< Исус Навиев 24 >

1 След това Исус събра всичките Израилеви племена в Сихем и свика старейшините на Израиля, началниците им, съдиите им надзирателите им; и те се представиха пред Господа.
Nígbà náà ni Joṣua pe gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli jọ ní Ṣekemu. Ó pe àwọn àgbàgbà, àwọn olórí, onídàájọ́ àti àwọn ìjòyè Israẹli, wọ́n sì fi ara wọn hàn níwájú Ọlọ́run.
2 И Исус каза на всичките люде: Така говори Господ Израилевият Бог: В старо време оттатък реката живееха бащите ви, Тара, Авраамовият баща и Нахаровият баща, и служеха на други богове.
Joṣua sì sọ fun gbogbo ènìyàn pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, ‘Nígbà kan rí àwọn baba ńlá yín Tẹra baba Abrahamu àti Nahori ń gbé ní ìkọjá odò Eufurate, wọ́n sì sin àwọn òrìṣà.
3 И Аз взех баща ви Авраама от оная страна на реката, водих го през цялата Ханаанска земя, и умножих потомството му и му дадох Исаака;
Ṣùgbọ́n mo mú Abrahamu baba yín kúrò ní ìkọjá odò Eufurate, mo sì ṣe amọ̀nà rẹ̀ ni gbogbo Kenaani, mo sì fún ní àwọn ọmọ púpọ̀. Mo fún ní Isaaki,
4 а на Исаака дадох Якова и Исава. И на Исава дадох половината Сиир за притежание; а Яков и синовете му слязоха в Египет.
àti fún Isaaki ni mo fún ní Jakọbu àti Esau, mo sì fún Esau ní ilẹ̀ orí òkè Seiri ní ìní, ṣùgbọ́n Jakọbu àti àwọn ọmọ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti.
5 И против Моисея и Аарона, и поразиха Египет с язви, които извърших всред него, и после ви изведох.
“‘Nígbà náà ni mo rán Mose àti Aaroni, mo sì yọ Ejibiti lẹ́nu ní ti nǹkan tí mo ṣe níbẹ̀, mo sì mú yín jáde.
6 И като извеждах бащите ви из Египет, вие дойдохте на морето; и Египтяните се спуснаха след бащите ви с колесници и коне в Червеното море.
Nígbà tí mo mú àwọn baba yín jáde kúrò ní Ejibiti, ẹ wá sí Òkun, àwọn ará Ejibiti lépa wọn pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin títí ó fi dé Òkun Pupa.
7 Тогава те извикаха към Господа, и Той тури мрак между вас и египтяните, и навлече върху тях морето та ги покри; и очите ви видяха що сторих в Египет; и вие живяхте в пустинята дълго време.
Ṣùgbọ́n wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, ó sì fi òkùnkùn sí àárín yín àti àwọn ará Ejibiti, ó sì mú òkun wá sí orí wọn; ó sì bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ẹ sì fi ojú yín rí ohun tí mo ṣe sí àwọn ará Ejibiti. Lẹ́yìn náà ẹ sì gbé ní aginjù fún ọjọ́ pípẹ́.
8 После ви доведох в земята на аморейците, които живееха оттатък Иордан, и те воюваха против вас; но Аз ги предадох в ръцете ви, и вие завладяхте земята им, и Аз ги изтребих от пред вас.
“‘Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ àwọn ará Amori tí ó ń gbé ìlà-oòrùn Jordani. Wọ́n bá yín jà, ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé yín lọ́wọ́. Èmí pa wọ́n run kúrò níwájú u yín, ẹ sì gba ilẹ̀ ẹ wọn.
9 Тогава моавският цар Валак, Сепфоровият син, стана и воюва против Израиля; и прати да повикат Валаама Веоровия син, за да ви прокълне.
Nígbà tí Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, múra láti bá Israẹli jà, ó ránṣẹ́ sí Balaamu ọmọ Beori láti fi yín bú.
10 Но Аз не склоних да послушам Валаама, и той даже ви благослови; и Аз ви избавих от ръката му.
Ṣùgbọ́n èmi kò fetí sí Balaamu, bẹ́ẹ̀ ni ó súre fún un yín síwájú àti síwájú sí i, mo sì gbà yín kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
11 И вие преминахте Иордан та дойдохте в Ерихон; и воюваха против вас ерихонските мъже; амонците, ферезейците, ханаанците, хетейците, гергесейците, евейците и евусейците; и Аз ги предадох в ръцете ви.
“‘Lẹ́yìn náà ni ẹ rékọjá Jordani, tí ẹ sì wá sí Jeriko. Àwọn ará ìlú Jeriko sì bá yín jà, gẹ́gẹ́ bí ará Amori, Peresi, Kenaani, Hiti, Girgaṣi, Hifi àti Jebusi. Ṣùgbọ́n mo fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
12 И изпратих пред вас стършели, които изгониха от пред вас двамата аморейски царе, - не с твоя нож, нито с твоя лък.
Èmi sì rán oyin sí iwájú yín, tí ó lé wọn kúrò ní iwájú yín, àní ọba Amori méjì. Ẹ kò ṣe èyí pẹ̀lú idà yín àti ọrun yín.
13 И дадох ви земя на която не бяхте положили труд, и градове, които не бяхте съградили, и вие живеете в тях; и ядете от лозя и маслини, които не сте садили.
Bẹ́ẹ̀ ni mo fún un yín ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò ṣiṣẹ́ fún, àti àwọn ìlú tí ẹ̀ yin kò kọ́; ẹ sì ń gbé inú wọn, ẹ sì ń jẹ nínú ọgbà àjàrà àti ọgbà olifi tí ẹ kò gbìn.’
14 Сега, прочее, бойте се от Господа, и служете Му с искреност и истина; и махнете боговете, на които служеха бащите ви оттатък реката и в Египет, и служете Господу.
“Nísinsin yìí ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì máa sìn ín ní òtítọ́ àti òdodo. Kí ẹ sì mú òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate àti ní Ejibiti kúrò, kí ẹ sì máa sin Olúwa.
15 Но ако ви се види тежко да служите Господу, изберете днес кому искате да служите, - на боговете ли, на които служиха бащите ви оттатък реката, или на боговете на аморейците, в чиято земя живеете; но аз и моят дом ще служим Господу.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fẹ́ láti sin Olúwa, nígbà náà ẹ yàn fún ara yín ní òní ẹni tí ẹ̀yin yóò sìn bóyá òrìṣà tí àwọn baba ńlá yín sìn ní ìkọjá odò Eufurate, tàbí òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé. Ṣùgbọ́n ní ti èmi àti ilé mi, Olúwa ni àwa yóò máa sìn.”
16 И людете в отговор казаха: Не дай, Боже, да оставим Господа, за да служим на други богове!
Àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Kí a má ri tí àwa yóò fi kọ Olúwa sílẹ̀ láti sin òrìṣà!
17 защото Господ нашият Бог, Той е, Който изведе нас и бащите ни из Египетската земя, от дома на робството, и Който извърши пред нас ония големи знамения, и ни опази през целия път, по който пътувахме, и между всичките племена, през сред които минахме.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni ó gba àwọn baba ńlá wa là kúrò ní Ejibiti, ní oko ẹrú. Òun ni Ọlọ́run tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá níwájú àwọn ọmọ Israẹli. Ó pa wá mọ́ nínú gbogbo ìrìnàjò wa àti ní àárín gbogbo orílẹ̀-èdè tí a là kọjá.
18 Тоже Господ изгони от пред нас всичките племена, аморейците, които живееха в тая земя. За това и ние ще служим Господу, защото Той е нашият Бог.
Olúwa sì lé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè jáde kúrò ní iwájú wa, pẹ̀lú àwọn Amori, tí ń gbé ilẹ̀ náà. Àwa náà yóò máa sin Olúwa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa.”
19 Но Исус каза на людете: Не ще можете да служите Господу; защото Той е Бог пресвет; Той е Бог ревнив; не ще да прости престъпленията и греховете ви.
Joṣua sì wí fún àwọn ènìyàn náà, pé, “Ẹ̀yin kò le sin Olúwa, nítorí Ọlọ́run mímọ́ ni òun; Ọlọ́run owú ni òun, kì yóò dárí ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín.
20 Защото, ако оставите Господа и служите на чужди Богове тогава Той ще се обърне и ще ви стори зло и ще ви изтреби, въпреки добрата, което ви е сторил.
Bí ẹ bá kọ Olúwa tí ẹ sì sin òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn òun yóò padà yóò sì mú ibi bá a yín, yóò sì pa yín run, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣe rere fún un yín tan.”
21 А людете казаха на Исуса: Не, но Господу ще служим.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn sọ fún Joṣua pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! A yàn láti sin Olúwa.”
22 Тогава Исус каза на людете: Вие сте свидетели против себе си, че си избрахте Господа, за да Му служите; (и те рекоха: Свидетели сме);
Lẹ́yìn náà ni Joṣua wí pé, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ara yín pé, ẹ ti yàn láti sin Olúwa.” Wọ́n dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí.”
23 сега, прочее, махнете чуждите богове, които са всред вас, и преклонете сърцата си към Господа Израилевия Бог.
Nígbà náà ni Joṣua dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárín yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.”
24 И людете казаха на Исуса: На Господа нашия Бог ще служим, и Неговия глас ще слушаме.
Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Joṣua pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí.”
25 И тъй, в същия ден Исус направи завет с людете, и им постави закон и постановление в Сихем.
Ní ọjọ́ náà Joṣua dá májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Ṣekemu.
26 И Исус написа тия думи в книгата на Божия закон; и взе голям камък та го изправи там подир дъба, който е близо при Господното светилище.
Joṣua sì kọ gbogbo ìdáhùn àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí inú Ìwé Òfin Ọlọ́run. Lẹ́yìn náà ó gbé òkúta ńlá kan, ó gbé e kalẹ̀ ní abẹ́ igi óákù ní ẹ̀bá ibi mímọ́ Olúwa.
27 И Исус каза на всичките люде: Ето тоя камък ще ни бъде за свидетел, защото той чу всичките думи, които Господ ни говори, и той ще ви бъде за свидетел, в случай, че се откажете от вашия Бог.
“E wò ó!” ó wí fún gbogbo ènìyàn pé, “Òkúta yìí ni yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí fún wa, nítorí ó ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ fún wa. Yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí yín tí ẹ bá ṣe àìṣòótọ́ sí Ọlọ́run yín.”
28 Така Исус разпусна людете, да отидат всеки в наследството си.
Lẹ́yìn náà ni Joṣua jẹ́ kí àwọn ènìyàn lọ, olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
29 След това, Господният слуга Исус Навиевият син, умря на възраст сто и десет години.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Joṣua ọmọ Nuni ìránṣẹ́ Olúwa, kú ní ẹni àádọ́fà ọdún.
30 И погребаха го в предела на наследството му в Тамнат-сарах, който е в хълмистата земя на Ефрема, на север от хълма Гаас.
Wọ́n sì sin ín sí ilẹ̀ ìní rẹ̀, ní Timnati Serah ni ilẹ̀ orí òkè Efraimu, ní ìhà àríwá òkè Gaaṣi.
31 И Израил служи на Господа през всичките дни на Исуса, и през всичките дни на старейшините, които преживяха Исуса, и които знаеха всичките дела, които Господ бе извършил за Израиля.
Israẹli sì sin Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé Joṣua àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbàgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Israẹli.
32 И в Сихем погребаха Иосифовите кости, които израилтяните изнесоха из Египет, в местността на нивата, която Яков купи за сто сребърника от синовете на Емора, Сихемовия баща; и тя стана наследство на Иосифовите потомци.
Egungun Josẹfu, èyí tí àwọn ọmọ Israẹli kó kúrò ní Ejibiti, ni wọ́n sin ní Ṣekemu ní ìpín ilẹ̀ tí Jakọbu rà fún ọgọ́rùn-ún fàdákà ní ọwọ́ Hamori, baba Ṣekemu. Èyí sì jẹ́ ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Josẹfu.
33 И Елеазар Аароновият син умря; и погребаха го на хълма на сина му Финееса, който му бе даден в хълмистата земя на Ефрема.
Eleasari ọmọ Aaroni sì kú, wọ́n sì sin ín ní Gibeah, tí a ti pín fún ọmọ rẹ̀ Finehasi ní òkè ilẹ̀ Efraimu.

< Исус Навиев 24 >