< Hosea 7 >

1 Israel ngan ka tuisak naah, Ephraim zaehaih to amtueng ueloe, Samaria poeksethaih doeh amtueng tih. Nihcae mah kami aling o pongah, kamqu imthung ah angzoh moe, mingcahnawk mah tasa bang ih hmuenmaenawk to lomh pae o.
nígbà tí èmi ìbá mú Israẹli láradá. Ẹ̀ṣẹ̀ Efraimu ń farahàn ìwà búburú Samaria sì ń hàn síta. Wọ́n ń ṣe ẹ̀tàn, àwọn olè ń fọ́ ilé; àwọn ọlọ́ṣà ń jalè ní òpópónà;
2 Toe nihcae mah sak o ih sethaih to ka panoek pae boih, tito nihcae mah poek o ai; a sak o ih hmuen mah nihcae to takui khoep boeh; nihcae loe ka hmaa ah ni oh o.
ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo rántí gbogbo ìwà búburú wọn. Ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbé wọn mì pátápátá; wọ́n wà níwájú mi nígbà gbogbo.
3 A set o haih mah siangpahrang to anghoe o sak moe, lok amlai o haih hoiah ukkung angraengnawk to anghoe o sak.
“Wọ́n ń mú inú ọba dùn pẹ̀lú ìwà búburú wọn, àti inú ọmọ-aládé dùn pẹ̀lú irọ́ wọn.
4 Nihcae loe tamquta hoi zaehaih sah kami ah oh o moe, takaw haek kami mah camphaek laom hmai pangaeh ih baktiah oh o; takaw naep kami mah takaw to naep naah, takaw naep boih ai karoek to hmai kamngaeh azuh baktiah a oh o.
Alágbèrè ni gbogbo wọn wọ́n gbóná bí ààrò àkàrà tí a dáwọ́ kíkoná dúró, lẹ́yìn ìgbà tí o ti pò ìyẹ̀fun tán, títí ìgbà tí yóò wú.
5 Aicae siangpahrang ih poih niah anih ih toksah ukkung angraengnawk loe misurtui to paquih o; siangpahrang loe minawk mah pahnuithui ih kaminawk hoi nawnto amyok.
Ní ọjọ́ àjọ̀dún ọba wa wáìnì mú ara ọmọ-aládé gbóná ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn oníyẹ̀yẹ́.
6 Nihcae mah anih to zing o naah, palungthin to takoeng hmai baktiah a suek o; nihcae han takaw haek pae kami loe qum puek a iih; akhawnbang phak naah loe hmai kangqong baktiah angqongh.
Ọkàn wọn ń gbóná bí i ààrò wọ́n sì tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú rìkíṣí, ìbínú wọn pa lọ́lọ́ ní gbogbo òru ó sì bú jáde bí ọ̀wọ́-iná ní òwúrọ̀.
7 Nihcae loe omthu baktiah bet o boih moe, angmacae lokcaekkungnawk doeh kangh boih; nihcae ih siangpahrangnawk doeh amtimh o boih boeh. Nihcae thungah kai kawk kami mi doeh om o ai.
Gbogbo wọn gbóná bí ààrò wọ́n pa gbogbo olórí wọn run, gbogbo ọba wọn si ṣubú kò sì ṣí ẹnìkan nínú wọn tí ó ké pè mí.
8 Ephraim loe kaminawk hoi angbaeh moe, nawnto khosak; Ephraim loe qoi ai ah ahap khue hmai paaem ih takaw karoem baktiah ni oh.
“Efraimu ti darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn náà; Efraimu jẹ́ àkàrà tí a kò yípadà.
9 Minawk kalah mah anih ih tha to caak pae o, toe anih mah panoek ai; ue, a lu nui ih sam doeh pok boeh, toe anih mah panoek ai.
Àwọn àlejò ti jẹ agbára rẹ̀ run ṣùgbọ́n kò sì mọ̀. Ewú ti wà ní orí rẹ̀ káàkiri bẹ́ẹ̀ ni kò kíyèsi i.
10 Israel amoekhaih loe a mikhmai ah amtueng, toe nihcae loe angmacae ih Angraeng khaeah amlaem o ai, anih to pakrong o ai.
Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí sí i ṣùgbọ́n pẹ̀lú gbogbo èyí kò padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run, tàbí kí ó wá a.
11 Ephraim loe poekhaih tawn ai, pahu baktiah oh: Izip to kawk o moe, Assyria khaeah caeh o.
“Efraimu dàbí àdàbà tó rọrùn láti tànjẹ àti aláìgbọ́n tó wá ń pé Ejibiti nísinsin yìí tó sì tún ń padà lọ si Asiria.
12 Nihcae caeh o naah, palok hoi ka haengh han; nihcae to van ih tavaanawk baktiah ka zaeh tathuk han; angmacae ih kaminawk mah thaih o ih baktih toengah, nihcae to ka thuitaek han.
Nígbà tí wọ́n bá lọ, èmi ó ta àwọ̀n mi sórí wọn, Èmi ó fà wọ́n lulẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ ojú ọ̀run. Nígbà tí mo bá gbọ́ pé wọ́n rìn pọ̀, Èmi ó nà wọ́n fún iṣẹ́ búburú ọwọ́ wọn.
13 Nihcae loe Kai khae hoi cawnh o ving boeh pongah, khosak bing o boeh! Ka nuiah zaehaih a sak o pongah, nihcae loe anghmat o boeh. Nihcae to ka krang boeh, toe kai khaeah amsawnlok a thuih o.
Ègbé ní fún wọn, nítorí pé wọ́n ti yà kúrò lọ́dọ̀ mi! Ìparun wà lórí wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi! Èmi fẹ́ láti rà wọ́n padà. Ṣùgbọ́n wọ́n ń parọ́ mọ́ mi.
14 Nihcae iihkhun ah qah o naah, palungthin tang hoi kai khaeah hang o ai. Nihcae loe cang hoi misurtui hak hanah nawnto amkhueng o, toe ka lok to aek o.
Wọn kò kégbe pè mí láti ọkàn wọn, ṣùgbọ́n wọ́n ń pohùnréré ẹkún lórí ibùsùn wọn. Wọ́n kó ara wọn jọ, nítorí ọkà àti wáìnì ṣùgbọ́n wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.
15 Nihcae to ka thuitaek moe, bantha ka caksak, toe nihcae mah ka nuiah kasae sak han pacaeng o lat.
Mo kọ́ wọn, mo sì fún wọn ní agbára, síbẹ̀ wọ́n tún ń dìtẹ̀ mọ́ mi.
16 Nihcae loe angqoi o, toe kasang koek khaeah angqoi o ai; nihcae loe kamro thaih kalii hoiah ni anghmong o boeh: angmacae ukkung angraengnawk loe angmacae tangoenghaih lok pongah sumsen hoiah dueh o tih. Nihcae loe Izip kaminawk mah pahnui o thui tih.
Wọn kò padà sí ọ̀dọ̀ Ọ̀gá-ògo; wọ́n dàbí ọfà tí ó ti bàjẹ́. Àwọn aṣíwájú wọn yóò ti ipa idà ṣubú nítorí ìrunú ahọ́n wọn. Torí èyí, wọn ó fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ní ilẹ̀ Ejibiti.

< Hosea 7 >