< Псалми 132 >
1 Песен на възкачванията. Помни, Господи, заради Давида, Всичките му скърби,
Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
2 Как се кле на Господа, И се обрече на Силния Яковов, като каза:
Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
3 Непременно няма да вляза в шатъра на къщата си, Нито ще се кача на постланото си легло,
Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
4 Няма да дам сън на очите си, Или дрямка на клепачите си,
Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
5 Докато не намеря място за Господа, Обиталище за Силния Яковов.
títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
6 Ето, ние чухме, че той бил в Ефрата; Намерихме го в полетата на Яара.
Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
7 Нека влезем в скинията Му, Нека се поклоним при подножието Му.
Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
8 Стани, Господи, и влез в покоя Си. Ти и ковчега на Твоята сила;
Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
9 Свещениците Ти да бъдат облечени с правда, И светиите Ти нека викат радостно.
Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
10 Заради слугата Си Давида Недей отблъсква лицето на помазаника Си.
Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
11 Господ се кле с вярност на Давида, - И няма да пристъпи думата Си, - Казвайки: От рожбата на тялото ти Ще сложа на престола ти.
Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
12 Ако чадата ти опазят Моя завет И Моите свидетелства, на които ще ги науча, То и техните чада ще седят за винаги на престола ти.
Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
13 Защото Господ избра Сиона, Благоволи да обитава в него.
Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
14 Това, каза Той, Ми е покой до века: Тук ще обитавам, защото го пожелах.
Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
15 Ще благоволя изобилно храната му! Сиромасите му ще наситя с хляб.
Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
16 Ще облека и свещениците му със спасение; И светиите му ще възклицават от радост.
Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
17 Там ще направя да изникне рог от Давида; Приготвих светилник за помазаника Си.
Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
18 Неприятелят му ще облека със срам; А на него ще блещи короната.
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.