< Исус Навиев 2 >

1 Тогава Исус Навиевият син изпрати от Ситим двама мъже да съгледат тайно, и каза: Идете, разгледайте земята и Ерихон. И отидоха, и като влязоха в къщата на една блудница на име Раав, престояха там.
Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
2 Но известиха на ерихонския цар, казвайки: Ето, нощес дойдоха тук мъже от израилтяните, за да съгледат земята.
A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
3 И тъй, ерихонският цар прати в Раав да кажат: Изведи мъжете, които дойдоха при тебе, и които влязоха в къщата ти; защото са дошли да съгледат цялата земя.
Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
4 Но жената взе двамата мъже та ги скри; и рече: Наистина мъжете дойдоха при мене, но не знаех от где бяха;
Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
5 и като щяха да се затворят портите, на мръкване, мъжете излязоха. Не зная къде отидоха мъжете; тичайте скоро след тях и ще ги стигнете.
Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
6 Но тя ги беше качила на къщния покрив, и бе ги скрила в ленените гръсти, които беше наредила на къщния покрив.
(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
7 И изпратените мъже ги гониха по пътя, който отива за Иордан, гониха ги до бродовете; и щом тръгнаха ония, които ги подгониха, затвориха портата.
Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
8 А преди те да си легнат, тя се качи при тях на къщния покрив
Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
9 и рече на мъжете: Зная, че Господ ви даде тая земя и страх от вас ни нападна, и всичките жители на тая земя се стопиха пред вас;
Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
10 понеже чухме как Господ пресуши водата на Червеното море пред вас, когато излязохте то Египет, и какво направихте на двамата аморейски царе, които бяха оттатък Иордан, - на Сиона и на Ога, които изтребихте.
Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
11 Като чухме сърцата ни се стопиха, и в никого не остана вече душа поради вас; защото Господ вашият Бог, Той е Бог на небето горе и на земята долу.
Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
12 И сега, моля, закълнете ми се в Господа, че както аз показах милост към вас, ще покажете и вие милост към бащиния ми дом; и дайте ми знак за уверение,
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
13 че ще запазите живота на баща ми, на майка ми, на братята ми и на сестрите ми, и всичко що имат, и ще избавите живота ни от смърт.
pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
14 Мъжете й рекоха: Вместо вас ние сме готови да умрем, ако само не издадете тая наша работа: и когато Господ ни даде земята, ще ти покажем милост и вярност.
“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
15 Тогава тя ги спусна с въже през прозореца; защото къщата й беше на градската стена, и на стената живееше.
Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
16 И рече им: Идете в гората, за да не ви срещнат гонителите и крийте се там три дена догде се върнат гонителите; и после си идете по пътя.
Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
17 И мъжете й рекоха: Ето как ще бъдем свободни от тая клетва, с която ти ни направи да се закълнем:
Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
18 ето, когато влезем в земята, да вържеш това въже от червена прежда на прозореца, през който ти ни спусна; а баща си и майка си братята си и целия си бащин дом да събереш при себе си в къщи.
Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
19 Всеки, който би излязъл из вратата на къщата ти кръвта му ще бъде на главата му, а ние ще бъдем невинни; на всеки, който остане с тебе в къщи, неговата кръв ще бъде на нашата глава, ако се издигне ръка против него.
Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
20 Обаче, ако издадеш тая наша работа, тогава пак ще бъдем свободни от клетвата, с която ти ни направи да се закълнем.
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
21 А тя каза: Да бъде според както сте казали. И изпрати ги та си отидоха; и тя върза червеното въже на прозореца.
Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
22 И като тръгнаха отидоха в гората, и там останаха три дена догде се върнаха гонителите; а гонителите ги търсиха по целия път, но не ги намериха.
Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
23 Тогава двамата мъже се върнаха и като слязоха от гората, преминаха и дойдоха при Исуса Навиевия син; и казаха му всичко що се бе случило.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
24 И рекоха на Исуса: Наистина Господ предаде в ръцете ни цялата земя; а при това, всичките местни жители се стопиха пред нас.
Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”

< Исус Навиев 2 >