< Exodus 31 >
1 To pacoengah Angraeng mah Mosi khaeah,
Olúwa wí fún Mose pé,
2 khenah, Judah acaeng, Uri capa, Bazalel to ahmin hoiah ka kawk boeh;
“Wò ó, Èmi ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
3 anih loe Sithaw ih Muithla, palunghahaih, kophaih, panoek thaihaih hoi congca bantok sak thaihaih hoiah ka koisak boeh.
Èmi sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un pẹ̀lú ọgbọ́n, òye àti ìmọ̀ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
4 Anih khaeah sui, sum kanglung hoi sum kamling sak thaihaih tok,
Láti ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní wúrà, fàdákà àti idẹ,
5 thlung aah kophaih hoi thing aah kophaih tok, tok congca sak thaihaih to ka paek boeh.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò wọ́n, láti ṣiṣẹ́ ní igi, àti láti ṣiṣẹ́ ní gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
6 Khenah, anih to abomh hanah Dan acaeng, Ahisamak capa Aholiah to ka paek boeh; palungha kaminawk mah kang thuih ih loknawk to sak o boih hanah, nihcae palung thungah palunghahaih to ka paek boeh;
Síwájú sí i, èmi ti yan Oholiabu ọmọ Ahisamaki, ti ẹ̀yà Dani, láti ràn án lọ́wọ́. “Bákan náà, Èmi ti fi ọgbọ́n fún gbogbo àwọn oníṣẹ́-ọnà láti ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún ọ:
7 kaminawk amkhuenghaih kahni im, hnukung ah kaom thingkhong, to thingkhong nuiah kaom palungnathaih tangkhang hoi kahni im ih hmuennawk boih,
“àgọ́ àjọ náà, àpótí ẹ̀rí pẹ̀lú ìtẹ́ àánú tí ó wà lórí rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò àgọ́ náà,
8 caboi hoi hmuennawk, kaciim hmaithawk hoi paanghaih tungnawk boih, hmuihoih thlaekhaih hmaicam,
tábìlì àti ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà tí ó jẹ́ kìkì wúrà àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, pẹpẹ tùràrí,
9 hmai angbawnhaih hmaicam hoi hmuennawk boih, amsaehhaih sabae kathuk hoi pahnuthaih a khoknawk,
pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀,
10 toksakhaih khukbuennawk, qaima toksak naah, Aaron hoi a capanawk mah angkhuk han ih kaciim kahninawk,
àti aṣọ híhun pẹ̀lú, papọ̀ pẹ̀lú aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ bí àlùfáà,
11 bawh ih situi hoi hmuenciim ah thlaek ih hmuihoih to sak hanah, nang khaeah kang thuih ih lok baktih toengah, nihnik mah sah hoi tih, tiah a naa.
òróró ìtasórí àti tùràrí olóòórùn dídùn fún Ibi Mímọ́. “Kí wọ́n ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí mo ṣe pàṣẹ fún ọ.”
12 To pacoengah Angraeng mah Mosi khaeah,
Olúwa wí fún Mose pé,
13 kai loe nangcae ciimsakkung, Angraeng ah ka oh, tiah na panoek o moe, angzo han koi na caanawk dung khoek to, nangcae hoi kai salakah angmathaih ah oh hanah, Kai ih Sabbath to zaa oh, tiah Israel kaminawk khaeah thui paeh.
“Kí ìwọ kí ó sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ẹ̀yin gbọdọ̀ máa pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́. Èyí ni yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti ẹ̀yin fún ìrandíran tó ń bọ̀, nítorí kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, ẹni tí ó yà yín sí mímọ́.
14 Sabbath ni loe nangcae han ciimcai pongah, zaa oh; Sabbath ni amhnongsak kami loe, paduek han oh; Sabbath niah toksah kami loe, acaeng thung hoiah pahnawt oh.
“‘Nítorí náà, kí ẹ̀yin kí ó máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, nítorí mímọ́ ni fún un yín. Ẹnikẹ́ni tí ó bá bà á jẹ́, ni a yóò pa; ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà ni a yóò gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ.
15 Ni tarukto thung toksah oh, toe ni sarihto haih loe anghakhaih Sabbath niah oh moe, kaciim Angraeng ih niah oh; Sabbath niah toksah kami loe, paduek han oh.
Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ní ọjọ́ ìsinmi tí ẹ̀yin yóò fi sinmi, mímọ́ ni fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ni a ó pa nítòótọ́.
16 To pongah Israel kaminawk loe, angzo han koi a caanawk dung khoek to, dungzan lokkamhaih ah patoh hanah, Sabbath ni to zaa oh.
Nítorí náà ni àwọn ọmọ Israẹli yóò ṣe máa pa ọjọ́ ìsinmi mọ́, ẹ máa ṣe àkíyèsí rẹ̀ dé ìrandíran tó ń bọ̀ bí i májẹ̀mú títí láé.
17 Hae loe Israel kaminawk hoi kai salakah dungzan angmathaih ah om tih; Angraeng mah ni tarukto thung van hoi long to sak moe, ni sarihto naah loe, toksah ai ah anghak pongah, tha oh let, tiah thui paeh, tiah a naa.
Yóò jẹ́ àmì láàrín Èmi àti àwọn ọmọ Israẹli títí láé, nítorí ní ọjọ́ mẹ́fà ni Olúwa dá ọ̀run àti ayé, àti ní ọjọ́ keje ni ó fi iṣẹ́ sílẹ̀, ó sì sinmi.’”
18 Sinai mae ah Angraeng mah Mosi khaeah lokthuih pacoengah, Sithaw ih banpazung hoi tarik ih, hnukung ah kaom, thlung kangphaek hnetto, Mosi hanah a paek.
Nígbà tí Olúwa parí ọ̀rọ̀ sísọ fún Mose lórí òkè Sinai, ó fún un ní òkúta wàláà ẹ̀rí méjì, òkúta wàláà òkúta tí a fi ìka Ọlọ́run kọ.