< Exodus 12 >

1 Izip prae ah Angraeng mah Mosi hoi Aaron khaeah,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni ni ilẹ̀ Ejibiti pé,
2 Vaihi khrah loe nangcae han khrah tangsuek ah om tih; nangcae han saning amtong tangsuekhaih khrah ah om tih.
“Oṣù yìí ni yóò jẹ́ oṣù àkọ́kọ́ fún yín, oṣù àkọ́kọ́ nínú ọdún yín.
3 Vaihi khrah ni hato naah, kami boih, angmacae imthung takoh maeto mah, tuucaa maeto sin hanah, amkhueng Israel kaminawk boih khaeah thui ah, tiah a naa.
Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli pé ni ọjọ́ kẹwàá oṣù yìí, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan yóò mú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan fún ìdílé rẹ̀, ọ̀kan fún agbo ilé kọ̀ọ̀kan.
4 Imthung takoh maeto hanah tuucaa maeto khawt ai nahaeloe, a imtaeng ih kami hoi angcuu o nasoe loe, kami khawt ah tuucaa to sin o nasoe.
Bí ìdílé kan bá kéré jù fún odidi ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí wọn kí ó ṣe àjọpín ọ̀kan pẹ̀lú aládùúgbò wọn ti ó sun mọ́ wọn kí wọ́n lo iye ènìyàn tiwọn jẹ láti ṣe òdínwọ̀n irú ọ̀dọ́-àgùntàn tiwọn yóò lò ní ìbámu pẹ̀lú ìwọ̀n ti ẹni kọ̀ọ̀kan lè jẹ.
5 Coek koi kaom ai, saningto kaom Tuu tae to sin oh; to loe Tuu, to tih ai boeh loe Ma-eh thung hoiah qoi oh;
Ọ̀dọ́-àgùntàn tí ìwọ yóò mú gbọdọ̀ jẹ́ akọ ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, ìwọ lè mú lára àgbò tàbí ewúrẹ́.
6 to khrah ni hatlai palito pha ai karoek to tuucaa to kahoih ah khen oh loe, ani phak naah amkhueng Israel kaminawk mah to tuucaa to khoving ah bop o tih.
Ṣe ìtọ́jú wọn títí di ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò pa ẹran náà ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
7 Athii to la oh loe, tuu moi na caak o haih im thok ranuih hoi thok tung ranui ah nok oh.
Wọn yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò fi kan ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àti òkè ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé níbi tí wọ́n bá ti jẹ ẹran ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
8 To na ni duembang ah, hmai pakhaem ih moi to, kakhaa aan hoi taeh thuh ai ih takaw hoiah nawnto caa oh.
Ní òru ọjọ́ kan náà, wọn yóò jẹ ẹran tí a ti fi iná sun, pẹ̀lú ewé ewúro àti àkàrà aláìwú.
9 Kahaeng moi maw, to tih ai boeh loe tui hoiah bueh ih moi to caa o hmah; toe a lu moi, a khok hoi palung pathinnawk loe hmai pakhaem pacoengah caa oh.
Ẹ má ṣe jẹ ẹran náà ni tútù tàbí ní bíbọ̀ nínú omi, ṣùgbọ́n kí ẹ fi iná sun orí, ẹsẹ̀ àti àwọn nǹkan inú ẹran náà.
10 Moi to khawnbang khoek to suem o hmah; kamthlai zetta om nahaeloe, hmai hoiah qoeng oh.
Ẹ má ṣe fi èyíkéyìí sílẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí ó bá ṣẹ́kù di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ẹ jó o níná.
11 Moi na caak o naah, kaengkaeh to angzaeng oh, khokpanaibum abuen oh loe, ban ah cunghet to sin pacoengah, karangah caa oh; hae loe Angraeng ih loihhaih poih ah oh.
Báyìí ni ẹ̀yìn yóò ṣe jẹ́ tí ẹ̀yin ti àmùrè ní ẹ̀gbẹ́ yín, sáńdà yín ní ẹsẹ̀ yín àti ọ̀pá yín ni ọwọ́ yín. Ẹ yára jẹ ẹ́, oúnjẹ àjọ ìrékọjá Olúwa ni.
12 To na ni qum ah Izip prae thung boih ah ka caeh moe, kaminawk ih caa lu hoi tapen tangsuek moi to ka dueksak boih han; Izip sithawnawk to lok ka caek boih han; Kai loe Angraeng ah ka oh.
“Ní òru ọjọ́ yìí kan náà ni Èmi yóò la gbogbo ilẹ̀ Ejibiti kọjá, èmi yóò sì pa gbogbo àkọ́bí àti ènìyàn, àti ẹranko, èmi yóò mú ìdájọ́ wà sí orí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Ejibiti. Èmi ni Olúwa.”
13 Athii loe nangcae ohhaih im ah, angmathaih maeto ah om tih; athii ka hnuk naah, nangcae to kang takanh taak han; Izip prae ka tuk naah, nangcae nuiah kasae nathaih pha mak ai.
Ẹ̀jẹ̀ ni yóò jẹ́ àmì fún un yín ní àwọn ilé tí ẹ̀yin wà, nígbà tí èmi bá rí ẹ̀jẹ̀ náà, Èmi yóò ré e yín kọjá. Ààrùn kan kì yóò kàn yín nígbà tí èmi bá kọlu Ejibiti láti pa wọ́n run.
14 Hae ani hae pakuem o poe ah; na caanawk dung khoek to hae ani phak naah, Angraeng khaeah buh raenghaih poih to sah oh; sakzong ih atawk baktih toengah, to poih to dungzan khoek to sah oh.
“Ọjọ́ òní ni yóò sì máa ṣe ọjọ́ ìrántí fún yín, ẹ́yin yóò sì máa láàrín àwọn ìran tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn ni ẹ̀yin yóò ti máa ṣe ní àjọ fún Olúwa; ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
15 Ni sarihto thung taeh thuh ai ih takaw to caa oh; ni amtong tangsuek naah imthung ih taeh to va oh; ni amtong tangsuek hoi ni sarihto thung taeh thuh ih takaw caa kami loe, Israel acaeng thung hoiah pahnawt oh.
Fún ọjọ́ méje ni ẹ̀yin yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, ẹ ó gbé ìwúkàrà kúrò ni ilé yín, nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú láti ọjọ́ kìn-ín-ní di ọjọ́ keje ni kí a yọ kúrò ni Israẹli.
16 Amtong tangsuekhaih ni hoi sarihto niah, kaciim amkhuenghaih to sah oh; caaknaek khue ai ah loe tok kalah roe sah o hmah.
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; àti ní ọjọ́ keje àpéjọ mímọ́ mìíràn yóò wà fún yín. Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, bí kò ṣe oúnjẹ tí olúkúlùkù yóò jẹ; kìkì èyí ni gbogbo ohun tí ẹ̀yin lè ṣe.
17 Hae na ni roe ah Izip prae thung hoiah kang tacawt o haih pongah, taeh thuh ai ih takaw caakhaih poih to sah oh; sakzong ih atawk baktih toengah, na caanawk dung khoek to hae ani hae zaa o poe ah.
“Ẹ ó sì kíyèsí àjọ àìwúkàrà, nítorí ní ọjọ́ náà gan an ni mo mú ogun yín jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. Nítorí náà ni kí ẹ máa kíyèsi ọjọ́ náà ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
18 Khrah tangsuek, to akhrah ni hathlai palito duembang hoi kamtong ni pumphaeto pacoeng, nito duembang karoek to taeh thuh ai ih takaw to caa oh.
Àkàrà ti kò ni ìwúkàrà ni ẹ̀yin yóò jẹ láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kọ̀kànlélógún oṣù àkọ́kọ́.
19 Ni sarihto thung na imthung ah taeh to suem o hmah; angvin maw, to tih ai boeh loe prae thung tapen kami mah maw, taeh thuh ih takaw to caa nahaeloe, Israel acaeng thung hoiah pahnawt oh.
Fún ọjọ́ méje ni ẹ kò gbọdọ̀ ni ìwúkàrà nínú ilé yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó ni ìwúkàrà nínú ni a ó yọ kúrò ni àárín àwùjọ Israẹli, ìbá à ṣe àlejò tàbí ẹni tí a bí ní ilẹ̀ náà.
20 Taeh hoi sak ih takaw to caa o hmah; na ohhaih ahmuen kruekah taeh thuh ai ih takaw to caa oh, tiah a naa.
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe. Ní ibikíbi tí ẹ̀yin bá ń gbé, kí ẹ̀yin kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.”
21 To pacoengah Mosi mah Israel kacoehtanawk to kawk boih moe, nihcae khaeah, Caeh oh, nangmacae imthung takoh kakhawt ah, tuucaa maeto la oh loe, loihhaih poih sak hanah bop oh.
Ní ìgbà náà ni Mose pé gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ jáde lọ, kí ẹ sì yan ọ̀dọ́-àgùntàn fún àwọn ìdílé yín, kí ẹ sì pa ẹran àjọ ìrékọjá Olúwa.
22 Hissop thing tadok tamsum maeto la oh, sabae kathuk pong ih tuu thii thungah nup oh loe, thok ranui hoi thok tung ranui boih ah nok oh; khawnbang khoek to mi doeh thok tasa bangah caeh o hmah.
Ẹ̀yin yóò sì mú ìdí-ewé hísópù, ẹ tì í bọ inú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà nínú ọpọ́n kí ẹ sì fi kun òkè à bá wọ ẹnu-ọ̀nà ilé yín àti ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ìlẹ̀kùn yín. Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ jáde sí òde títí di òwúrọ̀.
23 Angraeng loe Izip kaminawk hum hanah Izip prae thung boih ah caeh tih; thok ranuih hoi thok tung ranuih boih ah nok ih athii to a hnuk naah, Angraeng mah to im thok to takan taak tih, to tiah kami humkung loe nangcae hum hanah imthung ah akunsak mak ai.
Ní ìgbà tí Olúwa bá ń lọ káàkiri ní ilẹ̀ Ejibiti láti kọlù wọn, yóò rí ẹ̀jẹ̀ ni òkè ẹnu-ọ̀nà àti ni ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé yín, yóò sì ré ẹnu-ọ̀nà ilé náà kọjá, kì yóò gba apanirun láààyè láti wọ inú ilé e yín láti kọlù yín.
24 Sakzong ih atawk baktih toengah, hae hmuen hae nangmacae hoi na caanawk mah doeh pazui o poe ah.
“Ẹ pa ìlànà yìí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ ó máa ṣe títí ayérayé láàrín yín àti àwọn ìran yín.
25 Angraeng mah lokkam ih baktih toengah, anih mah paek han thuih ih prae thungah na kun o naah, hae tok hae sah o poe ah.
Nígbà tí ẹ̀yin bá de ilẹ̀ tí Olúwa yóò fi fún un yín bí òun ti ṣe ìlérí, ẹ máa kíyèsi àjọ yìí.
26 Na caanawk mah, Hae tok loe tih thuih koehhaih ih maw? tiah na dueng o nahaeloe,
Ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni ohun tí àjọ yìí túmọ̀ sí fún un yín?’
27 nangcae mah nihcae khaeah, Hae loe Angraeng mah Izip kaminawk to hum moe, kaicae ih im loe pathlung, Izip prae ih Israel kaminawk ih im takan taakhaih, Angraeng ih loihhaih poih ah oh, tiah thui pae oh, tiah a naa. To pacoengah kaminawk mah akuep hoiah bok o.
Ẹ sọ fún wọn ni ìgbà náà, ‘Ẹbọ ìrékọjá sí Olúwa ni, ẹni tí ó rékọjá ilé àwọn ọmọ Israẹli ni ìgbà tí ó kọlu àwọn ara Ejibiti. Tí ó si da wa sí nígbà ti ó pa àwọn ara Ejibiti.’” Àwọn ènìyàn sì tẹríba láti sìn.
28 Angraeng mah Mosi hoi Aaron khaeah thuih ih lok baktih toengah, Israel kaminawk mah sak o.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
29 Aqum naah Angraeng mah Izip prae ih caa lu boih, angraeng tangkhang nuiah anghnu, Faro caa lu hoi kamtong thongkrah kami ih caa lu, tapen tangsuek moinawk to dueksak boih.
Ní ọ̀gànjọ́ òru Olúwa kọlu gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, láti orí àkọ́bí. Farao tí ó wà ní orí ìtẹ́ títí dé orí àkọ́bí ẹlẹ́wọ̀n tí ó wà nínú túbú àti àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
30 Faro, anih ih tamnanawk hoi Izip kaminawk loe qum ah angthawk o boih, Izip prae thungah qahhaih to oh; kadueh ai kami im roe maeto doeh om ai.
Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn ara Ejibiti dìde ní ọ̀gànjọ́ òru, igbe ẹkún ńlá sì gba gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, nítorí kò sí ilé kan tí ó yọ sílẹ̀ tí ènìyàn kan kò ti kú.
31 Aqum ah Faro mah Mosi hoi Aaron to kawk, Angthawk hoih! Nangmah hnik hoi Israel kaminawk to angthawk oh loe, kai kaminawk khae hoiah caeh o lai ah! Nang hnik hoi ih baktih toengah, Angraeng to bok oh.
Farao sì ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni ní òru, ó sì wí pé, “Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin àti àwọn ènìyàn Israẹli! Ẹ lọ láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹ ti béèrè.
32 Nangmacae ih tuunawk hoi maitawnawk doeh la oh loe, na thuih o ih baktih toengah caeh oh! Kai doeh tahamhoihaih na paek o toengah, tiah a naa.
Ẹ kó agbo àgùntàn yín àti agbo màlúù yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti sọ, kí ẹ sì máa lọ, kí ẹ sì súre fún mi.”
33 Izip kaminawk mah, Kaicae loe kadueh kami ah ni ka oh o boih boeh, tiah a thuih o pongah, Israel kaminawk to Izip prae thung hoi karangah haek hanah, kaminawk to karangah pahruek o.
Àwọn ara Ejibiti ń rọ àwọn ènìyàn náà láti yára máa lọ kúrò ní ilẹ̀ wọn. Wọ́n wí pé, “Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ gbogbo wa ni yóò kú!”
34 To pongah kaminawk mah taeh thuh ai ih takaw kahaeng to lak o moe, takaw naephaih boengloengnawk doeh kahni hoiah tapawk o pacoengah, palaeng ah aput o.
Àwọn ènìyàn náà sì mú ìyẹ̀fun púpọ̀ kí wọn tó fi ìwúkàrà sí i, wọ́n gbe le èjìká wọn nínú ọpọ́n tí wọ́n ti fi aṣọ dì.
35 Mosi mah thuih ih lok baktih toengah, Israel kaminawk mah sak o; Izip kaminawk khaeah sui, sum kanglungnawk hoi khukbuennawk to a hnik o;
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti sọ fún wọn. Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ ará Ejibiti fún ohun èlò fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ pẹ̀lú.
36 Angraeng mah Izip kaminawk khaeah tahmenhaih palungthin to paek pongah, nihcae mah hnik ih hmuen boih to a paek o. Nihcae mah Izip kaminawk ih hmuen to lak pae o.
Olúwa ti mú kí àwọn ènìyàn yìí rí ojúrere àwọn ará Ejibiti wọ́n sì fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún, wọ́n sì ko ẹrù àwọn ará Ejibiti.
37 Israel kaminawk loe Rameses hoi Sukkoth ah caeh o; to ah caeh kaminawk loe nongpata hoi nawkta thui ai ah, kami sang cumvai tarukto oh o.
Àwọn ọmọ Israẹli sì rìn láti Ramesesi lọ sí Sukkoti. Àwọn ọkùnrin tó ń fi ẹsẹ̀ rìn tó ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ni iye láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
38 Congca kaminawk loe tuunawk, maitawnawk, paroeai pop moinawk hoi nawnto caeh o.
Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn ni ó bá wọ́n lọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn, agbo àgùntàn àti agbo màlúù.
39 Izip prae hoi sin o ih, taeh thuh ai ih takaw to lak o moe, taeh thuh ai ih takaw to hmai paop o; nihcae to Izip prae thung hoi karangah haek o, angmacae caak han mataeng doeh sak patok o pongah, takaw to taeh thuh ai ah a sin o.
Pẹ̀lú ìyẹ̀fun tí kò ní ìwúkàrà nínú tí wọ́n gbé jáde láti Ejibiti wá ni wọ́n fi ṣe àkàrà aláìwú. Ìyẹ̀fun náà kò ni ìwúkàrà nínú nítorí a lé wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wọn kò si rí ààyè láti tọ́jú oúnjẹ fún ara wọn.
40 Israel kaminawk loe Izip prae thungah saning cumvai pali, qui thumto oh o.
Iye ọdún ti àwọn ará Israẹli gbé ní ilẹ̀ Ejibiti jẹ́ irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n.
41 Angraeng ih misatuh kaminawk loe saning cumvai pali, qui thumto boeng na niah, Izip prae thung hoiah tacawt o.
Ó sì ní òpin irinwó ọdún ó le ọgbọ̀n, ní ọjọ́ náà gan an, ni ó sì ṣe tí gbogbo ogun Olúwa jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
42 Aqum ah Izip prae thung hoi caeh haih hanah, Angraeng mah nihcae to toep pongah, to aqum loe Israel caanawk boih mah zah han koi Angraeng ih aqum ah oh.
Nítorí pé, Olúwa ṣe àìsùn ni òru ọjọ́ náà láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní òru yìí ni gbogbo Israẹli ní láti máa ṣe àìsùn láti fi bu ọlá fún Olúwa títí di àwọn ìran tí ń bọ̀.
43 Angraeng mah Mosi hoi Aaron khaeah, Hae loe loihhaih poih sakhaih atawk ah oh; to pongah kawbaktih angvin mah doeh caa thai mak ai.
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Ìwọ̀n yìí ni àwọn òfin fún àjọ ìrékọjá: “Àjèjì kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀.
44 Toe misong ah na qan ih kami loe, tangzat hin aah pacoengah ni, caa tih.
Ẹrú tí ẹ̀yin bá rà lè jẹ́ nínú rẹ̀ lẹ́yìn tí ẹ̀yin bá ti kọ ọ́ ní ilà,
45 Prae kalah kami, toksak han na tlai ih kaminawk loe caa o thai mak ai.
ṣùgbọ́n àtìpó àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
46 Im maeto ah caa oh; moi to im tasa bangah sin o hmah; ahuh doeh angkhaek o sak hmah.
“Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
47 Israel kaminawk boih mah to poih to sah oh.
Gbogbo àjọ Israẹli ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
48 Nangcae thung kaom angvin mah Angraeng loihhaih poih to sak koeh nahaeloe, a imthung takoh ih nongpanawk boih tangzat hin aat o nasoe; to pacoengah ni prae kaminawk baktiah sah o thai tih; tangzat hin aat ai kami loe mi doeh caa thai mak ai.
“Àjèjì ti ó bá ń gbé ní àárín yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ilà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ilà, wọ́n kò ni jẹ nínú rẹ̀.
49 Prae thung tapen kami hoi nangcae salakah kaom prae kalah kami hanah, kanghmong daan maeto patoh oh, tiah a naa.
Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárín yín.”
50 Angraeng mah Mosi hoi Aaron khaeah thuih ih lok baktih toengah, Israel kaminawk boih mah sak o.
Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
51 To na niah Angraeng mah Israel misatuh kaminawk to, Izip prae thung hoiah a caeh haih.
Àti pé ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.

< Exodus 12 >