< Nehemiah 1 >

1 Hakaliah capa Nehemiah ih loknawk loe, Susan vangpui ah ka oh nathuem, saning pumphaeto haih, Khislev khrah ah,
Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
2 kam nawk maeto Hanani loe thoemto Judah kaminawk hoi nawnto angzoh, to naah nihcae khaeah misong ah kaom Judah kaminawk hoi Jerusalem vangpui kawng to ka dueng.
Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
3 Nihcae mah kai khaeah, Misong loih kaminawk hoi prae thungah kaom kaminawk loe paroeai raihaih tong o; Jerusalem tapang loe amtim rup boeh, tapang khongkhanawk doeh hmai mah kang boih boeh, tiah ang thuih o.
Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
4 To lok to ka thaih naah, anghnut moe, ka qah; ni nazetto maw loe palung ka set moe, buhcaa ai ah, van Sithaw khaeah lawk ka thuih.
Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
5 Hae tiah lawk ka thuih, Aw Angraeng, van Sithaw, lensawk moe, zitthok Angraeng, a palung ih kami hoi a paek ih lok tahngai kaminawk khaeah, a lokmaihaih baktih toengah koepsakkung Sithaw,
Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
6 na tamna, Israel kaminawk hanah, khoving khodai, na hmaa ah, na tamna mah kang thuih ih lok to thaih hanah, na mikpadai ah loe, na naa to patueng raeh; kaicae Israel caanawk mah ka sak o ih zaehaihnawk, kaimah hoi kam pa imthung takoh mah sak ih zaehaihnawk boih na hmaa ah kang taphong.
Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
7 Na hmaa ah kahoih ai hmuen ka sak o moeng boeh, na tamna Mosi khaeah na paek ih loknawk, daan hoi lok takroekhaihnawk to ka pazui o ai boeh.
Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
8 Na tamna Mosi khaeah, Zaehaih na sak o nahaeloe, prae kalah kaminawk salakah kam hetsak phang han;
“Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
9 toe kai khaeah nam laem let moe, ka paek ih loknawk na pazui o pacoengah, na sak o nahaeloe, van tlim ih kangthla koek prae ah na haek o langlacadoeh, to ahmuen hoiah kang tacuu o let moe, ka hmin caksak hanah ka qoih ih ahmuen ah kang hoih o let han, tiah na thuih ih lok to poek let ah.
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
10 Vaihiah hae kaminawk hae kalensawk thacakhaih, na ban thacakhaih hoiah na krang ih, na tamna hoi nangmah ih kami ah ni oh o.
“Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
11 Aw Angraeng, na tamna lawkthuihaih hoi na hmin azathaih paek hanah na tamna ih lawkthuihaih lok hae na tahngai pae ah; vaihi na tamna hae tahamhoihaih paek ah; hae kami hmaa ah khosak hoihaih akoepsak ah, tiah lawkthuih.
Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.

< Nehemiah 1 >