< Йов 31 >

1 Направих завет с очите си; И как бих погледнал на девица?
“Mo ti bá ojú mi dá májẹ̀mú, èmi yó ha ṣe tẹjúmọ́ wúńdíá?
2 Защото какъв дял се определя от Бога отгоре, И какво наследство от Всемогъщия свише?
Nítorí pé kí ni ìpín Ọlọ́run láti ọ̀run wá? Tàbí kí ni ogún Olódùmarè láti òkè ọ̀run wá.
3 Не е ли разорение за нечестивия, И погибел за тия, които вършат беззаконие?
Kò ṣe pé àwọn ènìyàn búburú ni ìparun wà fún, àti àjàkálẹ̀-ààrùn fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀?
4 Не вижда ли Той пътищата ми? И не брои ли всичките ми стъпки?
Òun kò ha ri ipa ọ̀nà mi, òun kò ha sì ka gbogbo ìṣísẹ̀ mi?
5 Ако съм ходил с лъжата, И ногата ми е бързала на измама,
“Bí ó bá ṣe pé èmi bá fi àìṣòótọ́ rìn, tàbí tí ẹsẹ̀ mi sì yára sí ẹ̀tàn,
6 (Но нека ме претеглят в прави везни, За да познае Бог непорочността ми, -)
(jẹ́ kí Ọlọ́run wọ́n mí nínú ìwọ̀n òdodo, kí Ọlọ́run le mọ ìdúró ṣinṣin mi.)
7 Ако се е отклонила ногата ми от пътя, И сърцето ми е последвало очите ми, И ако е залепило петно на ръцете ми,
Bí ẹsẹ̀ mí bá yà kúrò lójú ọ̀nà, tí àyà mí sì tẹ̀lé ipa ojú mi, tàbí bí àbàwọ́n kan bá sì lẹ̀ mọ́ mi ní ọwọ́,
8 То нека сея аз, а друг да яде, И нека се изкоренят произведенията ми
ǹjẹ́ kí èmi kí ó gbìn kí ẹlòmíràn kí ó sì mújẹ, àní kí a fa irú-ọmọ mi tu.
9 Ако се е прелъстило сърцето ми от жена, И съм причаквал при вратата на съседа си,
“Bí àyà mi bá di fífà sí ipasẹ̀ obìnrin kan, tàbí bí mo bá lọ í ba de ènìyàn ní ẹnu-ọ̀nà ilé aládùúgbò mi,
10 То нека моята жена меле за другиго, И други да се навеждат над нея;
kí àyà mi kí ó lọ ọlọ fún ẹlòmíràn, kí àwọn ẹlòmíràn kí ó tẹ̀ ara wọn ní ara rẹ̀.
11 Защото това би било гнусно дело, И беззаконие, което да се накаже от съдиите;
Nítorí pé yóò jẹ́ ohun ìtìjú àní, ẹ̀ṣẹ̀ tí a ó ṣe onídàájọ́ rẹ̀.
12 Понеже това е огън, който изгорява до погубване, И би изкоренил всичките ми плодове.
Nítorí pé iná ní èyí tí ó jó dé ibi ìparun, tí ìbá sì fa gbòǹgbò ohun ìbísí mi gbogbo tu.
13 Ако съм презрял правото на слугата си или на слугинята си, Когато имаха спор с мене,
“Tí mo bá sì ṣe àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrin mi tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí, nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;
14 То какво бих сторил, когато се подигне Бог? И какво бих Му отговорил, когато посети?
kí ni èmi ó ha ṣe nígbà tí Ọlọ́run bá dìde? Nígbà tí ó bá sì ṣe ìbẹ̀wò, ohùn kí ni èmi ó dá?
15 Оня, който е образувал мене в утробата, не образува ли и него? И не същия ли ни образува в утробата?
Ẹni tí ó dá mi ní inú kọ́ ni ó dá a? Ẹnìkan náà kí ó mọ wá ní inú ìyá wa?
16 Ако съм въздържал сиромасите от това, което желаеха, Или съм направил да помрачеят очите на вдовицата,
“Bí mo bá fa ọwọ́ sẹ́yìn fún ìfẹ́ inú tálákà, tàbí bí mo bá sì mú kí ojú opó rẹ̀wẹ̀sì,
17 Или съм изял сам си залъка си, Без да е яло сирачето от него,
tàbí tí mo bá nìkan bu òkèlè mi jẹ, tí aláìní baba kò jẹ nínú rẹ̀;
18 (Напротив, от младостта ми то порасте при мене като при баща, И от утробата на майка си съм наставлявал вдовицата; )
nítorí pé láti ìgbà èwe mi wá ni a ti tọ́ ọ dàgbà pẹ̀lú mi bí ẹni pé baba, èmi sì ń ṣe ìtọ́jú opó láti inú ìyá mi wá:
19 Ако съм гледал някого да гине от нямане дрехи, Или сиромах, че няма завивка,
bí èmi bá rí olùpọ́njú láìní aṣọ, tàbí tálákà kan láìní ìbora;
20 И не са ме благославяли чреслата му, Като се е стоплял с вълната от овцете ми;
bí ọkàn rẹ̀ kò bá súre fún mi, tàbí bí ara rẹ̀ kò sì gbóná nípasẹ̀ irun àgùntàn mi;
21 Ако съм подигнал ръка против сирачето, Като виждах, че имам помощ в портата;
bí mo bá sì gbé ọwọ́ mi sókè sí aláìní baba, nítorí pé mo rí ìrànlọ́wọ́ mi ní ẹnu ibodè,
22 То да падне мишцата ми от рамото, И ръката ми да се пречупи от лакътя;
ǹjẹ́, ní apá mi kí o wọ́n kúrò ní ihò èjìká rẹ̀, kí apá mi kí ó sì ṣẹ́ láti egungun rẹ̀ wá.
23 Защото погибел от Бога беше ужас за мене, И пред Неговото величие не можех да сторя нищо.
Nítorí pé ìparun láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ẹ̀rù ńlá fún mi, àti nítorí ọláńlá rẹ̀ èmi kò le è dúró.
24 Ако съм турял надеждата си в злато, Или съм рекъл на чистото злато: Ти си мое упование;
“Bí ó bá ṣe pé mo fi wúrà ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé mi, tàbí tí mo bá wí fún fàdákà dídára pé, ‘Ìwọ ni ààbò mi,’
25 Ако съм се веселил, защото богатството ми бе голямо, И защото ръката ми бе намерила изобилие;
bí mo bá yọ̀ nítorí ọrọ̀ mí pọ̀, àti nítorí ọwọ́ mi dara lọ́pọ̀lọ́pọ̀,
26 Ако, като съм гледал слънцето, когато изгряваше, Или луната, когато ходеше в светлостта си,
bí mo bá bojú wo oòrùn nígbà tí ń ràn, tàbí òṣùpá tí ń ràn nínú ìtànmọ́lẹ̀,
27 Се е увлякло тайно сърцето ми, И устата ми са целували ръката ми;
bí a bá tàn ọkàn mi jẹ láti fi ẹnu mi kò ọwọ́ mi,
28 И това би било беззаконие, което да се накаже от съдиите, Защото бих се отрекъл от Всевишния Бог.
èyí pẹ̀lú ni ẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn onídàájọ́ ní láti bẹ̀wò, nítorí pé èmí yóò jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run tí ó wà lókè.
29 Ако съм злорадствувал в загиването на мразещия ме, Или ми е ставало драго, когато го е сполетявало зло,
“Bí ó bá ṣe pé mo yọ̀ sì ìparun ẹni tí ó kórìíra mi. Tàbí bí mo bá sì gbéraga sókè, nígbà tí ibi bá a.
30 (Даже не съм допуснал на устата си да съгрешат Та да иксам живота му с проклетия);
Bẹ́ẹ̀ èmi kò sì jẹ ki ẹnu mi ki ó ṣẹ̀ nípa fífẹ́ ègún sí ọkàn rẹ̀.
31 Ако хората от шатъра ми не са рекли: Кой може да покаже едного, който не е бил наситен от него с месо?
Bí àwọn ènìyàn inú àgọ́ mi kò bá lè wí pé, ‘Ta ni kò ì tí ì jẹ ẹran rẹ̀ ní àjẹyó?’
32 (Чужденец не нощуваше вън; Отварях вратата си на пътника);
Àlejò kò wọ̀ ni ìgboro rí; èmí ṣí ìlẹ̀kùn mi sílẹ̀ fún èrò.
33 Ако съм покривал престъпленията си както Адама Като съм скривал беззаконието си в пазухата си,
Bí mo bá bò ẹ̀ṣẹ̀ mi mọ́lẹ̀ bí Adamu ni pápá, ẹ̀bi mi pamọ́ ni àyà mi.
34 Понеже се боях от голямото множество, И презрението на семействата ме ужасяваше, Така че млъквах и не излизах из вратата;
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni mo ha bẹ̀rù bí? Tàbí ẹ̀gàn àwọn ìdílé ní ń bà mí ní ẹ̀rù? Tí mo fi pa ẹnu mọ́, tí èmí kò sì fi sọ̀rọ̀ jáde?
35 (О, да имаше някой да ме слуша! - Ето виж тука подписа ми; Всемогъщият нека ми отговори!- И да имах акта който противникът ми е написал!
(“Ìbá ṣe pé ẹnìkan le gbọ́ ti èmí! Kíyèsi i, àmì mi, kí Olódùmarè kí ó dá mi lóhùn, kí èmí kí ó sì rí ìwé náà tí olùfisùn mi ti kọ.
36 Ето, на рамо щях да го нося, За венец щях да го привържа на себе си!
Nítòótọ́ èmí ìbá gbé le èjìká mi, èmi ìbá sì dé bí adé mọ́ orí mi.
37 Щях да му дам отчет за стъпките си; Като княз щях да се приближа при него-)
Èmi ìbá sì sọ iye ìṣísẹ̀ mi fún un, bí ọmọ-aládé ni èmi ìbá súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀.)
38 Ако нивата ми вика против мене, И браздите й плачат заедно;
“Bí ilẹ̀ mi bá sì ké rara lòdì sí mi tí a sì fi omijé kún gbogbo poro rẹ̀.
39 Ако съм изял плода й без да платя, Или съм изгасил живота на стопаните й;
Bí mo bá jẹ èso oko mi láìsan owó tàbí tí mo sì mú ọkàn olúwa rẹ̀ fò lọ,
40 Тогава да израстат тръни вместо жито, И вместо ечемик плевели. Свършиха се думите на Иова.
kí ẹ̀gún òṣùṣú kí ó hù dípò alikama, àti èpò búburú dípò ọkà barle.” Ọ̀rọ̀ Jobu parí.

< Йов 31 >