< Еремия 37 >
1 А вместо Иехония, Иоакимовия син, се възцари цар Седекия, Иосиевият син, когото вавилонският цар Навуходоносор постави цар в Юдовата земя.
Sedekiah ọmọ Josiah sì jẹ ọba ní ipò Jehoiakini ọmọ Jehoiakimu ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli fi jẹ ọba ní ilẹ̀ Juda.
2 Но ни той, ни слугите му, ни людете на земята, послушаха думите на Господа, които говори чрез пророк Еремия.
Ṣùgbọ́n àti òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kò fetísí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípa wòlíì Jeremiah.
3 И цар Седекия изпрати Еухала, Селемиевия син и Софония, син на свещеник Маасия, при пророк Еремия да рекат: Моля, помоли се за нас на Господа нашия Бог.
Sedekiah ọba sì rán Jehukali ọmọ Ṣelemiah àti Sefaniah ọmọ Maaseiah sí Jeremiah wòlíì wí pé, “Jọ̀wọ́ gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
4 Защото Еремия още влизаше и излизаше между людете, понеже не бяха го турили в тъмница.
Nígbà yìí Jeremiah sì ń wọlé, ó sì ń jáde láàrín àwọn ènìyàn nítorí wọ́n ti fi sínú túbú.
5 И Фараоновата войска излезе от Египет; и когато халдейците, които обсаждаха Ерусалим, чуха това известие за тях, оттеглиха се от Ерусалим.
Àwọn ọmọ-ogun Farao ti jáde kúrò nílẹ̀ Ejibiti àti nígbà tí àwọn ará Babeli tó ń ṣàtìpó ní Jerusalẹmu gbọ́ ìròyìn nípa wọn, wọ́n kúrò ní Jerusalẹmu.
6 Тогава дойде Господното слово към пророк Еремия и рече:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì Ọlọ́run wá:
7 Така казва Господ, Израилевият Бог: По тоя начин да говорите на Юдовия цар, който ви прати при Мене да се допитате до Мене: Ето, Фараоновата войска, която излезе да ви помага, ще се върне в земята си Египет.
“Èyí ni, ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ fún ọba àwọn Juda tó rán ọ láti wádìí nípa mi. ‘Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáde láti kún ọ lọ́wọ́ yóò padà sílẹ̀ wọn sí Ejibiti.
8 И халдейците пак ще дойдат и ще воюват против тоя град, ще го превземат, и ще го изгорят с огън.
Nígbà náà ni àwọn ará Babeli yóò padà láti gbógun ti ìlú. Wọn yóò mú wọn nígbèkùn, wọn yóò sì fi iná jó ìlú náà kanlẹ̀.’
9 Така казва Господ: Недейте се мами да казвате: Халдейците непременно ще се оттеглят от нас; понеже те няма да се оттеглят.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹ má ṣe tan ara yín jẹ ní èrò wí pé, ‘Àwọn ará Babeli yóò fi wá sílẹ̀ pẹ̀lú ìdánilójú.’ Wọn kò ní ṣe bẹ́ẹ̀.
10 Защото даже ако поразите цялата войска на халдейците, които воюват против вас, и оцелеят от тях само някои ранени, пак те ще станат всеки от шатъра си и ще изгорят тоя град с огън.
Kódà tó bá ṣe pé wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọmọ-ogun Babeli tí ń gbóguntì yín àti àwọn tí ìjàǹbá ṣe, tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ibùdó wọn; wọn yóò jáde láti jó ìlú náà kanlẹ̀.”
11 И когато войската на халдейците беше се оттеглила от Ерусалим поради страха от Фараоновата войска,
Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ-ogun Babeli ti kúrò ní Jerusalẹmu nítorí àwọn ọmọ-ogun Farao.
12 тогава Еремия излезе от Ерусалим, за да отиде във Вениаминовата земя, и да вземе там дела си заедно с другите люде.
Jeremiah múra láti fi ìlú náà sílẹ̀, láti lọ sí olú ìlú Benjamini láti gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ nínú ohun ìní láàrín àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀.
13 И когато той бе при Ваниаминовата порта, там се намираше началника на стражата, чието име бе Ирия, син на Селемия Ананиевия син; и той хвана пророк Еремия и рече: Ти бягаш при халдейците.
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ẹnu ibodè Benjamini, olórí àwọn olùṣọ́ tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Irijah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Hananiah mú un, ó wí pé, “Ìwọ ń fi ara mọ́ àwọn ará Babeli.”
14 А Еремия рече: Лъжа е; аз не бягам при халдейците. Но Ирия не го послуша, но хвана Еремия та го заведе при първенците.
Jeremiah sọ wí pé, “Èyí kì í ṣe òtítọ́! Èmi kò yapa sí àwọn ará Babeli.” Ṣùgbọ́n Irijah ko gbọ́ tirẹ̀, dípò èyí a mú Jeremiah, ó sì mú un lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ìjòyè.
15 И първенците се разгневиха на Еремия та го биха, и туриха го в тъмница в къщата на писача Ионатан; защото нея бяха направили на тъмница.
Nítorí náà ni àwọn ìjòyè ṣe bínú sí Jeremiah, wọ́n jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n tún fi sí túbú nílé Jonatani akọ̀wé nítorí wọ́n ti fi èyí ṣe ilé túbú.
16 След като Еремия беше влязъл в подземната тъмница и в избите, и Еремия беше седял там много дни,
Wọ́n fi Jeremiah sínú túbú tí ó ṣókùnkùn biribiri; níbi tí ó wà fún ìgbà pípẹ́.
17 тогава цар Седекия прати да го доведат; и царят го попита скришно в двореца си, като рече: Има ли слово от Господа? А Еремия рече: Има. Каза още: Ти ще бъдеш предаден в ръката на вавилонския цар.
Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ sí i, tí ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n mú wá sí ààfin níbi tí ó ti bi í ní ìkọ̀kọ̀ pé, “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ kan wà láti ọ̀dọ̀ Olúwa?” Jeremiah fèsì pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, wọn ó fi ọ́ lé ọwọ́ ọba Babeli.”
18 При това, Еремия рече на цар Седекия: Що съм съгрешил на тебе или на слугите ти или на тия люде, та ме туриха в тъмница?
Nígbà náà, Jeremiah sọ fún ọba Sedekiah pé, “Irú ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ yín, àwọn ìjòyè yín pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ fi sọ mí sínú túbú?
19 Где са сега вашите пророци, които пророкуваха, казвайки: вавилонският цар няма да дойде против вас или против тая земя?
Níbo ni àwọn wòlíì yín tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín wí pé ọba Babeli kò ní gbóguntì yín wá?
20 Затова, слушай сега, моля, господарю мой, царю; нека бъде приета, моля, молбата ми пред тебе щото да не ме накараш да се върна в къщата на писача Ионатана, за да не умра там.
Ṣùgbọ́n ní báyìí, olúwa mi ọba, èmí bẹ̀ ọ. Jẹ́ kí n mú ẹ̀dùn ọkàn mi tọ̀ ọ́ wá; má ṣe rán mi padà sí ilé Jonatani akọ̀wé, àfi kí n kú síbẹ̀.”
21 Тогава цар Седекия заповяда, и предадоха Еремия да бъде пазен в двора на стражата, и даваха му всеки ден по един хляб от улицата на хлебарите, догдето се свърши всичкият хляб на града. И така Еремия седеше в двора на стражата.
Ọba Sedekiah wá pàṣẹ pé kí wọ́n fi Jeremiah sínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, àti kí wọn sì fún ní àkàrà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan títí tí àkàrà tó wà ní ìlú yóò fi tán; bẹ́ẹ̀ ni Jeremiah wà nínú àgbàlá náà.