< Лука 24 >
1 А в първия ден на седмицата, сутринта рано, жените дойдоха на гроба, носещи ароматите, които бяха приготвили.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ ọ̀sẹ̀, àwọn obìnrin wá sí ibojì, wọ́n sì mú ìkunra olóòórùn dídùn ti wọ́n tí pèsè sílẹ̀ wá.
2 О и как нашите главни свещеници и началници Го предадоха да бъде осъден на смърт и Го разпнаха.
Òkúta ti yí kúrò ní ẹnu ibojì.
3 И като влязоха, не намериха тялото на Господа Исуса.
Nígbà tí wọ́n sì wọ inú rẹ̀, wọn kò rí òkú Jesu Olúwa.
4 И когато бяха в недоумение за това, ето застанаха пред тях двама мъже с ослепително облекло.
Bí wọ́n ti dààmú kiri níhà ibẹ̀, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì aláṣọ dídán dúró tì wọ́n.
5 И обзети от страх, те наведоха лицата си до земята; а мъжете им рекоха: Защо търсите живия между мъртвите?
Nígbà tí ẹ̀rù ń bà wọ́n, tí wọ́n sì dojúbolẹ̀, àwọn angẹli náà bi wọ́n pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń wá alààyè láàrín àwọn òkú?
6 Няма Го тука, но възкръсна. Спомнете си какво ви говореше, когато беше още в Галилея,
Kò sí níhìn-ín yìí, ṣùgbọ́n ó jíǹde; ẹ rántí bí ó ti wí fún yín nígbà tí ó wà ní Galili.
7 като казваше, че Човешкият Син трябва да бъде предаден в ръцете на грешни човеци, да бъде разпнат, и в третия ден да възкръсне.
Pé, ‘A ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀ lọ́wọ́, a ó sì kàn án mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.’”
8 И спомниха си думите му.
Wọ́n sì rántí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
9 И като се върнаха от гроба, известиха всичко това на единадесетте и на всичките други.
Wọ́n sì padà ti ibojì wá, wọ́n sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún àwọn mọ́kànlá, àti fún gbogbo àwọn ìyókù.
10 А бяха Магдалина Мария, и Иоанна, и Мария Якововата майка и другите жени с тях, които казаха тия неща на апостолите.
Maria Magdalene, àti Joanna, àti Maria ìyá Jakọbu, àti àwọn mìíràn pẹ̀lú wọn sì ni àwọn tí ó ròyìn nǹkan wọ̀nyí fún àwọn aposteli.
11 А тия думи им се видяха като празни приказки, и не вярваха.
Ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sì dàbí ìsọkúsọ lójú wọn, wọn kò sì gbà wọ́n gbọ́.
12 А Петър стана и изтича на гроба, и, като надникна, видя саваните, сложени отделно; и отиде у дома си, чудейки се за станалото.
Nígbà náà ni Peteru dìde, ó súré lọ sí ibojì; nígbà tí ó sì bẹ̀rẹ̀, ó rí aṣọ àlà lọ́tọ̀ fúnra wọn, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀, ẹnu yà á sí ohun tí ó ṣe.
13 И, ето, в същия ден двама от тях отиваха в едно село на име Емаус, шестдесет стадии(Около 11 километра.) далеч от Ерусалим.
Sì kíyèsi i, àwọn méjì nínú wọn ń lọ ní ọjọ́ náà sí ìletò kan tí a ń pè ní Emmausi, tí ó jìnnà sí Jerusalẹmu níwọ̀n ọgọ́ta ibùsọ̀.
14 И те се разговаряха помежду си за всичко онова, що бе станало.
Wọ́n ń bá ara wọn sọ̀rọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣẹlẹ̀.
15 И като се разговаряха и разискваха, сам Исус се приближи и вървеше с тях;
Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń bá ara wọn sọ̀rọ̀, tí wọ́n sì ń bá ara wọn jíròrò, Jesu tìkára rẹ̀ súnmọ́ wọn, ó sì ń bá wọn rìn lọ.
16 Но очите им се удържаха да Го не познаят.
Ṣùgbọ́n a rú wọn lójú, kí wọn má le mọ̀ ọ́n.
17 И рече им: Какви са тия думи, които разменявате помежду си, като пътувате? И те се спряха натъжени.
Ó sì bi wọ́n pé, “Ọ̀rọ̀ kín ni ẹ̀yin ń bá ara yín sọ, bí ẹ̀yin ti ń rìn?” Wọ́n sì dúró jẹ́, wọ́n fajúro.
18 И един от тях, на име Клеопа, в отговор Му рече: Само ти ли си пришелец в Ерусалим и не знаеш станалото там тия дни?
Ọ̀kan nínú wọn, tí a ń pè ní Kileopa, sì dáhùn wí fún un pé, “Àlejò sá à ni ìwọ ní Jerusalẹmu, tí ìwọ kò sì mọ ohun tí ó ṣẹ̀ níbẹ̀ ní ọjọ́ wọ̀nyí?”
19 И рече им: Кое? А те му рекоха: Станалото с Исуса Назарянина, Който бе пророк, силен в дело и в слово пред Бога и пред всичките люде;
Ó sì bi wọ́n pé, “Kín ni?” Wọ́n sì wí fún un pé, “Ní ti Jesu ti Nasareti, ẹni tí ó jẹ́ wòlíì, tí ó pọ̀ ní ìṣe àti ní ọrọ̀ níwájú Ọlọ́run àti gbogbo ènìyàn,
20 и как нашите главни свещеници и началници Го предадоха да бъде осъден на смърт и Го разпнаха.
àti bí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn alàgbà wa ti fi òun lé wọn lọ́wọ́ láti dá a lẹ́bi ikú, àti bí wọ́n ti kàn án mọ́ àgbélébùú.
21 А ние се надявахме, че Той е Онзи, Който ще избави Израиля. И освен всичко това, вече е трети ден, откак стана това.
Bẹ́ẹ̀ ni òun ni àwa ti ní ìrètí pé, òun ni ìbá dá Israẹli ní ìdè. Àti pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, òní ni ó di ọjọ́ kẹta tí nǹkan wọ̀nyí ti ṣẹlẹ̀.
22 При туй и някои жени измежду нас ни смаяха, които като отишли отзарана на гроба,
Àwọn obìnrin kan pẹ̀lú nínú ẹgbẹ́ wa, tí wọ́n lọ si ibojì ní kùtùkùtù, sì wá yà wá lẹ́nu,
23 и не намерили тялото Му, дойдоха и казаха, че видели и видение на ангели, които казали, че Той бил жив.
nígbà tí wọn kò sì rí òkú rẹ̀, wọ́n wá wí pé, àwọn rí ìran àwọn angẹli tí wọ́n wí pé, ó wà láààyè.
24 И някои от ония, които бяха с нас, отидоха на гроба, и намериха тъй както рекоха жените; а Него не видели.
Àti àwọn kan tí wọ́n wà pẹ̀lú wa lọ sí ibojì, wọ́n sì rí i gẹ́gẹ́ bí àwọn obìnrin náà ti wí, ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ ni wọn kò rí.”
25 И Той им рече: О несмислени и мудни по сърце да вярвате всичко, което са говорили пророците!
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin tí òye kò yé, tí ẹ sì yigbì ní àyà láti gba gbogbo èyí tí àwọn wòlíì ti wí gbọ́,
26 Не трябваше ли Христос да пострада така и да влезе в славата Си?
kò ha yẹ kí Kristi ó jìyà nǹkan wọ̀nyí kí ó sì wọ inú ògo rẹ̀ lọ.”
27 И като почна от Моисея и от всичките пророци, тълкуваше им писаното за Него във всичките писания.
Ó sì bẹ̀rẹ̀ láti Mose àti gbogbo àwọn wòlíì wá, ó sì túmọ̀ nǹkan fún wọn nínú ìwé mímọ́ gbogbo nípa ti ara rẹ̀.
28 И приближиха селото, в което отиваха; Той се държеше, като че отива по-надалеч.
Wọ́n sì súnmọ́ ìletò tí wọ́n ń lọ, ó sì ṣe bí ẹni pé yóò lọ sí iwájú.
29 Но те Го нудеха, казвайки: Остани с нас, защото е привечер, и денят вече е превалил. И Той влезе да остане с тях.
Wọ́n sì rọ̀ ọ́, pé, “Bá wa dúró: nítorí ó di ọjọ́ alẹ́, ọjọ́ sì kọjá tán.” Ó sì wọlé lọ, ó bá wọn dúró.
30 И като седна с тях на трапезата, взе хляба и благослови, разчупи и даде им.
Ó sì ṣe, bí ó ti bá wọn jókòó ti oúnjẹ, ó mú àkàrà, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún wọn.
31 И очите им се отвориха и Го познаха; а Той стана невидим за тях.
Ojú wọn sì là, wọ́n sì mọ̀ ọ́n, ó sì nù mọ́ wọn ní ojú.
32 И рекоха помежду си: Не гореше ли в нас сърцето, когато ни говореше по пътя и когато ни тълкуваше писанията?
Wọ́n sì bá ara wọn sọ pé, “Ọkàn wa kò ha gbiná nínú wa, nígbà tí ó ń bá wa sọ̀rọ̀ tí ó sì ń túmọ̀ ìwé mímọ́ fún wa!”
33 И в същия час станаха и се върнаха в Ерусалим, гдето намериха събрани единадесетте и тия, които бяха с тях,
Wọ́n sì dìde ní wákàtí kan náà, wọ́n padà lọ sí Jerusalẹmu, wọ́n sì bá àwọn mọ́kànlá péjọ, àti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ wọn.
34 които и казаха: Господ наистина възкръснал и се явил на Симона.
Wọn si wí pé, “Olúwa jíǹde nítòótọ́, ó sì ti fi ara hàn fún Simoni!”
35 Те пък разправиха станалото по пътя, и как Го познаха, когато разчупваше хляба.
Àwọn náà sì ròyìn nǹkan tí ó ṣe ní ọ̀nà, àti bí ó ti di mí mọ̀ fún wọn ní bíbu àkàrà.
36 И когато говореха за това, сам Исус застана посред тях и каза им: Мир вам!
Bí wọ́n sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí Jesu tìkára rẹ̀ dúró láàrín wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Àlàáfíà fún yín.”
37 А те се стреснаха и се уплашиха, като мислеха, че виждат дух.
Ṣùgbọ́n àyà fò wọ́n, wọ́n sì wárìrì, wọ́n ṣe bí àwọn rí ẹ̀mí kan.
38 И Той им рече: Защо се смущавате? И защо се пораждат такива мисли в сърцата ви?
Ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ara yín kò lélẹ̀? Èé sì ti ṣe tí èròkerò fi ń sọ nínú ọkàn yín?
39 Погледнете ръцете Ми и нозете Ми, че съм Аз същият; попипайте Ме и вижте, защото дух няма меса и кости, както виждате, че Аз имам.
Ẹ wo ọwọ́ mi àti ẹsẹ̀ mi, pé èmi tìkára mi ni! Ẹ dì mímú kí ẹ wò ó nítorí tí iwin kò ní ẹran àti egungun lára, bí ẹ̀yin ti rí tí èmi ní.”
40 И като рече това, показа им ръцете и нозете си.
Nígbà tí ó sì wí bẹ́ẹ̀ tan, ó fi ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ hàn wọ́n.
41 Но понеже те от радост още не вярваха и се чудеха, Той рече: Имате ли тук нещо за ядене?
Nígbà tí wọn kò sì tí ì gbàgbọ́ fún ayọ̀, àti fún ìyanu, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ní ohunkóhun jíjẹ níhìn-ín yìí?”
42 И дадоха му част от печена риба [и меден сок].
Wọ́n sì fún un ní ẹja tí a fi oyin sè.
43 И взе та яде пред тях.
Ó sì gbà á, ó jẹ ẹ́ lójú wọn.
44 И рече им: Тия са думите, които ви говорих, когато бях още с вас, че трябва да се изпълни всичко, което е писано за Мене в Моисеевия закон, в пророците и в псалмите.
Ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún yín, nígbà tí èmí ti wà pẹ̀lú yín pé, a ní láti mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ nínú òfin Mose, àti nínú ìwé àwọn wòlíì, àti nínú Saamu, nípasẹ̀ mi.”
45 Тогава им отвори ума, за да разберат писанията.
Nígbà náà ni ó ṣí wọn ní iyè, kí ìwé mímọ́ lè yé wọn.
46 И рече им: Така е писано, че Христос трябва да пострада и да възкръсне от мъртвите в третия ден,
Ó sì wí fún wọn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni a ti kọ̀wé rẹ̀, pé: kí Kristi jìyà, àti kí ó sì jíǹde ní ọjọ́ kẹta kúrò nínú òkú,
47 и че трябва да се проповядва в Негово име покаяние и прощение на греховете между всичките народи, като се започне от Ерусалим.
àti pé kí a wàásù ìrònúpìwàdà àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ lórúkọ rẹ̀, ní orílẹ̀-èdè gbogbo, bẹ̀rẹ̀ láti Jerusalẹmu lọ.
48 Вие сте свидетели на това.
Ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí nǹkan wọ̀nyí.
49 И, ето, Аз изпращам върху вас обещанието на Отца Ми; а вие стойте в града [Ерусалим], докато се облечете със сила от горе.
Èmi yóò rán ohun tí Baba mi ṣe ìlérí sí yín, ṣùgbọ́n ẹ jókòó ní ìlú Jerusalẹmu, títí a ó fífi agbára wọ̀ yín, láti òkè ọ̀run wá.”
50 И ги заведе до едно място срещу Витания; и дигна ръцете Си да ги благослови.
Ó sì mú wọn jáde lọ títí wọ́n fẹ́rẹ̀ dé Betani, nígbà tí ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè, ó súre fún wọn.
51 И като ги благославяше, отдели се от тях, и се възнесе на небето.
Ó sì ṣe, bí ó ti ń súre fún wọn, ó yà kúrò lọ́dọ̀ wọn, a sì gbé e lọ sí ọ̀run.
52 И те Му се поклониха, и върнаха се в Ерусалим с голяма радост;
Wọ́n sì foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì padà lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ayọ̀ púpọ̀.
53 и бяха постоянно в храма, [хвалещи и] благославящи Бога. [Амин].
Wọ́n sì wà ní tẹmpili nígbà gbogbo, wọ́n ń fi ìyìn, àti ìbùkún fún Ọlọ́run.