< Псалми 106 >

1 Алилуя. Славете Господа, защото е благ. Защото неговата милост трае до века.
Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
2 Кой може да изкаже мощните дела на Господа, Или да разгласи всичките Негови хвали?
Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
3 Блажени ония, които пазят правосъдие; Блажен оня, който върши правда на всяко време.
Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
4 Помни ме, Господи, с благоволението, което питаеш към Людете Си; Посети ме със спасението Си;
Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
5 За да видя благоденствието на Твоите избрани, За да се радвам във веселието на народа Ти, За да се хваля заедно с Твоето наследство.
kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
6 Съгрешихме ние и бащите ни, Беззаконие и нечестие сторихме.
Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
7 Бащите ни не разсъждаваха за Твоите чудесни дела в Египет, Не си спомняха многото Твои милости, Но се възпротивиха при морето, при Червеното море.
Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
8 При все това Бог ги избави заради името Си, За да направи познато могъществото Си.
Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
9 Смъмра Червеното море, и то изсъхна; И така ги преведе през дълбочините като през пасбище,
O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
10 И ги спаси от ръката на ненавистника им, И ги изкупи от ръката на неприятеля.
O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
11 Водите покриха противниците им; Не остана ни един от тях.
Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
12 Тогава повярваха думите Му, Пееха хвалата Му.
Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
13 Но скоро забравиха делата Му, Не чакаха изпълнението на намерението Му,
Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
14 Но се полакомиха твърде много в пустинята, И изпитаха Бога в безводната страна;
Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
15 И Той им даде това, което искаха; Прати, обаче, мършавост на душите им.
Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
16 Също и на Моисея те завидяха в стана. И на Господния светия Аарон.
Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
17 Земята се затвори та погълна Датана, И покри Авироновата дружина;
Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
18 И огън се запали в дружината им; Пламък изгори нечестивите.
Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
19 Те направиха теле в Хорив, И поклониха се на излеян идол;
Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
20 Така размениха Славата си Срещу подобие на вол, който яде трева!
Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
21 Забравиха своя избавител Бог, Който беше извършил велики дела в Египет,
Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
22 Чудесни дела в Хамовата земя, Страшни неща около Червеното море.
iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
23 Затова Той каза, че ще ги изтреби; Само че избраният му Моисей застана пред Него в пролома За да отвърне гнева Му, да не би да ги погуби.
Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
24 Дори те презряха желаната земя, Не повярваха Неговото слово,
Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
25 А пороптаха в шатрите си, И не послушаха гласа на Господа.
Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
26 Затова Той им се закле, Че ще ги повали в пустинята,
Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
27 И че ще повали потомството им между народите, И ще ги разпръсне по разни страни,
láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
28 Тоже те се прилепиха към Ваалфегора, И ядоха жертви принесени на мъртви богове.
Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
29 И тъй, предизвикаха Бога с делата си До толкова щото язвата направи пролом между тях.
wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
30 Но стана Финеес и извърши посредничество, Та язвата престана;
Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
31 И това му се вмени за правда Из род в род до века.
A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
32 Също и при водите на Мерива те Го разгневиха, Така щото стана зле с Моисея поради тях;
Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
33 Защото се възбунтуваха против Духа Му, Та Моисей говори несмислено с устните си.
Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
34 При това, те не изтребиха племената Според както Господ им бе заповядал,
Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
35 Но се смесиха с тия народи, И се научиха на техните дела;
Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
36 Тъй щото служиха на идолите им, Които станаха примка за тях.
Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
37 Да! Синовете и дъщерите си Принесоха в жертва на бесовете,
Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
38 И проляха невинна кръв, кръвта на синовете си и на дъщерите си, Които пожертвуваха на ханаанските идоли; И земята се оскверни от кръвопролития.
Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
39 Така те се оскверниха от делата си, И блудствуваха в деянията си.
Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
40 Затова гневът на Господа пламна против людете Му И Той се погнуси от наследството Си.
Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
41 Предаде ги в ръцете на народите; И завладяха ги ненавистниците им.
Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
42 Неприятелите им още ги притесняваха; И те останаха подчинени под ръката им.
Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
43 Много пъти Той ги избавя; Но, понеже намеренията им бяха бунтовнически, Затова се и унищожиха поради беззаконието си.
Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
44 Въпреки това, обаче, Той погледна на утеснението им, Когато чу вика им;
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
45 Спомни си за тях Своя завет, И разкая се според голямата Си милост;
ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
46 Тоже стори да ги съжаляват Всички, които ги бяха пленили.
Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
47 Избави ни, Господи Боже наш, И събери ни измежду народите, За да славословим Твоето свето име, И да тържествуваме с Твоята хвала.
Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
48 Благословен да е Господ Израилевият Бог от века до века; И всичките люде да рекат: Амин. Алилуя.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!

< Псалми 106 >