< Йов 21 >

1 Тогава Иов в отговор рече:
Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
2 Слушайте внимателно говоренето ми, И с това ме утешавайте.
“Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
3 Потърпете ме, и аз ще говоря; А след като изговоря, присмивайте се.
Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
4 За човека ли се оплаквам аз? А как да се не утесни духът ми?
“Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
5 Погледнете на мене, и почудете се, И турете ръка на устата си.
Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
6 Само да си наумя тия въпроси ужасявам се, И трепет обзема снагата ми.
Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
7 Защо живеят нечестивите, Остаряват; даже стават и много силни.
Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
8 Чадата им се утвърждават заедно с тях пред лицето им, И внуците им пред очите им.
Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
9 Домовете им са свободни от страх; И Божията тояга не е върху тях.
Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
10 Говедата им се гонят и не напразно; Юницата им се тели, и не помята.
Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
11 Пущат чадата си като овце; И децата им скачат.
Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
12 Пеят при музиката на тъпанчето и арфата, И веселят се при звука на свирката.
Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
13 Прекарват дните си в благополучие; И в една минута слизат в гроба. (Sheol h7585)
Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
14 Все пак казват Богу: Оттегли се от нас, Защото не искаме да знаем пътищата Ти.
Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
15 Що е Всемогъщият, та да Му служим? И какво се ползваме, като Го призоваваме?
Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
16 Ето, щастието им не е в тяхна ръка; Далеч да бъде от мене мъдруването на нечестивите!
Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
17 Колко често изгасва светилникът на нечестивите, И дохожда бедствието им върху тях! Бог им разпределя болезни в гнева Си.
“Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
18 Те са като плява пред вятъра, И като прах от плява, който вихрушката отвява.
Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
19 Думате, Бог пази наказанието на тяхното беззаконие за чадата им. По-добре нека въздаде на сами тях, за да го усещат;
Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
20 Собствените им очи нека видят гибелта им, И сами те нека пият от гнева на Всемогъщия.
Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
21 Защото какво наслаждение от дома си има нечестивият след себе си, Когато се преполови числото на месеците му?
Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
22 Ще научи ли някой Бога на знание, Тъй като Той съди високите?
“Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
23 Един умира в пълно благополучие, Като е във всичко охолен и спокоен;
Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
24 Ребрата му са покрити с тлъстина, И костите му са напоени с мозък.
Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
25 А друг умира в душевна горест, Като никога не е ял с весело сърце.
Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
26 Заедно лежат в пръстта, И червеи ги покриват.
Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
27 Ето, зная мислите ви И хитруванията ви за съсипването ми.
“Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
28 Защото думате: Где е къщата на княза? И где е шатърът, гдето живееха нечестивите?
Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
29 Не сте ли попитали минаващите през пътя? И не разбирате ли бележитите им примери,
Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
30 Че нечестивият се пази за ден на погибел, И че в ден на гняв ще бъде закаран?
pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
31 Кой ще изяви пред лицето му неговия път? И кой ще му въздаде за онова, което е сторил?
Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
32 Но и той ще бъде донесен в гроба, И ще пази над гробницата си.
Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
33 Буците на долината ще му бъдат леки; И всеки човек ще отиде подир него, Както безбройни са отишли преди него,
Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
34 Как, прочее, ми давате празни утешения, Тъй като в отговорите ви остава само лъжа?
“Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”

< Йов 21 >