< Еремия 42 >

1 Тогава всичките военачалници, и Иоанан Кариевият син, и Езания Осаиевият син, и всичките люде, от най-скромен до най-велик, пристъпиха,
Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
2 та рекоха на пророк Еремия: Молим, нека бъде молбата ни приятна пред тебе, и помоли се за нас - за тия, всички които остават - на Господа твоя Бог, (защото от мнозина останахме малцина, както очите ти ни виждат),
Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
3 да ни изяви Господ твоят Бог пътя, по който трябва да ходим и какво трябва да правим.
Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
4 Тогава пророк Еремия им рече: Чух. Ето, ще се помоля на Господа вашия Бог според думите ви; и каквото ви отговори Господ ще ви го известя; няма да скрия нищо от вас.
Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
5 Тогава те рекоха на Еремия: Господ да бъде истинен и верен свидетел между нас, че наистина ще постъпим според всичките думи, с които Господ твоят Бог ще те прати до нас.
Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
6 Било добро или зло, ще послушаме гласа на Господа нашия Бог, при Когото те пращаме, за да ни бъде добре, когато послушаме гласа на Господа нашия Бог.
Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
7 И подир десет дни Господното слово дойде към Еремия.
Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
8 Тогава той повика Иоанана Кариевия син, всичките военачалници, които бяха с него, и всичките люде, от най-скромен до най-велик, та им рече:
O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
9 Така казва Господ, Израилевият Бог, при когото ме пратихте, за да сложа молбата ви пред него:
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
10 Ако следвате да живеете в тая земя, Тогава ще ви съградя, и няма да ви разоря; Защото се разкаях за злото, което ви сторих.
Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
11 Не бойте се от вавилонския цар, От когото се страхувахте, Не бойте се от него, казва Господ; Защото Аз съм с вас за да ви спася И да ви избавя от ръката му.
Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
12 Ще ви покажа милост, Тъй щото той да ви пожали И да ви върне в земята ви.
Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
13 Но ако кажете: Не щем да живеем в тая земя, И не послушате гласа на Господа вашия Бог,
“Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
14 И речете: Не; но ще идем в Египетската земя, Гдето няма да видим война, Нито да чуем тръбен глас. Нито да огладнеем за хляб, И там ще живеем,
Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
15 Тогава слушайте словото Господно, вие останали от Юда - Така казва Господ на Силите, Израилевият Бог: Ако положително насочите лицата си да влезете в Египет, И отидете да пришелствувате там,
nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
16 Тогава ножът, от който се боите, Ще ви стигне там в Египетската земя, И гладът, от който се страхувате, Ще ви преследва там в Египет; И там ще измрете.
Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
17 Така ще стане и с всичките мъже, Които биха насочили лицата си да отидат в Египет, За да пришелствуват там; Те ще измрат от нож, от глад и от мор; Ни един от тях няма да остане, или да избегне от злото, Което Аз ще докарам върху тях.
Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
18 Защото така казва Господ на Силите, Израилевият Бог: Както гневът Ми и яростта Ми се изляха Върху Ерусалимските жители. Така яростта Ми ще се излее върху вас, Когато влезете в Египет; И ще бъдете за проклинание и за учудване, За проклетия и за укоряване; И няма да видите вече това място.
Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
19 Господ е говорил за вас, останали от Юда, казвайки: Не отивайте в Египет; знайте добре, че днес ви заявявам това.
“Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
20 Защото вие постъпихте лукаво против своите души, когато ме пратихте при Господа вашия Бог и казахте: Помоли се за нас на Господа нашия Бог, и извести ни всичко това, което Господ нашият Бог ще рече, и ще го сторим.
pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
21 Аз днес ви известих, но вие не послушахте гласа на Господа вашия Бог в нищо, за което ме прати при вас.
Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
22 Сега, прочее, знайте добре, че ще измрете от нож, от глад и от мор на мястото, гдето желаете да отидете, за да пришелствувате там.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”

< Еремия 42 >