< Исус Навиев 4 >
1 А когато целият народ съвсем беше преминал Иордан, Господ говори на Исуса, казвайки:
Nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọjá nínú odò Jordani tan, Olúwa sọ fún Joṣua pé,
2 Вземете си дванадесет човека от людете, по един човек от всяко племе,
“Yan ọkùnrin méjìlá nínú àwọn ènìyàn, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
3 и заповядайте им кат кажете: Вземете си дванадесет камъни от тук, от сред Иордан, от мястото гдето нозете на свещениците стоеха твърди, и занесете ги със себе си и турете ги на мястото, гдето ще пренощувате тая нощ.
kí o sì pàṣẹ fún wọn pé, ‘Ẹ gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani ní ibi tí àwọn àlùfáà dúró sí, kí ẹ sì rù wọn kọjá, kí ẹ sì gbé wọn sí ibi tí ẹ̀yin yóò sùn ní alẹ́ yìí.’”
4 Тогава Исус повика дванадесетте човека, които беше определил от израилтяните, по един човек от всяко племе;
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pe àwọn ọkùnrin méjìlá tí ó ti yàn nínú àwọn ọmọ Israẹli, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,
5 и Исус им каза: Заминете пред Ковчега на Господа вашия Бог всред Иордан и дигнете всеки от вас по един камък на рамената си, според числото на племената на израилтяните,
ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kọjá lọ ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa Ọlọ́run yín sí àárín odò Jordani. Kí olúkúlùkù yín gbé òkúta kọ̀ọ̀kan lé èjìká a rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli,
6 за да бъде това белег между вас. И утре, когато чадата ви попитат, казвайки: Защо ви са тия камъни?
kí ó sì jẹ́ àmì láàrín yín. Ní ọjọ́ iwájú, nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín pé, ‘Kí ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
7 - Тогава ще из кажете: Понеже водата на Иордан се раздели пред ковчега на Господния завет; когато ковчегът преминаваше Иордан, водата на Иордан се раздели. И тия камъни ще бъдат за спомен до века на израилтяните.
Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò dá wọn lóhùn pé, nítorí a gé omi odò Jordani kúrò ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí a rékọjá a Jordani, a gé omi Jordani kúrò. Àwọn òkúta wọ̀nyí yóò sì jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli láéláé.”
8 Тогава израилтяните сториха така както заповяда Исус; взеха дванадесет камъни отсред Иордан, според както рече Господ на Исуса, според числото на племената на израилтяните; и донесоха ги със себе си на мястото гдето пренощуваха, и там го положиха.
Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí Joṣua ti pàṣẹ fún wọn. Wọ́n gbé òkúta méjìlá láti àárín odò Jordani gẹ́gẹ́ bí iye ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli, bí Olúwa ti sọ fún Joṣua; wọ́n sì rù wọ́n kọjá lọ sí ibùdó, ní ibi tí wọ́n ti gbé wọn kalẹ̀.
9 Още Исус постави дванадесет камъни сред Иордан, на мястото гдето стояха нозете на свещениците, които носеха ковчега на завета; и те са там до днес.
Joṣua sì to òkúta méjìlá náà sí àárín odò Jordani fún ìrántí ní ọ̀kánkán ibi tí àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí ẹ̀rí dúró sí. Wọ́n sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
10 А свещениците, които носеха ковчега, стояха всред Иордан догде се свърши всичко що Господ заповяда на Исуса да говори на людете, според всичко, което Моисей беше заповядал на Исуса. И людете побързаха та преминаха.
Àwọn àlùfáà tí ó ru àpótí náà dúró ní àárín Jordani títí gbogbo nǹkan tí Olúwa pàṣẹ fún Joṣua fi di ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún Joṣua. Àwọn ènìyàn náà sì yára kọjá,
11 А когато всичките люде бяха съвсем преминали, мина и Господният ковчег и свещениците пред людете.
bí gbogbo wọn sì ti rékọjá tán, ni àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àwọn àlùfáà wá sí òdìkejì. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń wò wọ́n.
12 И рувимците, гадците и половината от Манасиевото племе преминаха въоръжени пред израилтяните, според както Моисея им бе казал;
Àwọn ọkùnrin Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase náà sì rékọjá ní ìhámọ́ra ogun níwájú àwọn ọmọ Israẹli, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ fún wọn.
13 около четиридесет хиляди въоръжени ратници преминаха пред Господа на бой към ерихонските полета.
Àwọn bí ọ̀kẹ́ méjì tó ti múra fún ogun rékọjá lọ ní iwájú Olúwa sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko láti jagun.
14 В оня ден Господ възвеличи Исуса пред очите на целия Израил; и те се бояха от него, както се бояха от Моисея, през всичките дни на живота му.
Ní ọjọ́ náà ni Olúwa gbé Joṣua ga ní ojú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì bẹ̀rù u rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé e wọn, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti bẹ̀rù Mose.
15 Тогава Господ говори на Исуса, казвайки:
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé,
16 Заповядай на свещениците, които носят ковчега на свидетелството, да излязат от Иордан.
“Pàṣẹ fún àwọn àlùfáà tí o ń ru àpótí ẹ̀rí, kí wọn kí ó jáde kúrò nínú odò Jordani.”
17 И тъй, Исус заповяда на свещениците, като рече: Излезте от Иордан.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua pàṣẹ fún àwọn àlùfáà pé, “Ẹ jáde kúrò nínú odò Jordani.”
18 А щом свещениците, които носеха ковчега на Господния завет, излязоха изсред Иордан, и стъпалата на свещеническите нозе стъпиха на сухо, водата на Иордан се върна на мястото си и преля всичките му брегове както по-напред.
Àwọn àlùfáà náà jáde láti inú odò pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa ni orí wọn. Bí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ ẹ wọn tẹ orí ilẹ̀ gbígbẹ ni omi Jordani náà padà sí ààyè e rẹ̀, o sì kún wọ bèbè bí i ti àtẹ̀yìnwá.
19 На десетия ден от първия месец людете излязоха от Иордан, и разположиха стан в Галгал, на източната страна от Ерихон.
Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kìn-ín-ní àwọn ènìyàn náà lọ láti Jordani, wọ́n sì dúró ní Gilgali ní ìlà-oòrùn Jeriko.
20 И Исус постави в Галгал ония дванадесет камъни, които взеха от Иордан.
Joṣua sì to àwọn òkúta méjìlá tí wọ́n mú jáde ní Jordani jọ ní Gilgali.
21 Тогава говори на израилтяните, казвайки: Утре, когато чадата ви попитат бащите си, думайки: Какви са тия камъни?
Ó sì sọ fún àwọn ará Israẹli, “Ní ọjọ́ iwájú nígbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè ní ọwọ́ baba wọn pé, ‘Kín ni òkúta wọ̀nyí dúró fún?’
22 ( Тогава да разправите на чадата си, като речете: По сухо премина Израил тоя Иордан;
Nígbà náà ni ẹ ó jẹ́ kí àwọn ọmọ yín mọ̀ pé, ‘Israẹli rékọjá odò Jordani ní orí ilẹ̀ gbígbẹ.’
23 Защото Господ вашият Бог пресуши Иорданската вода пред вас догде преминахте, както Господ вашият Бог стори на Червеното море, което пресуши пред нас догде преминахме,
Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín mú Jordani gbẹ ní iwájú u yín títí ẹ̀yin fi kọjá. Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí Jordani gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Òkun Pupa, nígbà tí ó mú un gbẹ ní iwájú wa títí àwa fi kọjá.
24 за да знаят всички племена на света, че Господната ръка е мощна, та да се боят винаги от Господа вашия Бог.
Ó ṣe èyí kí gbogbo ayé lè mọ̀ pé ọwọ́ Olúwa ní agbára, àti kí ẹ̀yin kí ó lè máa bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run yín ní ìgbà gbogbo.”