< Числа 31 >

1 След това Господ говори на Моисея, казвайки:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Въздай на мадиамците за израилтяните, и след това ще се прибереш при людете си.
“Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”
3 Моисей, прочее, говори на людете, казвайки: Нека се въоръжат от вас мъже за бой и нека отидат против Мадиама за да извършат въздаяние върху Мадиама за Господа.
Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn.
4 По хиляда души от всяко племе от всичките Израилеви племена да изпратите на войната.
Rán ẹgbẹ̀rún ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.”
5 И така, от Израилевите хиляди се преброиха по хиляда души от всяко племе, дванадесет хиляди души, въоръжени, за бой.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá mẹ́fà ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun.
6 И Моисей ги изпрати на войната, по хиляда души от всяко племе, тях и Финееса, сина на свещеника Елеазара, със светите вещи и с тръбите за тревога в ръцете му.
Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.
7 Те воюваха против Мадиама според както Господ заповяда на Моисея, и убиха всяко мъжко.
Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn.
8 И между убитите убиха и мадиамските царе: Евия, Рекема, Сура, Ура и Рава, петима мадиамски царе; убиха с нож и Валаама Веоровия син.
Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori.
9 А израилтяните плениха жените на мадиамците, децата им, всичкия им добитък и всичките им стада; и разграбиха всичкия им имот.
Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
10 А всичките им градове, в местата населени от тях, и всичките им станове изгориха с огън.
Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
11 И взеха всичките користи и всичкото плячка, и човек и животно.
Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.
12 И докараха пленниците, плячката и користите на Моисея, на свещеника Елеазар и на обществото израилтяни в стана, на моавските полета при Иордан, срещу Ерихон.
Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.
13 Тогава Моисей, свещеникът Елеазар и всичките първенци на обществото излязоха да ги посрещнат вън от стана.
Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó.
14 Но Моисей се разгневи на военачалниците, на хилядниците и на стотниците, които се връщаха от военния поход;
Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún tí wọ́n ti ogun dé.
15 и Моисей им рече: Оставихте ли живи всичките жени?
Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí?
16 Ето, те, по съвета на Валаама, накараха израилтяните да беззаконствуват против Господа в делото на Фегора, тъй че язвата се яви всред Господното общество.
Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa.
17 За това, убийте сега всичките мъжки от децата, и убийте всяка жена, която е познала мъж, като е лежала с него.
Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin,
18 А всичките момичета, които не са познали мъж, които не са лежали с такъв, оставете живи за себе си.
ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.
19 И вие останете вън от стана седем дена; вие и пленниците ви, всеки от вас, който е убил човек, и който се е допрял до убит, очистете се на третия ден и на седмия ден;
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje. Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́.
20 очистете и всичките дрехи, всичките кожени вещи, и всичко, което е направено от козина, и всичките дървени съдове.
Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”
21 Също и свещеник Елеазар рече на войниците, които бяха ходили на война: Това е повелението, което Господ заповяда на Моисея като закон.
Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose.
22 Само че златото, среброто, медта, желязото, оловото и калая,
Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé.
23 всичко, което може да устои на огън, прекарайте през огън, и ще бъде чисто; обаче, трябва да се очисти и с очистителна вода; и всичко що не може да устои на огън прекарай през вода.
Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi.
24 Тогава на седмия ден да изперете дрехите си, и ще бъдете чисти; и подир това да влезете в стана.
Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”
25 И Господ говори на Моисея, казвайки:
Olúwa sọ fún Mose pé,
26 Ти и свещеникът Елеазар и началниците на бащините домове от обществото пребройте плячката и пленниците, и човек и животно,
“Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn.
27 и раздели плячката на две, между войниците, между войниците, които ходиха на война и цялото общество.
Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ.
28 От дела на войниците, които ходиха на бой, отдели като данък за Господа то една душа от петстотин - от човеци, от говеда, от осли и от овци;
Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà, ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.
29 от тяхната половина да вземеш това и да го дадеш на свещеника Елеазара, като възвишаем принос Господу.
Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.
30 А от половината, която се дава на израилтяните, да вземеш по един дял от петдесет - от човеци, от говеда, от осли и от овци - от всеки добитък, - и да ги дадеш на лавитите, които пазят заръчаното за Господната скиния.
Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”
31 И тъй Моисей и свещеникът Елеазар сториха, според както Господ заповяда на Моисея.
Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
32 А плячката, то ест, това, което остана в плен, което войниците заплениха, беше: овци, шестстотин седемдесет и пет хиляди;
Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.
33 говеда, седемдесет и две хиляди:
Ẹgbàá méjìléláàádọ́rin màlúù
34 осли, шестдесет и една хиляда
ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
35 и човеци - жени, които не бяха познали мъж, чрез лягане с такъв - всичко тридесет и две хиляди души.
pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.
36 Половината, делът на ония, които бяха ходили на бой, беше на брой: овци, триста и тридесет и седем хиляди и петстотин;
Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́: ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.
37 а данъкът за Господа от овците беше шестстотин седемдесет и пет;
Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn;
38 говедата бяха тридесет и шест хиляди, от които данъкът за Господа беше седемдесет и две;
ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàádọ́rin;
39 ослите бяха тридесет хиляди и петстотин, от които данъкът за Господа беше шестдесет и един;
kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta.
40 и човеците бяха шестнадесет хиляди, от които данъкът за Господа беше тридесет и двама души,
Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n.
41 И Моисей даде данъка, като възвишаем принос Господу, на свещеника Елеазара, както Господ заповяда на Моисея.
Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
42 А половината, която се даде на израилтяните, който Моисей отдели от войниците,
Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun.
43 то ест, половината за обществото, беше: овци, триста и тридесет и седем хиляди и петстотин;
Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn,
44 говеда, тридесет и шест хиляди;
pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún màlúù
45 осли, тридесет хиляди и петстотин;
tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
46 и човеци - шестнадесет хиляди.
Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ.
47 От тия половината за израилтяните Моисей взе по един дял от петдесет от човеци и от животни, и ги даде на левитите, които пазеха заръчаното за Господната скиния, според както Господ заповяда на Моисея.
Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.
48 Тогава се приближиха при Моисея началниците, които бяха над хилядите на войската, хилядниците и стотниците,
Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose.
49 и рекоха на Моисея: Слугите ти преброиха войниците, които са под ръката ни; и не липсва ни един от нас.
Wọ́n sì sọ fún un pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín.
50 За това принасяме дар Господу, всеки каквото е намерил, златни неща, верижки, гривни, пръстени, обеци и мъниста, за да се извърши умилостивение за душите ни пред Господа.
Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”
51 И Моисей и свещеникът Елеазар взеха златото от тях, всичко в изработени украшения.
Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́.
52 И всичкото злато от възвишаемия принос, който хилядниците и стотниците принесоха Господу, беше шестнадесет хиляди седемстотин и петдесет сикли.
Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta ṣékélì.
53 (Защото войниците бяха грабили, всеки за себе си).
Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀.
54 И Моисей и свещеникът Елеазар, като взеха златото от хилядниците и стотниците, донесоха го в шатъра за срещане, за спомен на израилтяните пред Господа.
Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.

< Числа 31 >