< Откровение 1 >
1 Откровението от Исуса Христа, което Му даде Бог, за да покаже на слугите Си онова, което има да стане скоро; а Христос прати та го яви чрез ангела Си на Своя слуга Иоан,
Ìfihàn ti Jesu Kristi, tí Ọlọ́run fi fún un, láti fihàn fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ohun tí kò le ṣàìṣẹ ní lọ́ọ́lọ́ọ́; ó sì ránṣẹ́, ó sì fi í hàn láti ọwọ́ angẹli rẹ̀ wá fún Johanu, ìránṣẹ́ rẹ̀,
2 който възвести Божието слово и свидетелството Исус Христово
ẹni tí ó jẹ́rìí ohun gbogbo tí ó rí, èyí ì ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti ẹ̀rí ti Jesu Kristi.
3 Блажен, който прочита, и ония, които слушат думите на това пророчество и пазят написаното в него; защото времето е близу.
Ẹni ìbùkún ni ẹni tí ń kà, àti àwọn tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, tí ó sì ń pa nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a kọ sínú rẹ̀ mọ́, nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀.
4 Иоан до седемте църкви, които са в Азия: Благодат и мир да бъде на вас от Онзи, Който е, и Който е бил, и Който иде, и от седемте духове, които са пред неговия престол,
Johanu, Sí àwọn ìjọ méje tí ń bẹ ní Asia: Oore-ọ̀fẹ́ fún yín, àti àlàáfíà, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ń bẹ, tí ó sì ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá; àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹ̀mí méje tí ń bẹ níwájú ìtẹ́ rẹ̀;
5 и от Исуса Христа, който е верният свидетел, първороденият от мъртвите и началникът на земните царе. На Този, Който ни люби, и ни е развързал от греховете ни чрез кръвта Си,
àti láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, ẹlẹ́rìí olóòtítọ́, àkọ́bí nínú àwọn òkú, àti aláṣẹ àwọn ọba ayé. Ẹni tí ó fẹ́ wa, ẹni tí ó gbà wá kúrò lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wa nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀,
6 и Който ни е направил Царство от свещеници на своя Бог и Отец, на Него да бъде слава и господство във вечни векове. Амин. (aiōn )
tí ó sì ti fi wá jẹ ọba àti àlùfáà láti sin Ọlọ́run àti Baba rẹ; tirẹ̀ ni ògo àti ìjọba láé àti láéláé. Àmín. (aiōn )
7 Ето, иде с облаците; и ще Го види всяко око, и ония, които го прободоха; и всички земни племена ще възридаят за Него. Така е. Амин.
“Kíyèsi i, o ń bọ̀ nínú àwọsánmọ̀, gbogbo ojú ni yóò sì rí i, àti àwọn tí ó gún un ní ọ̀kọ̀ pẹ̀lú”; àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni “yóò sì máa pohùnréré ẹkún nítorí rẹ̀.”
8 Аз съм Алфа и Омега, казва Господ Бог, Който е, и Който е бил, и Който иде, Всемогъщият.
“Èmi ni Alfa àti Omega,” ni Olúwa Ọlọ́run wí, “ẹni tí ó ń bẹ, tí ó ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá, alágbára.”
9 Аз Иоан, ваш брат и съучастник в неволите и в царството и в търпението, които са чрез Исуса [Христа], бях на острова, наречен Патмос, за Божието слово и свидетелството за Исуса [Христа].
Èmi, Johanu, arákùnrin yín àti alábápín pẹ̀lú yín nínú wàhálà àti ìjọba àti sùúrù tí ń bẹ nínú Jesu, wà ní erékúṣù tí a ń pè ní Patmo, nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí Jesu Kristi.
10 В Господния ден бях в изстъпление чрез Духа; и чух зад себе си силен глас като от тръба, който казваше:
Mo wà nínú Ẹ̀mí ní ọjọ́ Olúwa, mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan lẹ́yìn mi, bí ìró ìpè,
11 Каквото виждаш напиши на книга, и прати го до седемте църкви: до Ефес, до Смирна, до Пергам, до Тиатир, до Сардис, до Филаделфия и до Лаодикия.
Ó ń wí pé, “Kọ́ ìwé rẹ̀, ohun tí ìwọ rí, kí ó sí fi ránṣẹ́ sí àwọn ìjọ méje; sí Efesu, àti sí Smirna, àti sí Pargamu, àti sí Tiatira, àti sí Sardi, àti sí Filadelfia, àti sí Laodikea.”
12 И обърнах се да видя Този (Гръцки: Гласът. ), Който ми проговори; и като се обърнах, видях седем златни светилника;
Mo sì yí padà láti wo ohùn tí ń bá mi sọ̀rọ̀. Nígbà tí mo yípadà, mo rí ọ̀pá fìtílà wúrà méje,
13 и всред светилниците видях Един, Който приличаше на Човешкия Син, облечен в дълга дреха и препасан около гърдите си със златен пояс;
àti láàrín àwọn ọ̀pá fìtílà náà, ẹnìkan tí ó dàbí “ọmọ ènìyàn,” tí a wọ̀ ní aṣọ tí ó kanlẹ̀ dé ẹsẹ̀, tí a sì fi àmùrè wúrà dì ní ẹ̀gbẹ́.
14 а главата и косата Му бяха бели като бяла вълна, като сняг, и очите Му, като огнен пламък;
Orí rẹ̀ àti irun rẹ̀ funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú, ó funfun bí yìnyín; ojú rẹ̀ sì dàbí, ọwọ́ iná.
15 и нозете Му приличаха на лъскава мед, като в пещ пречистена: а гласът Му беше като на много води;
Ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára, bí ẹni pé a dà á nínú ìléru; ohùn rẹ̀ sì dàbí ìró omi púpọ̀.
16 и имаше в десницата Си седем звезди; и от устата му излизаше меч остър и от двете страни; и лицето Му светеше, както свети слънцето в силата си.
Ó sì ní ìràwọ̀ méje ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; àti láti ẹnu rẹ̀ wá ni idà olójú méjì mímú ti jáde. Ojú rẹ̀ sì dàbí oòrùn tí ó ń fi agbára rẹ̀ hàn.
17 И когато Го видях, паднах при нозете Му като мъртъв; а Той тури десницата Си върху мене и каза: Не бой се, Аз съм първият и последният и живият;
Nígbà tí mo rí i, mo wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ bí ẹni tí ó kú. Ó sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ lé mi, ó ń wí fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn.
18 бях мъртъв, и, ето, живея до вечни векове; и имам ключовете на смъртта и на ада. (aiōn , Hadēs )
Èmi ni ẹni tí ó ń bẹ láààyè, tí ó sì ti kú; sì kíyèsi i, èmi sì ń bẹ láààyè sí i títí láé! Mo sì ní kọ́kọ́rọ́ ikú àti ti ipò òkú lọ́wọ́. (aiōn , Hadēs )
19 Напиши, прочее, това, което си видял, и що значи, и това, което има да стане подире,
“Kọ̀wé nítorí náà ohun tí ìwọ ti rí, àti ti ohun tí ń bẹ, àti ti ohun tí yóò hù lẹ́yìn èyí;
20 тайната на седемте звезди, които видя в десницата Ми, и седемте златни светилника. Седемте звезди са ангелите на седемте църкви; и седемте светилника са седемте църкви.
ohun ìjìnlẹ̀ tí ìràwọ̀ méje náà tí ìwọ rí ní ọwọ́ ọ̀tún mi, àti ọ̀pá wúrà fìtílà méje náà. Ìràwọ̀ méje ni àwọn angẹli ìjọ méje náà: àti ọ̀pá fìtílà méje náà ní àwọn ìjọ méje.