< Йов 20 >
1 Тогава нааматецът Софар в отговор рече:
Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
2 Понеже ме карат мислите ми да отговоря, Затова бързам.
“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
3 Чух укорително изобличение против мене; И духът на разума ме кара да отговоря.
Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
4 Не знаеш ли това от старо време, От когато е поставен човек на земята,
“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
5 Че тържеството на нечестивите е кратковременно, И радостта на безбожния е минутна?
pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
6 Макар величието му да се издигне до небето, И главата му да стигне до облаците.
Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
7 Пак той ще се изрине за винаги, както нечистотиите му; Ония, които са го гледали, ще кажат, Где е той?
ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
8 Като сън ще отлети и няма да се намери, И като нощно видение ще изчезне.
Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
9 Окото, което го е гледало, не ще го гледа вече; И мястото му няма да го види вече.
Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
10 Чадата му ще потърсят благоволението на сиромасите; И ръцете му ще повърнат имота им.
Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
11 Костите му са пълни със съгрешенията на младостта му; И те ще лежат с него в пръстта.
Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
12 Ако и да е сладко злото в устата му, Та го крие под езика си.
“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
13 Ако и да го жали и не го оставя, Но все още го държи вътре в устата си,
bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
14 Пак храната му ще се измени в червата му, На жлъчка аспидна ще се обърне във вътрешностите му.
ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
15 Погълнал е богатство, но ще го повърне; Бог ще го изтръгне из корема му.
Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
16 Отрова аспидна ще суче; Език ехиднин ще го умъртви.
Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
17 Няма вече да гледа потоците, Реките, които текат с мед и масло.
Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
18 Това, за което се трудим, ще го възвърне, И няма да се наслаждава на него; Съразмерно с имота, който е придобил, Той няма да се радва,
Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
19 Защото е угнетил сиромасите и ги е оставил; Заграбил е къща, която не бе построил.
Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
20 Понеже не е знаел насита на лакомството си, Няма да запази нищо от това, което му е най-мило;
“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
21 Понеже не остана нищо, което не изпояде, Затова благоденствието му няма да трае.
Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
22 Когато е в пълно изобилие, ще го сполети оскъдност; Ръката на всеки окаяник ще го нападне.
Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
23 Когато се кани да напълни корема си, Бог ще хвърли върху него яростния Си гняв, И ще го навали върху него, когато още яде.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
24 Когато бяга от желязното оръжие, Стрелата на медния лък ще го прониже.
Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
25 Той я изтръгва, и тя излиза из тялото му, Да! лъскавият й връх излиза из жлъчката му; Ужаси го обземат.
O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
26 Всякаква тъмнина е запазена за съкровищата му; Огън нераздухван от човек ще го пояде; На тия, които останат в шатъра му, зле ще им бъде.
òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
27 Небето ще открие беззаконието му, И земята ще се повдигне против него.
Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
28 Богатството на дома му ще изчезне, В деня на Божия гняв ще се разпилее.
Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
29 Това е от Бога делът на нечестивия, И определеното му от Бога наследство.
Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”