< Hosea 5 >
1 Patalinghugi kini, Oh kamo nga mga sacerdote, ug pamatia, Oh balay sa Israel, ug paminawa, Oh balay sa hari; kay ang paghukom nahitungod kaninyo; kay kamo nahimong lit-ag sa Mizpa, ug pukot nga gibuklad sa Tabor.
“Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà! Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli! Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba! Ìdájọ́ yìí kàn yín. Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori.
2 Ug ang manggugubot nanghiunlod sa kinahiladman tungod sa pagpatay; apan sila nga tanan pagabadlongon ko.
Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
3 Ako nakaila kang Ephraim, ug ang Israel, wala matago kanako; kay karon, Oh Ephraim, ikaw nakighilawas, ang Israel nahugawan.
mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu Israẹli kò sì pamọ́ fún mi Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè Israẹli sì ti díbàjẹ́.
4 Ang ilang mga binuhatan dili makatugot kanila sa pagbalik ngadto sa ilang Dios; kay ang espiritu sa pagpakighilawas anaa sa sulod nila, ug sila wala makaila kang Jehova.
“Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn. Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn, wọn kò sì mọ Olúwa.
5 Ug ang pagpagarbo sa Israel nagapamatuod sa iyang atubangan; busa ang Israel ug ang Ephraim manghisukamod sa ilang kasal-anan; ang Juda usab mahasukamod uban kanila.
Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn; àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
6 Sila mangadto uban sa ilang mga panon ug sa ilang kahayupan aron sa pagpangita kang Jehova; apan siya dili nila hikaplagan: siya mipahawa sa iyang kaugalingon gikan kanila.
Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa, wọn kò ní rí i, ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
7 Sila nagamaluibon batok kang Jehova; kay sila nanganak ug mga anak sa gawas: karon pagalamyon sila sa bag-ong bulan uban sa ilang kaumahan.
Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ. Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn, ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
8 Patingoga ninyo ang corneta sa Gabaa, ug ang trompeta sa Rama: patingoga ang pagpagubok diha sa Beth-aven; sa imong luyo, Oh Benjamin.
“Fọn fèrè ní Gibeah, kí ẹ sì fun ìpè ní Rama. Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni; máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
9 Ang Ephraim mahimong kamingawan sa adlaw sa pagbadlong: sa mga banay sa Israel akong gipahibalo kadtong mahitabo sa pagkatinuod gayud.
Efraimu yóò di ahoro ní ọjọ́ ìbáwí láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli, Mo sọ ohun tí ó dájú.
10 Ang mga principe sa Juda mahasma kanila nga nag-irog sa mohon sa yuta: akong igabubo ang akong kaligutgut kanila maingon sa tubig.
Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í máa yí òkúta ààlà kúrò. Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí bí ìkún omi.
11 Ang Ephraim gipiutan sa mga principe, siya nadugmok sa paghukom; kay siya nahimuot nga magasunod sa sugo sa tawo.
A ni Efraimu lára, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́, nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà.
12 Busa alang sa Ephraim ako nahimong usa ka tangkob, ug sa balay sa Juda maingon nga usa ka pagkadunot.
Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu, Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
13 Sa pagkakita sa Ephraim sa iyang sakit, ug sa pagkakita sa Juda sa iyang samad, unya miadto ang Ephraim sa Asiria, ug nagpadala ngadto sa hari nga si Jareb: apan siya dili makahimo pagpaalim kaninyo, ni sa pag-ayo sa inyong samad.
“Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀, tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀ ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ, ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́. Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná.
14 Kay alang sa Ephraim ako mahimo nga daw usa ka leon, ug maingon sa batan-ong leon alang sa balay sa Juda: ako, bisan ako, mokunis-kunis ug mopahawa; ako mobihag, ug walay bisan kinsa nga makaluwas.
Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu, bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda. Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ; Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
15 Ako moadto ug mobalik sa akong dapit, hangtud nga ilang igasugid ang ilang paglapas, ug mangita sa akong nawong: sa ilang kasakit ilang pagapangitaon ako sa masingkamoton gayud.
Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi wọn yóò sì wá ojú mi nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”