< Еремия 25 >
1 Словото, което дойде към Еремия за всичките Юдови люде, в четвъртата година на Юдовия цар Иоаким, Иосиевия син, която година бе и първа на Вавилонския цар Навуходоносора,
Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
2 което слово пророк Еремия изговори на всичките Юдови люде и на всичките ерусалимски жители, като казва:
Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
3 От тринадесетата година на Юдовия цар Иосия, Амоновия син, дори до днес, тия двадесет и три години, Господното слово дохождаше към мене; и аз ви говорех; но вие не послушахте.
Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
4 И Господ прати до вас всичките Си слуги пророците, като ставаше рано и ги пращаше, (но не послушахте, нито приклонихте ухо да послушате),
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
5 и те казваха: Върнете се сега всеки от лошия си път и от злите си дела, и населявайте земята, която Господ даде на вас и на бащите ви от века и до века;
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
6 и не отивайте след други богове, за да им служите и да им се кланяте, и не Ме разгневявайте с делата на ръцете си; и Аз няма да ви сторя зло.
Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
7 Но вие не Ме послушахте, казва Господ, като Ме разгневявахте с делата на ръцете си за собственото си зло.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
8 Затова, така казва Господ на Силите: Понеже не послушахте думите Ми,
Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
9 ето, Аз ще изпратя и ще взема всичките северни родове, казва Господ, тоже и слугата Ми Навуходоносора, Вавилонския цар, та ще ги доведа против тая земя, и против нейните жители, и против всички тия околни народи; ще ги обрека на изтребление, и ще ги направя за учудване и за подсвиркване, и ще ги обърна на вечна пустота.
Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
10 При това, ще направя да престане между тях гласът на веселието и гласът на радостта, гласът на младоженеца и гласът на невестата, шумът на мелницата и светенето на светилото.
Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
11 И цялата тая земя ще бъде пуста и за учудване; и тия народи ще робуват на вавилонския цар седемдесет години.
Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
12 А когато се свършат седемдесетте години, Аз ще накажа Вавилонския цар и оня народ за беззаконието им, казва Господ, също и Халдейската земя, която ще обърна във вечна пустота.
“Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
13 И ще докарам върху оная земя всичките неща, които съм говорил против нея, всичко що има писано в тая книга, което Еремия пророкува против всичките народи.
Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
14 Защото много народи и велики царе ще поробят и тях; Аз ще им въздам според делата им и според работата на ръцете им.
Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
15 Защото така ми каза Господ, Израилевият Бог: Вземи от ръката Ми тая чаша с виното на яростта Ми, та напой от нея всичките народи, до които те пращам.
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
16 И като пият, ще политат и обезумеят поради ножа, който ще изпратя всред тях.
Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
17 Тогава взех чашата от ръката на Господа, та напоих всичките народи, при които ме беше изпратил Господа, а именно:
Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
18 Ерусалим и Юдовите градове, с царете им и първенците им, за да ги обърна в пустота, и за да станат за учудване и подсвиркване и проклетия, както са днес;
Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
19 египетският цар Фараона, със слугите му, първенците му, и всичките му люде;
Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
20 всичките разноплеменни люде, всичките царе на земята Уз, и всичките царе на Филистимската земя, с Аскалон, Газа, Акарон, и останалите от Азот;
Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
21 Едома, Моава, и амонците;
Edomu, Moabu àti Ammoni;
22 и всичките тирски царе, всичките сидонски царе, и царете на островите оттатък морето;
gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
23 Дедана, Тема, Вуза, и всички, които си стрижат издадените части на косата;
Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
24 всичките арабски царе, и всичките царе на разноплеменните люде, които населяват пустинята;
Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
25 всичките зимрийски царе, всичките еламски царе, и всичките мидски царе;
Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
26 всичките северни царе, ближните и далечните, едни с други, и всичките царства на света, които са по лицето на земята; а царят на Сесах ще пие подир тях.
Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
27 Затова, ще им речеш - Така казва Господ на Силите, Израилевият Бог: Пийте и опийте се, повръщайте, паднете, и не ставайте вече, поради ножа, който ще изпратя всред вас.
“Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
28 И ако откажат да вземат чашата от ръката ти и да пият, тогава да им речеш: Така казва Господ на Силите: Непременно ще пиете;
Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
29 защото, ето, Аз докарвам зло като започвам от града, който се нарича по Моето име; и вие ли ще останете съвсем ненаказани? Няма да останете ненаказани, защото Аз ще призова нож върху всичките земни жители, казва Господ на Силите.
Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
30 Затова, пророкувай ти против тях всички тия неща, като им кажеш: Господ ще изреве свише, И ще издаде гласа Си от светото Си обиталище; Ще изреве силно против паството Си; Ще извика, като ония, които тъпчат грозде, Против всичките жители на света.
“Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
31 Екотът ще стигне и до краищата на света, Защото Господ има съд с народите; Той ще се съди с всяка твар, Ще предаде нечестивите на нож, казва Господ.
Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
32 Така казва Господ на Силите: Ето, зло ще излезе от народ към народ, И голям ураган ще се подигне От краищата на земята.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
33 В оня ден убитите от Господа ще лежат От единия край на земята до другия край на земята; Няма да бъдат оплакани, нито прибрани, нито погребани; Ще бъдат за тор по повърхността на земята.
Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
34 Лелекайте, пастири и извикайте, И вие, началници на стадото, валяйте се в пръстта; Защото напълно настана времето, за да бъдете заклани и разпръснати, И ще паднете като отбран съд.
Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
35 И пастирите не ще имат средство за избягване, Нито началниците на стадото за избавление.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
36 Глас на вопъл от пастирите, И виене от началниците на стадото! Защото Господ опустошава пасбището им.
Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
37 И мирните кошари занемяха От пламенния гняв на Господа.
Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
38 Той е оставил убежището Си като лъв; Да! земята им стана за учудване От лютостта на насилника, И от яростния Му гняв.
Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.