< Неемия 10 >
1 А ония, които подпечатаха, бяха: управителят Неемия, Ахалиевият син и Седекия,
Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
2 Сераия, Азария, Еремия,
Seraiah, Asariah, Jeremiah,
3 Пасхор, Амария, Мелхия,
Paṣuri, Amariah, Malkiah,
Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
Harimu, Meremoti, Obadiah,
6 Даниил, Ганатон, Варух,
Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
8 Маазия, Велгай и Семаия; те бяха свещеници.
Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
9 Левити: Исус, Азаниевият син, Вануй от Инададовите потомци и Кадмиил;
Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
10 и братята им Севания, Одия, Келита, Фелаия, Анан,
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
12 Закхур, Серевия, Севания,
Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
14 Началниците на людете: Фарос, Фаат-моав, Елам, Зату, Ваний,
Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
20 Матфиас, Месулам, Изир,
Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
21 Месизавеил, Садок, Ядуа,
Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
Pelatiah, Hanani, Anaiah,
Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
Malluki, Harimu, àti Baanah.
28 А останалите от людете, свещениците, левитите, вратарите, певците, нетинимите, и всички, които бяха се отделили от племената на земите и се прилепили към Божия закон, жените им, синовете им и дъщерите им, всеки, който знаеше и разбираше,
“Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
29 присъединиха се към братята си, големците си, и постъпиха в заклинание и клетва да ходят по Божия закон, който бе даден чрез Божия слуга Моисея, и да пазят и вършат всичките заповеди на Иеова нашия Господ, съдбите Му и повеленията Му;
gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
30 и да не даваме дъщерите си на племената на земята, и да не вземаме техните дъщери за синовете си;
“A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
31 и ако племената на земята донесат стоки или каква да било храна за продан в съботен ден, да не купуваме от тях в събота или в свет ден; и да се отказваме от обработването на земята всяка седма година и от изискването на всеки дълг.
“Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
32 Наредихме Си още да се задължим да даваме всяка година по една трета от сикъла за службата на дома на нашия Бог,
“Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
33 за присъствените хлябове, за постоянния хлебен принос, за постоянното всеизгаряне, в съботите и на новолунията и на празниците, и за светите неща, за приносите за грях в умилостивение за Израиля, и за всичката работа на дома на нашия Бог.
nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
34 И ние - свещениците, левитите и людете - хвърлихме жребие помежду си за приноса на дървата, за да ги докарват в дома на нашия Бог, според бащините ни домове, в определените времена всяка година, за да горят върху олтара на Господа нашия Бог според предписаното в закона;
“Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
35 и всяка година да донасяме в Господния дом първите плодове от земята си и първите плодове от рожбата на всяко дърво;
“Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
36 и да довеждаме в дома на нашия Бог, на свещениците, които служат в дома на нашия Бог, първородните от синовете си и от добитъка си, според предписаното в закона, и първородните от говедата си и от стадата си;
“Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
37 и да донасяме на свещениците, в стаите на дома на нашия Бог първите плодове от нашето тесто, и приносите си, и плодовете от всякакво дърво, тоже и виното и дървеното масло; и да внасяме на левитите десетъците от земята си, и левитите да вземат десетъците по всичките градове, гдето обработваме земята.
“Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
38 И някой свещеник, Ааронов потомец да бъде с левитите, когато вземат десетъците; и левитете да донасят десетъка от десетъците в дома на нашия Бог, в стаите на съкровищницата.
Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
39 Защото израилтяните и левийците трябва да донасят приносите от житото, от виното и от дървеното масло в стаите, гдето са съдовете на светилището, и служащите свещеници, вратарите и първенците. И няма да оставим дома на нашия Бог.
Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”