< Еремия 2 >
1 Словото Господно дойде към мене и рече:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
2 Иди та прогласи в ушите на ерусалимската дъщеря, думайки: Така казва Господ: Помня за тебе Милеенето ти, когато беше млада, Любовта ти, когато беше невеста, Как Ме следваше в пустинята, В непосята земя.
“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
3 Израил беше свет Господу, Първак на рожбите Му; Всички, които го пояждаха, се счетоха за виновни; Зло ги постигаше, казва Господ.
Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
4 Чуйте словото Господно, доме Яковов, И всички родове на Израилевия дом:
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
5 Така казва Господ: Каква неправда намериха в Мене бащите ви, Та се отдалечиха от Мене, И ходиха след суетата, и станаха суетни?
Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
6 Нито рекоха: Где е Господ, Който ни изведе из Египетската земя, Който ни води през пустинята, През страна пуста и пълна с пропасти, През страна, по която не минаваше човек, И гдето човек не живееше?
Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
7 И въведох ви в плодородна страна, За да ядете плодовете й и благата й; Но като влязохте осквернихте земята Ми, И направихте мерзост наследството Ми.
Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
8 Свещениците не рекоха: Где е Господ? Законоведците не Ме познаха; Също и управниците станаха престъпници против мене, И пророците пророкуваха чрез Ваала, И ходиха след безполезните идоли.
Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
9 Затова, Аз още ще се съдя с вас, казва Господ, И с внуците ви ще се съдя.
“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
10 Защото, минете в китимските острови та вижте, Пратете в Кидар, та разгледайте внимателно, И вижте, ставало ли е такова нещо,
Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
11 Разменил ли е някой народ боговете си, при все че не са богове? Моите люде, обаче, са разменили Славата си срещу онова, което не ползува.
Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
12 Ужасете се, небеса, поради това, Настръхнете, смутете се премного, казва Господ.
Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
13 Защото две злини сториха Моите люде: Оставиха Мене, извора на живите води, И си изсякоха щерни, разпукнати щерни, Които не могат да държат вода.
“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
14 Израил слуга ли е? домороден роб ли е? Тогава защо стана пленник?
Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
15 Млади лъвове рикаха против него и реваха, И запустиха земята му; Градовете му са изпогорени и обезлюдени.
Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
16 Още и жителите на Мемфис и на Тафнес Строшиха темето на главата ти.
Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
17 Не докара ли ти това сам на себе си, Като си оставил Господа своя Бог, Когато те водеше в пътя?
Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
18 И сега, защо ти е пътят за Египет? Да пиеш водата на Нил ли? Или защо ти е пътят на Асирия? Да пиеш водата на Ефрат
Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
19 Твоето нечестие ще те накаже, И твоите престъпления ще те изобличат; Познай, прочее, и виж, че е зло и горчиво нещо Гдето си оставил Господа своя Бог, И гдето нямаш страх от Мене, Казва Господ, Иеова на Силите.
Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
20 Понеже отдавна съм строшил хомота ти И съм разкъсал връзките ти; И ти рече: Няма вече да бъда престъпница; А между това, на всеки висок хълм И под всяко зелено дърво Си лягала като блудница.
“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
21 А пък Аз те бях насадил лоза отбрана, Семе съвсем чисто; Тогава ти как си се променила в изродени пръчки на чужда за Мене лоза?
Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
22 Затова, ако и да се умиеш с луга И да употребиш много сапун, Пак твоето беззаконие си остава петно пред Мене, Казва Господ Иеова.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
23 Как можеш да речеш: Не съм се осквернила, Не съм ходила след ваалимите? Виж пътя си в долината, Познай що си сторила, Подобно на камила, която бърже тича насам натам из пътищата,
“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
24 Подобно на дива ослица, свикнала с пустинята, Която в страстта на душата си смърка въздуха; В устрема й кой може да я отвърне? Ония, които я търсят, няма да си дават труд за нея, - В месеца й ще я намерят.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
25 Въздържай ногата си, за да не ходиш боса, И гърлото си, за да не съхне от жажда; Но ти си рекла: Напразно! не; Защото залюбих чужденци, И след тях ще ида.
Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
26 Както се посрамя крадец, когато е открит, Така ще се посрами Израилевият дом - Те, царете им, първенците им, Свещениците им, и пророците им,
“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
27 Които думат на дървото: Ти си мой отец, И на камъка: Ти си ме родил; Защото обърнаха към Мене гърба си, а не лицето си; Но пак във време на бедствието си ще рекат: Стани та ни избави.
Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
28 Но где са твоите богове, които си си направил? Те нека станат, ако могат да те избавят Във време на бедствието ти; Защото колкото са градовете ти Толкова са и боговете ти, Юдо.
Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
29 Защо би искали да се препирате с мене? Вие всички сте отстъпници от Мене, казва Господ.
“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
30 Напразно поразих чадата ви; Те не приеха да се поправят; Собственият ви нож пояде пророците ви Като лъв-изтребител.
“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
31 О, човеци на тоя род, вижте словото на Господа, Който казва: Бил ли съм Аз пустиня за Израиля, Или земя на мрачна тъмнина? Защо тогава казват людете Ми: Ние сме скъсали връзките си, Не щем да дойдем вече при Тебе?
“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
32 Може ли момата да забрави накита си, Или невестата украшенията си? Но людете Ми забравяха Мене през безбройни дни.
Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
33 Как украсяваш пътя си, за да търсиш любов! Така щото си научила и лошите жени на твоите пътища!
Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
34 Тоже и по полите ти се намери кръвта На души - невинни сиромаси; Не намери кървите с разкопаване, но по всички тия поли.
Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
35 А при все това ти казваш: Невинна съм, За туй гневът Му непременно ще се отвърне от мене. Ето, Аз ще се съдя с тебе За гдето казваш: Не съм съгрешила.
ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
36 Защо се луташ толкоз много за да промениш пътя си? Ще се посрамиш и от Египет Както се посрами от Асирия.
Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
37 Ще излезеш и от там С ръцете си на главата си; Защото Господ отхвърли ония, на които уповаваш, И ти няма да успееш в тях.
Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.