< Псалми 36 >
1 За първия певец. Псалом на Господния слуга Давида. Беззаконието на нечестивия свидетелствува на вътрешното ми сърце, Че чрез очите ми няма страх от Бога.
Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ Olúwa. Ìré-òfin-kọjá ènìyàn búburú jẹ́ kí n mọ̀ nínú ọkàn mi pé, ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí níwájú wọn.
2 Защото той се лъже в своите очи. Че беззаконието му няма да се открие и да се намрази,
Nítorí pé wọ́n pọ́n ara wọn ní ojú ara wọn títí tí a kò fi le rí ẹ̀ṣẹ̀ wọn láti kórìíra.
3 Думите на устата му са беззаконие и измама; Той не иска да бъде разумен за да прави добро.
Ọ̀rọ̀ ẹnu wọn ni ẹ̀ṣẹ̀ òhun ẹ̀tàn; wọ́n ti fi ọgbọ́n àti ṣíṣe rere sílẹ̀.
4 Беззаконие измислюва на леглото си; Застава на недобър път; злото не мрази.
Wọ́n gbìmọ̀ ìwà ìkà nígbà tí wọ́n wà lórí ibùsùn wọn: wọ́n gba ọ̀nà tí kò dára wọn kò sì kọ ọ̀nà ibi sílẹ̀.
5 Господи, Твоето милосърдие стига до небето, Верността Ти до облаците;
Ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ, ìwọ Olúwa, ó ga dé ọ̀run, òtítọ́ ọ̀ rẹ ga dé àwọsánmọ̀.
6 Правдата Ти е като великолепните планини; Съдбите Ти са бездна голяма; Ти, Господи, запазваш човеци и животни.
Òdodo rẹ dàbí àwọn òkè Ọlọ́run, àwọn ìdájọ́ rẹ dàbí ibú ńlá; ìwọ gba ẹranko àti ènìyàn là, Olúwa.
7 Колко е скъпоценно Твоето милосърдие, Боже! Затова човешките чада прибягват под покрива на крилата Ти.
Báwo ni ìṣeun ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ ti tó! Ọlọ́run! Kí gbogbo ọmọ ènìyàn le sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ.
8 Ще се напояват от най-доброто на дома Ти. И от ръката на Твоите сладости ще им дадеш да пият.
Àsè ilé rẹ yóò tẹ́ wọn lọ́rùn gidigidi; ìwọ yóò sì mú wọn mu nínú odò inú dídùn rẹ.
9 Защото у Тебе е изворът на живота, В Твоята светлина ще видим светлина.
Nítorí pé pẹ̀lú rẹ ni orísun ìyè wà: nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ ni àwa yóò rí ìmọ́lẹ̀.
10 Простирай милосърдието Си към ония, които Те познават, И правдата Си към ония, които са с право сърце.
Mú ìṣeun ìfẹ́ ẹ̀ rẹ sí àwọn tí ó mọ̀ ọ́n àti ìgbàlà rẹ sí àwọn tí ó ní ìdúró ṣinṣin ọkàn!
11 Нека не дойде против мене ногата на горделивите, Нито ръката на нечестивите да ме поклати.
Má ṣe jẹ́ kí ẹsẹ̀ agbéraga kí ó wá sí orí mi, kí o má sì jẹ́ kí ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú sí mi ní ipò.
12 Там паднаха ония, които вършат беззаконие; Повалиха си и не ще могат да станат.
Níbẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ gbé ṣubú sí: a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn kì yóò le è dìde!