< 2 Manghai 5 >
1 Aram manghai kah caempuei mangpa Naaman tah a boei mikhmuh ah hlang len la om. BOEIPA loh anih soah Aram ham loeihnah te a paek dongah a maelhmai khaw cawkdawk. Tekah hlang te tatthai hlangrhalh la om dae boeih pahuk.
Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
2 Aram caem a caeh vaengah Israel kho lamkah hula ca a sol uh tih Naaman yuu kah mikhmuh ah a om pah.
Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
3 A boeinu taengah te, “Ka boei he Samaria kah tonghma mikhmuh ah koinih a hmaibae he amah la a toi sue,” a ti nah.
Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
4 Cet tih a boei te a voek phoeiah Israel kho kah hula loh a thui te heben hebang la a thui pah.
Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
5 Aram manghai loh, “Cet lamtah paan laeh. Israel manghai taengah ca ka pat bitni,” a ti nah. Te dongah cet tih a kut dongah cak talent parha, sui thawng rhuk, thovaelnah himbai yung rha a khuen.
“Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
6 Cabu te Israel manghai taengla a khuen tih, “Ca he nang taengla ha pawk coeng, ka sal Naaman te nang taengla kan tueih ne. Te dongah anih kah hmaibae te amah la toi pah mai,” a ti nah.
Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
7 Ca te Israel manghai loh a tae van neh a himbai te a phen tih, “Duek sak ham neh hing sak ham khaw kai he Pathen a? Hlang kah a hmaibae toi pah ham kai taengla he he ham pat. Te dongah rhep ming uh laeh lamtah anih loh kai taengah a hong te hmu uh,” a ti.
Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
8 Israel manghai loh a himbai a phen te Pathen kah hlang Elisha loh a yaak. Te dongah manghai te a tah tih, “Balae tih na himbai na phen? Kai taengah lo pawn saeh lamtah Israel ah tonghma a om te ming saeh,” a ti nah.
Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
9 Te dongah Naaman te a marhang neh cet tih a marhang khaw, a leng khaw Elisha im kah thohka ah a pai pah.
Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
10 Te vaengah Elisha loh a taengla puencawn a tueih pah tih,” Cet lamtah Jordan ah voei rhih sil uh. Na saa te maat vetih nang ham caihcil bitni,” a ti nah.
Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
11 Tedae Naaman te a thintoek neh cet tih, “'Kai taengla ha mop khaw ha mop mai vetih a pai doela a Pathen BOEIPA ming te a khue moko. A kut neh a hma he a yuh mai vetih aka pahuk he a toi mako,’ ka ti ne.
Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
12 Amanah kah Abana neh Damasku kah Pharpar tuiva he Israel tui boeih lakah a then moenih a? Te rhoek ah ka sil uh cakhaw ka caihcil mahpawt a?” a ti. Te phoeiah mael tih kosi neh cet.
Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
13 Tedae Naaman sal rhoek te thoeih uh tih amah te a thui pauh. Te vaengah, “A pa nae, tonghma loh nang taengah ol tloh thui koinih na ngai mahpawt nim? Te dongah nang te, 'Sil lamtah caihcil laeh,” a ti mai te,” a ti nah.
Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
14 Te daengah suntla tih Pathen hlang kah ol bangla Jordan ah voei rhih nuem uh. Te vaengah a saa te camoe ca kah saa bangla a khaam pah tih a caihcil pah.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
15 Te dongah Pathen hlang taengah amah khaw a lambong boeih neh cet tih Elisha mikhmuh ah a pai pah. Israel khui bueng phoeiah tah diklai pum ah Pathen tloe om pawh tila ka ming coeng he. Te dongah na sal taeng lamkah yoethennah he doe mai laeh,” a ti nah.
Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
16 Tedae,” BOEIPA kah hingnah bangla a mikhmuh ah ka pai coeng, ka lo mahpawh,” a ti nah. A doe hamla anih te a hloep dae a aal pah.
Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
17 Naaman loh, “Na loh pawt oeh atah na sal he diklai muli-marhang pumnit phueih m'pae mai. Yahweh ham bueng phoeiah tah pathen tloe ham hmueihhlutnah neh hmueih te na sal loh ka saii voel mahpawh.
Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
18 He ol dongah khaw na sal he BOEIPA loh khodawkngai saeh. Ka boei khaw Rimmon im ah kun tih pahoi bakop coeng. Anih te ka kut dongah a hangdang vaengah tah Rimmon im ah ka bakop coeng. Rimmon im ah ka bakop mai cakhaw he ol lamlong tah na sal he BOEIPA loh khodawkngai mai saeh,” a ti nah.
Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
19 Te phoeiah anih te, “Sading la cet laeh,” a ti nah tih a taeng lamloh kho lak la cet.
Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
20 Te vaengah Pathen hlang Elisha kah tueihyoeih Gehazi loh, “A khuen te a kut lamkah a doe pah ham khaw ka boei loh Arammi Naaman he a tuemsoem coeng. BOEIPA kah hingnah bangla a hnuk ah ka yong vetih anih taengkah khat khat ka lo ni,” a ti.
Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
21 Gehazi loh Naaman hnuk a hloem vaengah a hnukah a yong pah te Naaman loh a hmuh. Te dongah anih doe ham te leng dong lamloh rhum tih, “Na sading ngawn nama?” a ti nah.
Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
22 Te vaengah, “Sading ngawn ue, ka boei loh kai n'tueih tih, 'Ephraim tlang lamkah tonghma koca lamkah camoe panit kai taengla tarha ha pawk coeng he, amih rhoi ham cak talent khat neh thovaelnah himbai yung nit m'pae mai,’ a ti,” a ti nah.
“Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
23 Naaman loh, “Namah ngaih te talent panit khaw lo,” a ti nah. Anih te a pueh pah tih sungkoi panit dongah cak talent panit neh thovaelnah himbai yung nit a yom sak. Te phoeiah a tueihyoeih rhoi taengla a paek tih a hmai la ana phueih pah.
Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
24 Molpuei la a pawk vaengah amih kut lamkah te a loh tih im ah a tung. Te phoeiah hlang rhoek te a tueih tih khoe uh.
Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
25 Anih te kun tih a boei rhoek taengah a pai pah. Te vaengah Elisha loh anih te, “Me lamkah nim, Gehazi me lamkah nim?” a ti nah. Tedae, “Na sal he melam khaw a caeh moenih,” a ti nah.
Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
26 Hlang te nang doe ham a leng dong lamloh a mael vaengah ka lungbuei he anih taengah a caeh moenih a? Tangka na loh ham neh himbai, olive, misur, boiva, saelhung, salpa, salnu na loh ham a tue a?
Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
27 Naaman kah hmaibae loh namah neh na tiingan te kumhal duela n'dom laeh saeh,” a ti nah. Te dongah anih mikhmuh lamkah a nong neh vuelsong bangla pahoi pahuk.
Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.