< Псалми 73 >
1 Асафов псалом. Благ е наистина Бог към Израиля, Към чистосърдечните.
Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
2 А колкото за мене, нозете ми почти се отклониха. Без малко бяха се подхлъзнали стъпките ми.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
3 Защото завидях на надменните, Като гледах благоденствието на нечестивите.
Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
4 Понеже не се притесняват при умирането си, Но тялото им е тлъсто.
Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
5 Не са в общите човешки трудове Нито са измъчвани, като другите човеци.
Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
6 Затова гордостта като верижка окръжава шията им, Насилието ги облича като дреха.
Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
7 Очите им изпъкват от тлъстина; Мечтанията на сърцето им се превишават.
Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
8 Присмиват се и говорят нечестиво за насилие: Говорят горделиво,
Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
9 Издигат устата си до небето, И езикът им обхожда земята.
Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
10 Затова отбиват се при тях людете му; И вода с пълна чаша се изпива от тях.
Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
11 И казват: От где знае Бог? И: Има ли знание у Всевишния?
Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
12 Ето, такива са нечестивите! винаги са благополучни! Умножават богатство!
Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
13 Наистина аз съм напразно очистил сърцето си, И съм измил в невинност ръцете си,
Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
14 Тъй като съм измъчван цял ден, И наказван всяка заран.
Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
15 Ако речех да говоря така, Ето, изневерил бих на поколението на чадата Ти;
Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
16 И мислех как да разбера това, Но ми се виждаше много мъчно,
Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
17 До като влязох в Божието светилище И размишлявах върху сетнината им.
títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
18 Ти наистина си ги турил на плъзгави места, Тръшнал си ги на разорение.
Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
19 Как изведнъж стигат в запустение! Съвършено се довършват от ужаси.
Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
20 Както се презира съновидение, когато се събуди някой, Така и Ти, Господи, когато се събудиш, ще презреш образа им,
Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
21 Но тогава моето сърце кипеше. И чреслата ми се измъчваха.
Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
22 До толкова бях обезумял и не разбирах! Бях като скот пред Тебе.
mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
23 Обаче аз винаги съм с Тебе, Ти ме хвана за дясната ми ръка.
Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
24 Чрез съвета Си ще ме водиш, И подир това ще ме приемеш в слава.
Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
25 Кого имам на небето освен Тебе? И на земята не желая другиго освен Тебе.
Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
26 Чезне плътта ми и сърцето ми; Но Бог е сила на сърцето ми и вечния ми дял.
Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
27 Защото, ето, тия, които се отдалечават от Тебе ще погинат; Ти изтребваш всички, които като блудници Те оставят.
Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
28 Но за мене е добре да се приближа при Бога; Тебе, Господи Иеова, направих прибежището си, За да възгласявам всичките Твои дела.
Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.