< Съдии 6 >
1 И Израилтяните сториха зло пред Господа; и Господ ги предаде в ръката на Мадиама за седем години.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 И ръката на Мадиама преодоля над Израиля; и поради мадиамците, израилтяните си направиха ония ровове, които са по горите, и пещерите и укрепленията.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 И след като Израил посееше, мадиамците, амаличаните и източните жители дохождаха и нападаха против него;
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 и, като разполагаха стан против тях, унищожаваха рожбите на земята чак до Газа, и не оставяха храна за Израиля, нито овца, нито говедо, нито осел.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Защото дохождаха с добитъка си и с шатрите си, и влизаха в страната многобройни като скакалци; безбройни бяха и те и камилите им, и навлизаха в земята, за да я опустошават.
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 Така Израил изпадна в голямо униние поради мадиамците; затова, израилтяните извикаха към Господа.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 И когато израилтяните извикаха към Господа поради мадиамците,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 тогава Господ изпрати на израилтяните един пророк, който им каза: Така говори Господ Израилевият Бог: Аз ви изведох от Египет, и ви изведох от дома на робството;
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 И избавих ви от ръката на египтяните и от ръката на всички, които ви насилваха, и като ги изпъдих от пред вас, дадох ви земята им.
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 И рекох ви: Аз съм Господ вашият Бог; да не почитате боговете на аморейците, в чиято земя живеете. Обаче вие не послушахте гласа Ми.
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 И ангелът Господен дойде та седна под дъба, който е в Офра, и принадлежеше на авиезереца Иоас; а син му Гедеон чукаше жито в лина, за да го скрие от мадиамците.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 И ангелът Господен му се яви и му каза: Господ е с тебе, мъжо силни и храбри.
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 А Гедеон ме рече: О господине, ако Господ е с нас, то защо ни постигна всичко това? и къде са всичките Му чудеса, за които бащите ни ни разказваха, като думаха: Не изведе ли ни Господ от Египет? Но сега Господ ни е оставил и ни е предел в ръката на мадиамците.
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 И Господ погледна към него и му каза: Иди с тая твоя сила, и ще освободиш Израиля от ръката на мадиамците; не те ли изпратих Аз?
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 А той Му рече: О Господи! с какво ще освобадя аз Израиля? Ето, моето семейство е най-долно между Манасия, и аз съм най-малък в бащиния си дом.
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 Но Господ му рече: Непременно Аз ще бъда с тебе; и ти ще поразиш мадиамците като един човек.
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 Сетне той му каза: Моля Ти се, ако съм придобил Твоето благоволение, покажи ми знамение, за да зная Кой си Ти, Който говориш с мене;
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 моля Ти се, не си отивай от тук, докато не дойда при Тебе и изнеса приноса си и го положа пред Тебе. И Той ме рече: Ще чакам догдето се върнеш.
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Тогава Гедеон слезе та приготви яре и пресни пити от една ефа брашно; месото тури в кошница, а чорбата тури в гърне, и изнесе ги вън при него под дъба, та го представи.
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 И ангелът Божия му каза: Вземи месото и пресните пити та ги сложи на тоя камък, а чорбата излей. И стори така.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Тогава ангелът Господен простря края на жезъла, който беше в ръката му, та досегна месото и пресните пити; и излезе огън из камъка та пояде месото и пресните пити; а след това ангелът Господен си отиде отпред очите му.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 И като видя Гедеон, че това бе ангел Господен, Гедеон каза: Горко ми, Господи Иеова! защото видях ангела Господен лице с лице.
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 А Господ му каза: Мир на тебе, не бой се; няма да умреш.
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 И Гедеон издигна там олтар на Господа и нараче го Иеовашалом; той е до днес в Офра на авиезерците.
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 И в същата нощ Господ му каза: Вземи бащиния си вол, втория вол седемгодишния, та съсипи Вааловия жертвеник, който се намира у баща ти, и съсечи ашерата, която е при него.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 После на върха на тая скала издигни олтар на Господа твоя Бог, според наредбата, и вземи втория вол та го принеси за всеизгаряне с дървата на ашерата, която ще съсечеш.
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 И тъй, Гедеон взе десетина души от слугите си та стори както Господ му каза; а, понеже се боеше от бащиния си дом и от градските жители, затова не го стори денем, но го стори нощем.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 А когато градските жители станаха на утринта, ето, Вааловият жертвеник беше съборен, и ашерата, която беше при него, съсечена, и вторият вол цял изгорен на издигнатия олтар.
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 И казаха си един на друг: Кой е извършил тая работа? И като разпитаха и издириха, рекоха: Гедеон Иоасовият син е извършил тая работа.
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Тогава градските жители казаха на Иоаса: Изведете сина си да се умъртви, понеже той е съборил Вааловия жертвеник, и понеже е съсякъл ашерата, която беше при него.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 А Иоас рече на всички, които бяха се дигнали против него: Вие ли ще защитите делото на Ваала? или вие ще го спасите? Който защити неговото дело, нека бъде умъртвен докато е още заран. Ако той е бог, нека сам защити делото си, като са съборили жертвеника му
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 За това в същия ден той нарече сина си Ероваал, като казваше: Нека се съди Ваал с него, като е съборил жертвеника му.
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Тогава всичките мадиамци и амаличани и източните жители се събраха заедно та преминаха и разположиха стан в долината Езраел.
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 А Господният Дух дойде на Гедеона, и той засвири с тръба; и авиезерците се събраха да го последват.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 После изпрати вестители до целия Манасия, та и той се събра да го последва; прати вестители и до Асира, до Завулона и до Нефталима, а те дойдоха та ги посрещнаха.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 И Гедеон рече на Бога: Ако искаш да освободиш Израиля с моята ръка, според както си казал.
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 ето, аз ще туря руно вълна на гумното; ако падне роса само на руното, а цялата почва остане суха, тогаз ще позная, че ще освободиш Израиля с моята ръка, според както си казал.
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 Така биде; защото, като стана рано на утринта, той изстиска руното, и роса потече из руното, пълен леген вода.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 И Гедеон рече на Бога: Да не пламне гневът Ти против мене, и аз ще продумам само тоя път; да опитам моля Ти се, само тоя път с руното: сега нека остане сухо само руното, а по цялата почва нека падне роса.
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 И Бог стори така през оная нощ: само руното остана сухо, а по цялата почва падна роса.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.