< Числа 27 >

1 Тогава дойдоха дъщерите се Салпаада Еферовия син, а Ефер син на Галаада, син на Махира, син на Манасия, от семействата на Манасия Иосифовия син. А ето имената на дъщерите му: Маала, Нуа, Егла, Мелха и Терса.
Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
2 Те застанаха пред Моисея, пред свещеника Елеазара, и пред първенците и цялото общество, при входа на шатъра за срещане, и рекоха:
Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
3 Баща ни умря в пустинята; а той не беше от дружината на ония, които се събраха против Господа в Кореевата дружина, но умря поради своя си грях; и нямаше синове.
“Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
4 Защо да изчезне името на баща ни отсред семейството му по причина, че не е имал син? Дай на нас наследството между братята на бащите ни.
Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
5 И Моисей представи делото им пред Господа.
Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
6 Тогава Господ говори на Моисея, казвайки:
Olúwa sì wí fún un pé,
7 Право говорят Салпаадовите дъщери; непременно да им дадеш да притежават наследство между братята на баща си, и да направиш да мине върху тях наследството на баща им.
“Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
8 И говори на израилтяните, казвайки: Ако умре някой без да има син, тогава да прехвърлите наследството му върху дъщерите му.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
9 И ако няма дъщеря, тогава да дадете наследството му на братята му.
Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
10 И ако няма братя, тогава да дадете наследството му на бащините му братя.
Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
11 Но ако баща му няма братя, тогава да дадете наследството му на най-близкия му сродник от семейството му, и той да го притежава. Това да бъде съдебен закон за израилтяните, според както Господ заповяда на Моисея.
Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
12 След това Господ рече на Моисея: Възкачи се на тая планина Аварим и прегледай земята, която съм дал на израилтяните;
Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
13 и като я прегледаш, ще се прибереш и ти при людете си, както се прибра брат ти Аарон;
Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
14 защото в пустинята Цин, когато обществото се противеше, вие не се покорихте на повелението Ми, да Ме осветите при водата пред тях. (Това е водата на Мерива при Кадис в пустинята Цин).
nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
15 А Моисей говори на Господа, казвайки:
Mose sọ fún Olúwa wí pé,
16 Господ, Бог на духовете на всяка твар, нека постави над обществото човек,
“Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
17 който да излиза пред тях и който да влиза пред тях, който да ги извежда и който да ги въвежда, за да не бъде Господното общество като овци, които нямат пастир.
láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
18 И Господ каза на Моисея: Вземи при себе си Исуса Навиевия син, човек в когото е Духът, и положи на него ръката си;
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
19 и като го представиш пред свещеника Елеазара и пред цялото общество, дай му поръчка пред тях.
Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
20 И възложи на него част от твоята почетна власт, за да го слуша цялото общество израилтяни.
Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
21 И той да стои пред свещеника Елеазара, който ще се допитва до Господа за него според съда на Урима; и по неговата дума да влизат, той и всичките израилтяни с него, и цялото общество.
Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
22 И Моисей стори според както му заповяда Господ; взе Исуса и представи го пред свещеника Елеазара и пред цялото общество;
Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
23 и като положи ръцете си на него, даде му поръчка, според както Господ заповяда чрез Моисея.
Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< Числа 27 >