< Числа 9 >
1 И в първия месец на втората година, откак излязоха из Египетската земя, Господ говори още на Моисея в Сенайската пустиня, казвайки:
Olúwa sọ fún Mose nínú aginjù Sinai ní oṣù kìn-ín-ní ọdún kejì lẹ́yìn tí wọ́n kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti wí pé,
2 Нека направят израилтяните пасхата на определеното й време.
“Mú kí àwọn ọmọ Israẹli máa pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní àsìkò rẹ̀.
3 На четиринадесетия ден от тоя месец привечер да я направите, на определеното й време; според всичките закони за нея и според всичките наредби за нея да я направите.
Ẹ ṣe é ní àsìkò rẹ̀ gan an ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí ní ìbámu pẹ̀lú àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀.”
4 И тъй, Моисей каза на израилтяните да направят пасхата.
Mose sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọ́n máa pa àjọ ìrékọjá mọ́.
5 Направиха пасхата на четиринадесетия ден от първия месец привечер, в Синайската пустиня; напълно според както Господ заповяда на Моисея, така направиха израилтяните.
Wọ́n sì ṣe àjọ ìrékọjá ní aginjù Sinai ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní. Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo nǹkan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
6 А имаше някои, които бяха нечисти, поради мъртво човешко тяло, та не можаха да направят пасхата в оня ден; и в същия ден те дойдоха при Моисея и пред Аарона,
Àwọn díẹ̀ nínú wọn kò lè ṣe àjọ ìrékọjá lọ́jọ́ náà nítorí pé wọ́n di aláìmọ́ nítorí òkú ènìyàn. Nítorí èyí wọ́n wá sọ́dọ̀ Mose àti Aaroni lọ́jọ́ náà.
7 и тия мъже рекоха: Ние сме нечисти, поради мъртво човешко тяло, защо да ни спират да не принесем между израилтяните Господния принос на времето му?
Wọ́n sọ fún Mose pé, “A di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ló dé tí a kò fi ní í le è fi ọrẹ wa fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ará Israẹli yòókù ní àsìkò tí a ti yàn.”
8 А Моисей им рече: Постойте, за да чуя какво ще заповяда Господ за вас.
Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ dúró kí n ba lè mọ ohun tí Olúwa yóò pàṣẹ nípa yín.”
9 И Господ говори на Моисея, казвайки:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
10 Говори на израилтяните, казвайки: Ако някой човек от вас или от потомците ви бъде нечист, поради мъртво тяло, или е далеч на път, нека и той направи пасхата Господу;
“Sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘Bí ẹnìkan nínú yín tàbí nínú ìran yín bá di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn tàbí bí ó bá lọ sí ìrìnàjò síbẹ̀ yóò pa àjọ ìrékọjá Olúwa mọ́.
11 нека я направят на четиринадесетия ден на втория месец привечер, и нека я ядат с безквасни хлябове и горчиви треви;
Wọn yóò ṣe tiwọn ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kejì. Wọn yóò jẹ ẹran náà, pẹ̀lú àkàrà aláìwú àti ewúro.
12 да не оставят от нея до утринта, нито да трошат кост от нея; да я направят, според всичките повеления за пасхата.
Wọn kò gbọdọ̀ ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀, wọn kò sì gbọdọ̀ ṣẹ́ eegun rẹ̀. Wọ́n gbọdọ̀ tẹ̀lé gbogbo ìlànà fún ṣíṣe àjọ ìrékọjá.
13 А който е чист, и не е на път, ако пренебрегне да направи пасхата, тоя човек ще бъде изтребен измежду людете си; понеже не е принесъл Господния принос на времето му, тоя човек ще носи греха си.
Ṣùgbọ́n bí ẹnìkan tó wà ní mímọ́ tí kò sì lọ sí ìrìnàjò bá kọ̀ láti pa àjọ ìrékọjá mọ́, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí pé kò mú ọrẹ Olúwa wá ní àsìkò tí ó yẹ. Ẹni náà yóò sì ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
14 И ако някой чужденец, който е пришелец между вас, желае да направи пасхата Господу, нека я направи, според повеленията за пасхата и според наредбата за нея; един закон ще имате и за чужденеца и за туземеца.
“‘Bí àlejò tí ń gbé láàrín yín bá fẹ́ ṣe àjọ ìrékọjá Olúwa, ó gbọdọ̀ pa á mọ́ ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà àti òfin rẹ̀. Ìlànà kan náà ni kí ẹ ní fún àlejò àti àwọn ọmọ bíbí ilẹ̀ yín.’”
15 И в деня, когато се постави скинията, облакът покри скинията, шатъра за плочите на свидетелството; и от вечер до заран над скинията имаше като огнено явление.
Ní ọjọ́ tí wọ́n gbé àgọ́ ró, èyí tí í ṣe àgọ́ ẹ̀rí, dúró, ìkùùkuu àwọsánmọ̀ bò ó mọ́lẹ̀. Ìkùùkuu náà sì dàbí iná ní orí àgọ́ láti ìrọ̀lẹ́ títí di òwúrọ̀.
16 Така ставаше всякога: облакът я покриваше, и нощем имаше огнено явление.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí nígbà gbogbo; ìkùùkuu bò ó, àti pé ní alẹ́ ìrísí rẹ̀ sì dàbí iná.
17 И когато се дигаше облакът от шатъра, тогава, след това, израилтяните тръгваха; и гдето заставаше облакът, там израилтяните разполагаха стан.
Nígbàkígbà tí ìkùùkuu yìí bá ká sókè kúrò lórí àgọ́ ni àwọn ọmọ Israẹli yóò dìde láti máa lọ; ibikíbi tí ìkùùkuu náà bá dúró sí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò pa ibùdó wọn sí.
18 По Господно повеление тръгваха израилтяните, и по Господно повеление разполагаха стан; до тогаз, до когато облакът стоеше над скинията, те си оставаха в стана.
Nípa àṣẹ Olúwa ni àwọn ọmọ Israẹli ń jáde lọ, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń pa ibùdó wọn. Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́, àwọn náà yóò dúró sí ibùdó.
19 И когато облакът стоеше над скинията много дни, тогава израилтяните пазеха Господното заръчване и не тръгваха;
Nígbà tí ìkùùkuu bá dúró sórí àgọ́ fún ìgbà pípẹ́, síbẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa wọn kò sì ní gbéra láti lọ.
20 а понякога облакът стоеше над скинията малко дни; но пак по Господно повеление оставаха разположени в стана, и по Господно повеление тръгваха.
Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè wà lórí àgọ́ fún ọjọ́ díẹ̀; síbẹ̀ ní àṣẹ Olúwa, wọn yóò dúró ní ibùdó, bí ó sì tún yá, ní àṣẹ rẹ̀ náà ni wọn yóò gbéra.
21 И понякога облакът стоеше само от вечер до заран; но пак на заранта, когато се дигаше облакът, тогава и те тръгваха; когато се дигаше облакът, било денем или нощем, тогава и те тръгнаха;
Ìgbà mìíràn ìkùùkuu lè dúró láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀, nígbà tó bá ṣí kúrò ní àárọ̀, wọn ó gbéra. Ìbá à ṣe ní ọ̀sán tàbí òru, ìgbàkígbà tí ìkùùkuu bá tó kúrò náà ni wọn ó tó gbéra.
22 Ако облакът продължаваше да стои над скинията два дена, или един месец, или една година, то и израилтяните оставаха в стана си и не тръгваха; а когато той се дигаше, те тръгваха.
Ìbá à ṣe fún ọjọ́ méjì, oṣù kan tàbí ọdún kan ni ìkùùkuu fi dúró sórí àgọ́, àwọn ọmọ Israẹli yóò dúró ní ibùdó wọn, wọn kò ní gbéra; ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá lọ sókè ni wọn ó tó o gbéra.
23 Според Господно повеление разполагаха стан, и според Господно повеление тръгваха; те пазеха заръчаното от Бога, както заповядваше Господ чрез Моисея.
Nípa àṣẹ Olúwa ni wọ́n ń pa ibùdó wọn, nípa àṣẹ Olúwa náà sì ni wọ́n ń gbéra. Wọ́n gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa ní ìbámu pẹ̀lú àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.