< Йов 4 >

1 Тогава теманецът Елифаз проговаряйки рече:
Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé,
2 Ако започнем да ти говорим, ще ти дотегне ли? Но кой може се въздържа да не говори?
“Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́? Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
3 Ето, ти си научил мнозина, И немощни ръце си укрепил.
Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn, ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
4 Твоите думи са заякчили колебаещия, И отслабнали колене си укрепил.
Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró, ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
5 А сега това дойде на тебе, и ти е дотегнало; Допира те, и смутил си се.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́; ara rẹ kò lélẹ̀.
6 В страха ти от Бога не е ли твоето упование, И в правотата на пътищата ти твоята надежда?
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?
7 Спомни си, моля, кой някога е погивал невинен, Или где са били изтребени праведните.
“Èmi bẹ̀ ọ́ rántí, ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀? Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
8 До колко съм аз видял, ония, които орат беззаконие, И сеят нечестие, това и жънат.
Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀, tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
9 Изтребват се от дишането на Бога, И от духането на ноздрите Му погиват.
Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé, nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
10 Ревът на лъва и гласът на свирепия лъв замират, И зъбите на младите лъвове се изкъртват.
Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
11 Лъвът загива от нямане лов, И малките на лъвицата се разпръсват.
Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ, àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.
12 Тайно достига до мене едно нещо, И ухото ми долови един шепот от него:
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi, etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
13 Всред мислите от нощните видения, Когато дълбок сън напада човеците,
Ní ìrò inú lójú ìran òru, nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
14 Ужас ме обзе, и трепет, И разтърси всичките ми кости;
Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
15 Тогава дух премина пред мене; Космите на тялото ми настръхнаха;
Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi, irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
16 Той застана, но не можах да позная образа му; Призрак се яви пред очите ми; В тишина чух тоя глас:
Ó dúró jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀, àwòrán kan hàn níwájú mi, ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé,
17 Ще бъде ли смъртен човек праведен пред Бога? Ще бъде ли човека чист пред Създателя си?
‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run, ènìyàn ha le mọ́ ju ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
18 Ето, Той не се доверява на слугите Си, И на ангелите Си намира недостатък,
Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
19 Колко повече в ония, които живеят в къщи от кал. Чиято основа е в пръстта, И които се смазват като че ли са молци!
Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀, ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀ tí yóò di rírun kòkòrò.
20 Между заранта и вечерта се събират, Без да усети някой загубват се за винаги.
A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́ wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
21 Величието, което е в тях, не се ли премахва? Умират и то без мъдрост.
A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí? Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’

< Йов 4 >