< Johan 7 >
1 Acunkäna Jesuh Kalile hne da citki, Judahe naw hnim hlü u se Judah hne da am cit hlü.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Jesu ń rìn ní Galili, nítorí tí kò fẹ́ rìn ní Judea, nítorí àwọn Júù ń wá a láti pa.
2 Judahea Sam Pawi cäh law se,
Àjọ àwọn Júù tí í ṣe àjọ àgọ́ súnmọ́ etílé tan.
3 a nae naw, “Na hnukläke naw na pawhmsah ami hmuh vaia, ahin üngkhyüh Judah hnea cita.
Nítorí náà, àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Lọ kúrò níhìn-ín yìí, kí o sì lọ sí Judea, kí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ pẹ̀lú lè fi iṣẹ́ rẹ hàn fún aráyé.
4 “U naw amäta ngminga ngthang vai ngja hlü lü, anghmüa i am pawh khawi u. Hin akcanga na jah pawh üng, khawmdek avan naw ksing se,” ami ti.
Nítorí pé kò sí ẹnikẹ́ni tí í ṣe ohunkóhun níkọ̀kọ̀, tí òun tìkára rẹ̀ sì ń fẹ́ kí a mọ òun ní gbangba. Bí ìwọ bá ń ṣe nǹkan wọ̀nyí, fi ara rẹ hàn fún aráyé.”
5 (Amäta nae hngawh naw pi am jum u.)
Nítorí pé àwọn arákùnrin rẹ̀ pàápàá kò tilẹ̀ gbà á gbọ́.
6 Jesuh naw, “Ka kcün am pha law ham; nangmia kcün cun aläa pha lawki.
Nítorí náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Àkókò gan an fún mi kò tí ì dé; fún ẹ̀yin, gbogbo àkókò ni ó dára fún yín.
7 “Khawmdek naw nangmi am ning jah hneng thei, ami pawhmsah am dawki ka pyena phäh kei na hnengki ni.
Ayé kò lè kórìíra yín; ṣùgbọ́n èmi ni ó kórìíra, nítorí tí mo jẹ́rìí gbé é pé, iṣẹ́ rẹ̀ burú.
8 “Nangmi pawia jeng cit ua, kei ta akcün am a pha law hama phäha tuh pawia am cit hlü ham veng,” a ti.
Ẹ̀yin ẹ gòkè lọ sí àjọ yìí, èmi kì yóò tí ì gòkè lọ sí àjọ yìí; nítorí tí àkókò mi kò ì tí ì dé.”
9 Acun jah mtheh lü, Jesuh Kalile khawa ve hamki.
Nígbà tí ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún wọn tan, ó dúró ní Galili síbẹ̀.
10 A nae pawia ami jeng ceh käna, Jesuh pi khyangea käh ksinga anghmüa heng cit hngaki.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ gòkè lọ tan, nígbà náà ni òun sì gòkè lọ sí àjọ náà pẹ̀lú, kì í ṣe ní gbangba, ṣùgbọ́n bí ẹni pé níkọ̀kọ̀.
11 Judah ngvaie naw pawia sui hü u lü, “Hawia veki ni?” ami ti.
Nígbà náà ni àwọn Júù sì ń wá a kiri nígbà àjọ wí pé, “Níbo ni ó wà?”
12 Khyang he naw Jesuha mawng ampyua sumkyemkie. Akhäk naw, “Ani ta khyang kdaw ni,” ti se, avang naw, “Am daw, khyang jah mhleiki ni,” ami ti.
Ìkùnsínú púpọ̀ sì wà láàrín àwọn ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀, nítorí àwọn kan wí pé, “Ènìyàn rere ní í ṣe.” Àwọn mìíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n òun ń tan ènìyàn jẹ ni.”
13 Acunsepi, Judah ngvaie ami jah kyüha phäh u naw angdanga am pyen u.
Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ ní gbangba nítorí ìbẹ̀rù àwọn Júù.
14 Pawia nghning k’um üng, Jesuh naw Temple k’uma jeng cit lü Pamhnama ngthu jah mtheiki.
Nígbà tí àjọ dé àárín; Jesu gòkè lọ sí tẹmpili ó sì ń kọ́ni.
15 Judah ngvaie naw, “Hin, i pi am ngthei khawiki naw ihawkba kca ksingki ni?” ti u lü, münakie.
Ẹnu sì ya àwọn Júù, wọ́n wí pé, “Ọkùnrin yìí ti ṣe mọ ìwé, nígbà tí kò kọ́ ẹ̀kọ́?”
16 Jesuh naw, “Ka ning jah mtheia ngthu hin kamäta ngaiha ka ning jah mthei am ni. Na tüi lawki Pamhnam üngkhyüh lawkia ngthua kyaki.
Jesu dáhùn, ó sì wí pé, “Ẹ̀kọ́ mi kì í ṣe tèmi, bí kò ṣe ti ẹni tí ó rán mi.
17 “Au pi, ania ngjak hlü biloki naw ka ngthu pyen hin Pamhnama ngthu ja, kamäta ngaiha ka pyena kyaki aw, ti cun ksing khai.
Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ láti ṣe ìfẹ́ rẹ̀ yóò mọ̀ ní ti ẹ̀kọ́ náà, bí ìbá ṣe ti Ọlọ́run, tàbí bí èmi bá sọ ti ara mi.
18 “Amäta mhnüna ngthu pyenki cun amäta dawnak, hlüngtainak vai suiki ni. Acunsepi ani tüih lawkia hlüngtainak vai suiki cun ngsungpyun lü mkhyenak ani üng am ve.
Ẹni tí ń sọ ti ara rẹ̀ ń wá ògo ara rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ń wá ògo ẹni tí ó rán an, òun ni olóòtítọ́, kò sì sí àìṣòdodo nínú rẹ̀.
19 Mosi naw Thum ning jah peki am niki aw? Mat naw pi Thum am nami läki. Ise nami na hnim khaia nami ngtängki ni?” a ti.
Mose kò ha fi òfin fún yín, kò sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó pa òfin náà mọ́? Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá ọ̀nà láti pa mí?”
20 Khyang he naw, “Khawyai naw a ning venak ni; u naw ning hnim hlüki ni,” ti u lü, ami msang.
Ìjọ ènìyàn dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Ìwọ ní ẹ̀mí èṣù, ta ni ń wá ọ̀nà láti pa ọ́?”
21 Jesuh naw, “Müncankse mat ka pawh üng avan nami müncankie.
Jesu dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Kìkì iṣẹ́ àmì kan ni mo ṣe, ẹnu sì ya gbogbo yín.
22 “Ahina phäha ni Mosi naw vun mawih vaia Thum ning jah pe se (Acun cun Mosi üng tüna am kya, nami pupae üngkhyüh tüneikia kpamica üng ami na bilawh khawia kyaki), Sabbath mhnüp üng pi kpamicaa vun nami mawikie.
Síbẹ̀, nítorí pé Mose fi ìkọlà fún yín (kò tilẹ̀ kúkú wá láti ọ̀dọ̀ Mose bí kò ṣe láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá yín); nítorí náà ẹ sì ń kọ ènìyàn ní ilà ní ọjọ́ ìsinmi.
23 “Sabbath üng pi kpamicaa vun mawih uki lü, Mosia Thum lümkankia am a kya üng, kei naw Sabbath mhnüp üng khyang ka mdaw bea phäh ka khana ise am nami jeki ni?
Bí ènìyàn bá ń gba ìkọlà ní ọjọ́ ìsinmi, kí a má ba à rú òfin Mose, ẹ ha ti ṣe ń bínú sí mi, nítorí mo mú ènìyàn kan láradá ní ọjọ́ ìsinmi?
24 “Hmai teng u lü ngthu käh mkhyah ua, ngsungpyun dawkyakia mtai ua,” a ti.
Ẹ má ṣe ìdájọ́ nípa ti ara, ṣùgbọ́n ẹ máa ṣe ìdájọ́ òdodo.”
25 Jerusalem mlüha ka avang naw, “Hin hin Judah ngvaie naw hnim vaia ami büa khyang am niki aw?
Nígbà náà ni àwọn kan nínú àwọn ará Jerusalẹmu wí pé, “Ẹni tí wọ́n ń wá ọ̀nà láti pa kọ́ yìí?
26 “Teng u, khyangea ksunga ngthu pyen se, i pi am ti na be u. Ani hin Mesijah ti lü ngvaie naw akcanga ksing pängki he aw?
Sì wò ó, ó ń sọ̀rọ̀ ní gbangba, wọn kò sì wí nǹkan kan sí i. Àwọn olórí ha mọ̀ nítòótọ́ pé, èyí ni Kristi náà?
27 Mesijah a law üng, u naw pi hawia khyüh a law am ksing. Ani ta a ngtüinak law pi khyang naküt naw mi ksing,” ami ti u.
Ṣùgbọ́n àwa mọ ibi tí ọkùnrin yí gbé ti wá, ṣùgbọ́n nígbà tí Kristi bá dé, kò sí ẹni tí yóò mọ ibi tí ó gbé ti wá.”
28 Acunakyase, Jesuh naw Temple k'uma a jah mthei üng ngpyang lü, “Kei hawia ka, kei u ti nami na ksing kcangkie aw? Kamäta ngjak hlüa ka lawki am ni. Na tüi lawki cun ngthungtak ni, ani am ksing uki.
Nígbà náà ni Jesu kígbe ní tẹmpili bí ó ti ń kọ́ni, wí pé, “Ẹ̀yin mọ̀ mí, ẹ sì mọ ibi tí mo ti wá, èmi kò sì wá fún ara mi, ṣùgbọ́n olóòtítọ́ ni ẹni tí ó rán mi, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀.
29 “Kei naw ani ka ksingki. Isenitiüng, kei cun ani üngka naw ka lawki, ani naw a na tüih law ni,” a ti.
Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ ọ́n, nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ̀ ni mo ti wá, òun ni ó rán mi.”
30 Acunüng Jesuh man vaia ami bü kyaw, akcün am pha hamkia kyase, u naw pi am hnet u.
Nítorí náà wọ́n ń wá ọ̀nà à ti mú un, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e, nítorí tí wákàtí rẹ̀ kò tí ì dé.
31 Khyang avang naw ta jum u lü, “Mesijah a law üng, ania pawhmsaha kthaka daw bawki, müncanksee jah pawhmsah law khai aw” ti u lü amimät ngthäkie.
Ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn sì gbà á gbọ́, wọ́n sì wí pé, “Nígbà tí Kristi náà bá dé, yóò ha ṣe iṣẹ́ àmì jù wọ̀nyí, tí ọkùnrin yìí ti ṣe lọ?”
32 Acukba, khyange cun Jesuha mawng sumkyemkie ti Pharisee naw ami ngjak üng, ktaiyü ngvaie am ngthäh u lü, man khaiea yekape ami jah tüih.
Àwọn Farisi gbọ́ pé, ìjọ ènìyàn ń sọ nǹkan wọ̀nyí lábẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀; àwọn Farisi àti àwọn olórí àlùfáà sì rán àwọn oníṣẹ́ lọ láti mú un.
33 Jesuh naw, “Asängca nami hlawnga ka ve käna, na tüi lawkia veia ka cit be khai.
Nítorí náà Jesu wí fún wọn pé, “Níwọ́n ìgbà díẹ̀ ni èmi yóò wà pẹ̀lú yín, èmi yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó rán mi.
34 “Nangmi naw na sui u lü pi, am na hmu uki; ka venaka pi am law thei uki,” a ti.
Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi, àti ibi tí èmi bá wà, ẹ̀yin kì yóò le wà.”
35 Judah ngvaie amimät sumkyam u lü, “Am mi hmu ti vaia, hin hawia cit hlüki ni? Akce kcea ve hükie Krikea veia cit lü, Krike jah mthei hü hlüki aw’
Nítorí náà ni àwọn Júù ń bá ara wọn sọ pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí yóò gbé lọ tí àwa kì yóò fi rí i? Yóò ha lọ sí àárín àwọn Helleni tí wọ́n fọ́n káàkiri, kí ó sì máa kọ́ àwọn Helleni bí.
36 ‘Nangmi naw na sui u lü, am nami na hmu khai; ka venaka pi am law thei uki’ a ti hin, i a ti hlünak ni,” ami ti.
Ọ̀rọ̀ kín ni èyí tí ó sọ yìí, ‘Ẹ̀yin yóò wá mi, ẹ kì yóò sì rí mi,’ àti ‘Ibi tí èmi bá wà ẹ̀yin kì yóò le wà’?”
37 Pawia akpäihnak ja akkü säihkia mhnüp üng, Jesuh ngdüiki naw, ngpyang lü, “Au pi, tui xaiki ka veia law lü aw law se.
Lọ́jọ́ tó kẹ́yìn, tí í ṣe ọjọ́ ńlá àjọ, Jesu dúró, ó sì kígbe wí pé, “Bí òǹgbẹ bá ń gbẹ ẹnikẹ́ni, kí ó tọ̀ mí wá, kí ó sì mu.
38 “Au pi, kei na jumki cun Pamhnama cangcim üng a vea mäiha xünnak Tui Lawng cun ani üngkhyüh lawng law khai,” a ti.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí gbọ́ gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ti wí, láti inú rẹ̀ ni odò omi ìyè yóò ti máa sàn jáde wá.”
39 Jumeikie naw Ngmüimkhya ami yahnak vaia mawng a pyenaka kyaki. Jesuh cun hlüngtainak üng am tho be hamkia kyase, Ngmüimkhya cun jah peta am kya ham.
Ṣùgbọ́n ó sọ èyí ní ti ẹ̀mí, tí àwọn tí ó gbà á gbọ́ ń bọ̀ wá gbà, nítorí a kò tí ì fi Èmí Mímọ́ fún ni; nítorí tí a kò tí ì ṣe Jesu lógo.
40 Khyang avang naw a pyen ngja u lü, “Hin hin Sahma kcanga kya ve,” ami ti.
Nítorí náà, nígbà tí ọ̀pọ̀ nínú ìjọ ènìyàn gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n wí pé, “Lóòótọ́ èyí ni wòlíì náà.”
41 Avang naw, “Ani hin Mesijah ni,” ami ti. Avange naw pi, “Kalile khaw üngka naw Mesijah hmi law thei khai aw?
Àwọn mìíràn wí pé, “Èyí ni Kristi náà.” Ṣùgbọ́n àwọn kan wí pé kínla, “Kristi yóò ha ti Galili wá bí?
42 Mesijah cun Sangpuxang Davita ksawn üngka, Davita venaka mlüh Bethlehem üng hmi law khai ti lü cangcim üng veki” ami ti.
Ìwé mímọ́ kò ha wí pé, Kristi yóò ti inú irú-ọmọ Dafidi wá, àti Bẹtilẹhẹmu, ìlú tí Dafidi ti wá?”
43 Acukba Jesuha phäha khyange ngtaikie.
Bẹ́ẹ̀ ni ìyapa wà láàrín ìjọ ènìyàn nítorí rẹ̀.
44 Avange naw ta man vai ami jum, acunsepi u naw pi am hnet dat u.
Àwọn mìíràn nínú wọn sì fẹ́ láti mú un; ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbé ọwọ́ lé e.
45 Yekape ami ceh be üng, ktaiyü ngvaie ja Pharisee naw “Ise am nami lawpüi ni?” ti u se,
Ní ìparí, àwọn ẹ̀ṣọ́ tẹmpili padà tọ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisi lọ, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi mú un wá?”
46 yekape naw, “Ania mäiha u naw ngthu am pyen khawi” ti lü ami jah msang be.
Àwọn ẹ̀ṣọ́ dáhùn wí pé, “Kò sí ẹni tí ó tí ì sọ̀rọ̀ bí ọkùnrin yìí rí!”
47 Pharisee naw, “Nangmi pi a ning jah nghmawngmhlei hnga aw?
Nítorí náà àwọn Farisi dá wọn lóhùn pé, “A ha tan ẹ̀yin jẹ pẹ̀lú bí?
48 “Ngvaie ja Pharisee üngka ani jumki nami ksing khawiki aw?
Ǹjẹ́ nínú àwọn ìjòyè, tàbí àwọn Farisi ti gbà á gbọ́ bí?
49 “Mosia Thum am ksingkia khyange ta yüncenak khamei ve u,” ti lü, ami pyen.
Ṣùgbọ́n ìjọ ènìyàn yìí, tí ko mọ òfin di ẹni ìfibú.”
50 Ahlana mthana Jesuha veia lawkia Pharise üngka khyang mat Nikawdim naw,
Nikodemu ẹni tí ó tọ Jesu wá lóru rí, tí ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú wọn sì sọ fún wọn pé,
51 “Amäta mpyawng ye üng a ngthu am ngja kaa, a pawhmsah am hmu kaa, mi Thum üng khyang am mi cijang khawi,” a ti.
“Òfin wa ha ń ṣe ìdájọ́ ènìyàn kí ó tó gbọ́ ti ẹnu rẹ̀ àti kí ó tó mọ ohun tí ó ṣe bí?”
52 Amimi naw, “Nang pi Kalile khyanga na kya hngaki aw? Cangcim üng tenga, Kalile khaw üng sahma, u am hmi law khawi,” ti lü na hmu khai.
Wọ́n dáhùn wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ pẹ̀lú wá láti Galili bí? Wá kiri, kí o sì wò nítorí kò sí wòlíì kan tí ó ti Galili dìde.”
Wọ́n sì lọ olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.