< Съдии 3 >
1 А ето народите, които Господ остави, за да изпита чрез тях Израиля, всички от тях, които не знаеха всичките ханаански богове:
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa fi sílẹ̀ láti dán àwọn ìran tuntun ní Israẹli wò, àwọn ìran tí kò ì tí ì ní ìrírí ogun àwọn ará Kenaani.
2 само за да знаят и да се научат на бой поне тия от поколенията на израилтяните, които най-напред не са знаели; именно:
(Ó ṣe èyí láti fi kọ́ àwọn ìran Israẹli tí kò rí ogun rí níbí a ti ṣe ń jagun).
3 петте началници на филистимците, и всичките ханаанци, сидонци и евейци, които живеят в Ливанската планина, от планината Ваалермон до прохода на Емат.
Àwọn ìjòyè ìlú Filistini márààrún, gbogbo àwọn ará Kenaani, àwọn ará Sidoni, àti àwọn ará Hifi tí ń gbé ní àwọn òkè Lebanoni bẹ̀rẹ̀ láti òkè Baali-Hermoni títí dé Lebo-Hamati.
4 Те служеха, за да се изпита Израил чрез тях та да се знае, ще слушат ли заповедите, които Господ заповяда на бащите им чрез Моисея.
A fi àwọn ènìyàn náà sílẹ̀ láti dán àwọn Israẹli wò bóyá wọn yóò gbọ́rọ̀ sí àwọn òfin Olúwa, èyí tí ó ti fi fún àwọn baba wọn láti ipasẹ̀ Mose.
5 Така също израилтяните се заселиха между ханаанците, хетейците, аморейците, ферезейците, евейците и евусейците;
Àwọn ọmọ Israẹli gbé láàrín àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti àwọn ará Amori, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi.
6 и вземаха си дъщерите им за жени, и даваха дъщерите си на синовете им, и служеха на боговете им.
Dípò kí wọ́n run àwọn ènìyàn wọ̀nyí, Israẹli ń fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọbìnrin Israẹli fún àwọn ará ilẹ̀ náà ní aya, wọ́n sì ń sin àwọn òrìṣà wọn.
7 И израилтяните сториха зло пред Господа, като забравиха Господа своя Бог и служеха на ваалимите и на ашерите.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin Baali àti Aṣerah.
8 Затова гневът на Господа пламна против Израиля, и Той ги предаде в ръката на месопотамския цар Хусанрисатаима; и израилтяните бяха подчинени на Хусанрисатаима осем години.
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ kí Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu-Naharaimu bá wọn jà kí ó sì ṣẹ́gun wọn, Israẹli sì ṣe ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́jọ.
9 А когато израилтяните извикаха към Господа, Господ въздигна избавител на израилтяните, който ги спаси, Готониила син на Кенеза, по-младият брат на Халева.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli kígbe sí Olúwa, Òun gbé olùgbàlà kan dìde fún wọn, ẹni náà ni Otnieli ọmọ Kenasi àbúrò Kalebu tí ó jẹ́ ọkùnrin, ẹni tí ó gbà wọ́n sílẹ̀.
10 Дух Господен дойде върху него, и той съди Израиля. Излезе и на бой, и Господ предаде в ръката му месопотамския цар Хусанрисатаима; и ръката му преодоля против Хусанрисатаима.
Ẹ̀mí Olúwa bà lé e, òun sì ṣe ìdájọ́ Israẹli, ó sì síwájú wọn lọ sí ogun. Olúwa sì fi Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu lé Otnieli lọ́wọ́, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ sì borí Kuṣani-Riṣataimu.
11 Тогава земята имаше спокойствие четиридесет години. И Готониил Кенезовият син умря.
Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Otnieli ọmọ Kenasi sì kú.
12 Пак израилтяните сториха зло пред Господа; и Господ укрепи моавския цар Еглон против Израиля, по причина, че сториха зло пред Господа.
Àwọn ọmọ Israẹli sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí, Olúwa fún Egloni, ọba àwọn Moabu ní agbára ní orí Israẹli.
13 И той събра при себе си амонците и амаличаните и отиде та порази Израиля, и завладя Града на палмите.
Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ammoni àti àwọn ọmọ-ogun Amaleki ní Egloni gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ tí i se Jeriko.
14 И израилтяните бяха подчинени на моавския цар Еглон осемнадесет години.
Àwọn ọmọ Israẹli sì sin Egloni ọba Moabu fún ọdún méjìdínlógún.
15 А когато израилтяните извикаха към Господа, Господ им въздигна избавител, Аода син на вениаминеца Гира, мъж левак. Чрез него израилтяните пратиха подарък на моавския цар Еглон;
Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà kan sí wọn, Ehudu ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gera ti ẹ̀yà Benjamini. Àwọn ọmọ Israẹli fi ẹ̀bùn rán sí Egloni ọba Moabu.
16 но Аод си направи меч остър и от двете страни, дълъг един лакът, и опаса го под горната си дреха на дясното си бедро.
Ehudu sì rọ idà kan olójú méjì, ìgbọ̀nwọ́ kan ní gígùn; òun sì sán an ní abẹ́ aṣọ rẹ̀ ní itan rẹ̀ ọ̀tún.
17 Той, прочее, принесе подаръка на моавския цар Еглон. А Еглон беше човек твърде тлъст.
Ó sì mú ọrẹ náà wá fún Egloni ọba Moabu, Egloni ẹni tí ó sanra púpọ̀.
18 И като свърши да принесе подаръка, и изпрати човеците, които носеха подаръка,
Lẹ́yìn tí Ehudu ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.
19 той се върна от пограничните камъни които са при Галгал, и каза: Имам тайна дума за тебе, царю. А той му рече: Мълчи. И излязоха от него всичките, които стояха при него.
Ṣùgbọ́n nígbà tí òun fúnra rẹ̀ dé ibi ère fínfín tí ó wà létí Gilgali, ó padà sí Egloni, ó sì wí pé, “Ọba, mo ní ọ̀rọ̀ àṣírí láti bá ọ sọ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ dákẹ́!” Gbogbo àwọn tí ń ṣọ sì jáde síta kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
20 Тогава Аод дойде при него; и той седеше сам в лятната си горна стая. И рече Аод: Имам дума от Бога за тебе. Тогава той стана от стола си.
Ehudu lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ níbi tí ó ti jókòó ní iyàrá ìtura rẹ̀, Ehudu sì wí fún un pé, “Mo ní ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.” Bí ọba sì ti dìde ní orí ìtẹ́ rẹ̀,
21 А Аод простря лявата си ръка и, като измъкна меча от дясното си бедро, заби го в корема му
Ehudu fi ọwọ́ òsì rẹ̀ yọ idà láti ibi itan ọ̀tún rẹ̀ ó sì fi gún ọba nínú ikùn rẹ̀.
22 толкоз, щото и дръжката влезе след желязото; и тлъстината до там стисна желязото, щото не можеше да изтръгне из корема му меча, който излезе отзад.
Àti idà àti èèkù rẹ̀ sì wọlé ó sì yọ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ehudu kò yọ idà náà, ọ̀rá sì bo idà náà.
23 Тогава Аод излезе през трема и затвори след себе си вратата на горната стоя, и я заключи.
Ehudu ti àwọn ìlẹ̀kùn ní àtì-sínú òun sì bá yàrá òkè jáde, ó sì sálọ.
24 А когато излезе той, дойдоха слугите на Еглона, и, като видяха, че, ето, вратата на горната стая беше заключена, рекоха: Без съмнение по нуждата си е в лятната стая.
Lẹ́yìn tí ó ti lọ àwọn ìránṣẹ́ ọba dé, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ìlẹ̀kùn yàrá òkè ní títì, wọ́n rò pé, “Bóyá ó wà ní ilé ìyàgbẹ́ ní yàrá nínú ilé.”
25 Но макар че чакаха догде ги хвана срам, ето, той не отваряше вратата на горната стая, затова, взеха ключа та отвориха, и, ето, господарят им лежеше мъртъв на земята.
Nígbà tí wọ́n dúró dé ibi pé ó jẹ́ ìyanu fún wọn, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn. Níbẹ̀ ni wọ́n ti rí Olúwa wọn tí ó ti ṣubú, ó sì ti kú.
26 А докато те се бавеха, Аод избяга; и премина пограничните камъни, та се отърва в Сеирота.
Nígbà tí wọ́n dúró tí wọn sì ń retí, Ehudu ti sálọ. Ó ti gba ibi tí wọ́n ti ń gbẹ́ òkúta lére, ó sì sálọ sí Seira.
27 И когато дойде, засвири с тръба в Ефремовата хълмиста земя, та израилтяните слязоха с него от хълмистата земя, и той бе на чело.
Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó fọn ìpè ní orí òkè Efraimu, àwọn ọmọ Israẹli sì ba sọ̀kalẹ̀ lọ láti òkè náà wá, òun sì wà níwájú wọn.
28 И рече им: Вървете подир мене, защото Господ предаде неприятелите ви моавците в ръката ви. И те слязоха подир него, и като превзеха бродовете на Иордан към моавската страна, не оставиха да премине ни един човек.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa tẹ̀lé mi, nítorí Olúwa ti fi Moabu ọ̀tá yín lé yín lọ́wọ́.” Wọ́n sì tẹ̀lé e, wọ́n sì gba ìwọdò Jordani tí ó lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọn ò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá.
29 И в онова време поразиха от моавците около десет хиляди мъже, всички едри и всички яки; не се избави ни един човек.
Ní báyìí, wọ́n ti pa tó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ará Moabu tí wọ́n jẹ́ alágbára àti onígboyà ènìyàn, kò sí ènìyàn tí ó sálà.
30 Така в онова време Моав се покори под ръката на Израиля. Тогава земята имаше спокойствие осемдесет години.
Ní ọjọ́ náà ni Israẹli ṣẹ́gun àwọn ará Moabu, ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ọgọ́rin ọdún.
31 След него настана времето на Самегар Анатовият син, който с един волски остен порази шестстотин мъже от филистимците; също и той избави Израиля.
Lẹ́yìn Ehudu, ni Ṣamgari ọmọ Anati ẹni tí ó pa ẹgbẹ̀ta Filistini pẹ̀lú ọ̀pá tí a fi ń da akọ màlúù, òun pẹ̀lú sì gba Israẹli kúrò nínú ìpọ́njú.