah, kai kah thangpomnah loh amih rhoi a hlangping te bulbo boel saeh.
Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
7 Amih rhoi kah a thinpom khaw a tlung dongah a thintoek te thae a phoei thil. Te dongah a mangkhak te Jakob taengah ka tael vetih Israel taengah khaw ka taekyak ni.
Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
8 Judah nang he na manuca rhoek loh nang n'uem uh ni. Na kut te na thunkha a rhawn dongla cu ni. Na pacaboeina te nang taengah bakop uh ni.
“Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
9 Judah he sathueng ca ni. Ka ca loh maeh kung lamkah na bal phoeiah, sathueng neh sathuengnu bangla aka yuel tih, aka kol te ulong anih a haeng eh.
Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
10 Judah lamkah mancai tah nong boel lamtah, a kho laklo lamloh taem saeh. Shiloh a pha duela anih taengah, pilnam kah boengainah om saeh.
Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
11 A laaktal, laaktal te misur dongah, a laak ca te cangsawt misur dongah pael saeh. A pueinak te misurtui dongah, a hnipup, hnipup te misur thii dongah til saeh.
Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
12 Na mik khaw musurtui lakah ling vetih, na no te suktui lakah bok ni.
Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
13 Zebulun he tuitunli kah langkaeng ah khosa saeh lamtah, langkaeng kah sangpho rhoek bangla a bawtnah loh Sidon due pha saeh.
“Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
14 Issakhar he laak songrhuh bangla saelvong laklo ah na kol.
“Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
15 Duemnah then neh khohmuen hlahmae te khaw a hmuh dae, phueih te a laengpang ah a thueng tih aka thotat saldong la om ni.
Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
16 Dan he Israel koca pakhat vanbangla a pilnam kah lai a thui pah ni.
“Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
17 Dan he long taengkah rhul neh marhang dongkah aka ngol te a hnuk la bung saeh tila marhang khomik aka maeng tih, caehlong rhulthae bangla om ni.
Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
18 BOEIPA nang kah khangnah ham ni ka lamtawn he.
“Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
19 Gad he caem loh tloek cakhaw anih loh a khomik a tloek pah ni.
“Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
20 Asher ham caak bae vetih, manghai buhmong a tael ni.
“Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
21 Naphtali tah sayukrhuinu bangla khocaeh dangka vetih, ol then a thui ni.
“Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
22 Joseph tah a ca loh thaihsu tih, a ca loh tuiphuet taengkah pungtai. Ngannu ngankhong loh pangbueng dongla luei.
“Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
23 Thaltang boei rhoek a konaeh uh dongah, a phaep uh tih a kah uh.
Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
24 Tedae Jakob kah samrhang kut rhang neh, Israel aka dawn lungnu rhang neh,
Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
25 Na pa kah Pathen loh nang m'bom tih Tlungthang loh nang te vaan a sosang kah yoethennah, a laedil kah aka kol yoethennah nen khaw, a rhangsuk dongkah yoethennah nen khaw, a bung khuikah nen khaw yoethen m'paek dongah, a li khaw tangkuek la om tih, a kut bantha khaw caang.
nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
26 Na pa kah yoethennah he kai aka yom kah yoethennah lakah len. Khosuen som ah a saelongnah hil Joseph lu so neh a manuca hlangcoelh luki soah om saeh.
Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
27 Benjamin, uithang laihat loh, mincang ah maeh a ngaeh, hlaem ah kutbuem a tael,” a ti nah.
“Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
28 A pum boeih la Israel koca he hlai nit dongah a napa loh amih taengah a thui vaengah amah kah yoethennah neh amih te yoethen rhip a paek.
Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
29 Te phoeiah amih te a uen tih, “Kai he ka pilnam taengla ka khum atah a pa rhoek neh Khitti Ephron lo kah lungko ah n'up uh.
Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
30 Kanaan kho Mamre hmai, Makpelah lo kah lungko te phuel khohut la Khitti Ephron taeng lamkah Abraham loh a lai khohmuen ni.
Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
31 Ti ah te Abraham neh a yuu Sarah a up uh tih Isaak neh a yuu Rebekah te pahoi a up uh coeng. Leah khaw pahoi ka up coeng.
Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
32 Te dongah Kheth ca rhoek taeng lamkah te khohmuen boiva neh a khuikah lungko te,” a ti nah.
Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
33 Jakob loh a ca rhoek a uen te a khah phoeiah baiphaih dongla a kho a yueh. Te phoeiah pal tih a pilnam taengla khoem uh.
Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.