< Псалми 49 >
1 За първият певец, псалом на Кореевите синове. Слушайте това, всички племена; Внимавайте всички жители на вселената,
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ gbọ́ èyí, gbogbo ènìyàn! Ẹ fi etí sí i, gbogbo ẹ̀yin aráyé.
2 И ниско поставени и високопоставени, Богати и сиромаси заедно.
Àti ẹni tí ó ga àti ẹni tí ó kéré tálákà àti ọlọ́lá pẹ̀lú!
3 Устата ми ще говорят мъдрост, И размишлението на сърцето ми ще бъде за разумни неща;
Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, èrò láti ọkàn mi yóò mú òye wá
4 Ще поведа към притча ухото си, Ще изложа на арфа гатанката си.
èmi yóò dẹ etí mi sílẹ̀ sí òwe, èmi yóò ṣí ọ̀rọ̀ ìkọ̀kọ̀ mi sílẹ̀ lójú okùn dùùrù.
5 Защо да се боя във време на бедствие, Когато ме обкръжи беззаконието до петите?
Èéṣe ti èmi yóò bẹ̀rù nígbà tí ọjọ́ ibi dé? Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ajinnilẹ́sẹ̀ mi yí mi ká,
6 От ония, които уповават на имота си, И се хвалят с голямото си богатство,
àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn, tí wọn sì ń ṣe ìlérí ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ wọn.
7 Ни един от тях не може никак да изкупи брата си, Нито да даде Богу откуп за него.
Kò sí ọkùnrin tí ó lè ra ẹ̀mí ẹnìkejì rẹ̀ padà tàbí san owó ìràpadà fún Ọlọ́run.
8 (Защото толкова скъп е откупът на душата им, Щото всеки трябва да се оставя от това за винаги),
Nítorí ìràpadà fún ẹni jẹ́ iyebíye kò sì sí iye owó tó tó fún sísan rẹ̀,
9 Та да живее вечно И да не види изтление.
ní ti kí ó máa wà títí ayé láìrí isà òkú.
10 Защото гледа, бе мъдрите умират, И еднакво с тях погиват безумният и несмисленият, И оставят богатството си на други.
Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rí ọkùnrin ọlọ́gbọ́n tí ó kú, bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n pẹ̀lú ṣègbé wọ́n sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.
11 Тайната им мисъл е, че домовете им ще траят вечно, И жилищата им из род в род; Наричат земите си със своите си имена.
Ibojì wọn ni yóò jẹ́ ilé wọn láéláé, ibùgbé wọn láti ìrandíran, wọn sọ orúkọ ilẹ̀ wọn ní orúkọ ara wọn.
12 Но човекът не пребъдва в чест; Прилича на животните, които загиват.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí o wà nínú ọlá kò dúró pẹ́ ó sì dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
13 Това е пътят на безумните; Но пак идещите подир тях човеци одобряват думите им. (Села)
Èyí ni òtítọ́ àwọn ènìyàn tí ó gbàgbọ́ nínú ara wọn, àti àwọn tí ń tẹ̀lé wọn, tí ó gba ọ̀rọ̀ wọn. (Sela)
14 Назначават се като овци за преизподнята; Смъртта ще им бъде овчар; И праведните ще ги обладаят призори; И красотата им ще овехтее, Като остава преизподнята жилище на всеки един от тях. (Sheol )
Gẹ́gẹ́ bí àgùntàn ni a tẹ́ wọn sínú isà òkú ikú yóò jẹun lórí wọn; ẹni tí ó dúró ṣinṣin ni yóò, jẹ ọba lórí wọn ní òwúrọ̀. Ẹwà wọn yóò díbàjẹ́, isà òkú ni ibùgbé ẹwà wọn. (Sheol )
15 Но Бог ще изкупи душата ми от силата на преизподнята. Защото ще ме приеме. (Села) (Sheol )
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ra ọkàn mi padà kúrò nínú isà òkú, yóò gbé mi lọ sọ́dọ̀ òun fún rara rẹ̀. (Sheol )
16 Не бой се, когато забогатее човек, Когато се умножи славата на дома му;
Má ṣe bẹ̀rù nígbà tí ẹnìkan bá di ọlọ́rọ̀. Nígbà tí ìyìn ilé rẹ̀ ń pọ̀ sí i.
17 Защото, когато умре няма да вземе със себе си нищо, Нито ще мине славата му на друг подир него,
Nítorí kì yóò mú ohun kan lọ nígbà tí ó bá kú, ògo rẹ̀ kò ní bá a sọ̀kalẹ̀ sí ipò òkú.
18 Ако и да е облажавал душата си приживе, И човеците да те хвалят, когато правиш добро на себе си.
Nígbà tí ó wà láyé, ó súre fún ọkàn ara rẹ̀. Àwọn ènìyàn yìn ọ́ nígbà tí ìwọ ṣe rere.
19 Пак ще дойда при рода на бащите си. които никога няма да видят виделина.
Òun yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ìran àwọn baba rẹ̀ àwọn tí ki yóò ri ìmọ́lẹ̀ ayé.
20 Човек, който е на почит, а не разбира, Прилича на животните, които загиват.
Ọkùnrin tí ó ní ọlá tí kò ní òye dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.