< Псалми 27 >
1 Давидов псалом. Господ е светлина моя и избавител мой; От кого ще се боя? Господ е сила на живота ми; От кого ще се уплаша?
Ti Dafidi. Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi; ta ni èmi yóò bẹ̀rù? Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi, ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?
2 Когато се приближиха при мене злосторници, Противниците ми и неприятелите ми, За да изядат плътта ми, Те се спънаха и паднаха.
Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi láti jẹ ẹran-ara mi, àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi, wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
3 Ако се опълчи против мене и войска, Сърцето ми няма да се уплаши; Ако се подигне против мене война И тогава ще имам увереност.
Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi, ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù; bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi, nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
4 Едно нещо съм поискал от Господа, това ще търся, - Да живея в дома Господен през всичките дни на живота си. За да гледам привлекателността на Господа. И да Го диря в храма Му.
Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òhun ni èmi yóò máa wá kiri: kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa ní ọjọ́ ayé mi gbogbo, kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa, kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
5 Защото в зъл ден ще ме скрие под покрива Си, Ще ме покрие в скривалището на щита Си, Ще ме издигне на канара.
Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀; níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́; yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
6 И сега главата ми ще се издигне Над неприятелите ми, които ме окръжават; И ще принеса в скинията Му жертва на възклицания, Ще пея, да! ще славословя Господа.
Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká; èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀; èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.
7 Слушай, Господи, гласа ми, когато викам; Смили се тоже за мене, и отговори ми.
Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Olúwa, ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn,
8 Когато Ти рече: Търсете лицето Ми, Моето сърце Ти каза: Лицето Ти ще търся, Господи.
Ọkàn mi wí pé, “Wá ojú u rẹ̀!” Ojú rẹ, Olúwa, ni ti èmí ń wá.
9 Да не скриеш от мене лицето Си; Да не отхвърлиш с гняв слугата Си; Ти ми стана помощ; недей ме отхвърля, И недей ме оставя, Боже, Спасителю мой;
Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi, má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì; ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi, Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí, háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
10 Защото баща ми и майка ми са ме оставили: Господ, обаче, ще ме прибере.
Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
11 Научи ме, Господи, пътя Си, И води ме по равна пътека поради ония, които ме причакват.
Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú nítorí àwọn ọ̀tá mi.
12 Да не ме предадеш на волята на противниците ми; Защото лъжливи свидетели са се дигнали против мене, Които дишат насилие.
Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́, nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi, wọ́n sì mí ìmí ìkà.
13 Ако не бях повярвал, че ще видя благостите Господни В земята на живите - бих премалял.
Èmi ní ìgbàgbọ́ pé, èmi yóò rí ìre Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
14 Чакай Господа; Дерзай, и нека се укрепи сърцето ти; Да! чакай Господа.
Dúró de Olúwa; kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le àní dúró de Olúwa.