< Еремия 11 >

1 Словото, което дойде към Еремия от Господа и каза:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá:
2 Слушайте думите на тоя завет, и говорете на Юдовите мъже и ерусалимските жители; и ти да им речеш:
“Fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí o sì sọ wọ́n fún àwọn ènìyàn Juda, àti gbogbo àwọn tó ń gbé ni Jerusalẹmu.
3 Така казва Господ Израилевият Бог, - Проклет оня човек, който не слуша думите на тоя завет,
Sọ fún wọn wí pé èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ègbé ni fún ẹni náà tí kò pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí mọ́.
4 който заповядах на бащите ви в деня, когато ги изведох из Египетската земя, из железарската пещ, и рекох - Слушайте гласа ми, и изпълнявайте тия думи според всичко, що съм ви заповядал; и така вие ще бъдете Мои люде, и Аз ще бъда ваш Бог,
Àwọn májẹ̀mú tí mo pàṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, nígbà tí mo mú wọn jáde láti Ejibiti, láti inú iná alágbẹ̀dẹ wá.’ Mo wí pé, ‘Ẹ gbọ́ tèmi, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ènìyàn mi, Èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
5 за да изпълня клетвата, с която се клех на бащите ви, да им дам земя, която изобилва с мляко и мед, както я изпълнявам днес. Тогава отговорих, като рекох: Амин, Господи!
Nígbà náà ni Èmi ó sì mú ìlérí tí mo búra fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ; láti fún wọn ní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin,’ ilẹ̀ tí ẹ ní lónìí.” Mo sì dáhùn wí pé, “Àmín, Olúwa.”
6 И Господ ми рече: Възгласи всички тия думи в Юдовите градове и в ерусалимските улици, като кажеш - Слушайте думите на тоя завет и изпълнявайте ги.
Olúwa wí fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda àti ní gbogbo òpópónà ìgboro Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí ẹ sì se wọn.
7 Защото изрично заявявах пред бащите ви в деня, когато ги възведох от Египетската земя, дори до днес, като ставах рано и заявявах, казвайки - Слушайте гласа Ми.
Láti ìgbà tí mo ti mú àwọn baba yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá títí di òní, mo kìlọ̀ fún wọn lọ́pọ̀ ìgbà wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi.”
8 Но те не послушаха, нито приклониха ухото си, а ходиха всеки по упоритостта на нечестивото си сърце; затова докарах върху тях всичко казано в тоя завет, който им заповядах да изпълняват, но който не изпълниха.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kọbi ara sí i dípò èyí wọ́n tẹ̀síwájú ni agídí ọkàn wọn. Mo sì mú gbogbo ègún inú májẹ̀mú tí mo ti ṣèlérí, tí mo sì ti pàṣẹ fún wọn láti tẹ̀lé, tí wọn kò tẹ̀lé wa sórí wọn.’”
9 И Господ ми рече: Заговор се намери между Юдовите мъже и ерусалимските жители.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ọ̀tẹ̀ kan wà láàrín àwọn ará Juda àti àwọn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
10 Те са се върнали в беззаконията на праотците си, които отказаха да слушат Моите думи, и са последвали други богове, за да им служат. Израилевият дом и Юдовият дом са нарушили завета, който направих с бащите им.
Wọ́n ti padà sí ìdí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn tí wọn kọ̀ láti tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n ti tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti sìn wọ́n. Ilé Israẹli àti ilé Juda ti ba májẹ̀mú tí mo dá pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn jẹ́.
11 Затова, така казва Господ: - Ето ще докарам зло върху тях, От което не ще могат да избягнат; И ще извикат към мене, - Но няма да ги послушам.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi yóò mu ibi tí wọn kò ní le è yẹ̀ wá sórí wọn, bí wọ́n tilẹ̀ ké pè mí èmi kì yóò fetí sí igbe wọn.
12 Тогава Юдовите градове и ерусалимските жители ще отидат И ще извикат към боговете, на които кадят; Но те няма никак да ги спасят Във време на бедствието им.
Àwọn ìlú Juda àti àwọn ará Jerusalẹmu yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́njú náà bá dé.
13 Защото колкото е числото на градовете ти, Толкова са и боговете ти, Юдо; И колкото е числото на ерусалимските улици, Толкова олтари издигнахте на онова срамотно нещо, - Олтари, за да кадите на Ваала.
Ìwọ Juda, bí iye àwọn ìlú rẹ, bẹ́ẹ̀ iye àwọn òrìṣà rẹ; bẹ́ẹ̀ ni iye pẹpẹ tí ẹ̀yin ti tẹ́ fún sísun tùràrí Baali ohun ìtìjú n nì ṣe pọ̀ bí iye òpópónà tí ó wà ní Jerusalẹmu.’
14 Затова ти недей се моли за тия люде, Нито възнасяй вик или молба за тях; Защото Аз няма да ги послушам, когато викат към Мене, Поради своето бедствие.
“Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé, Èmi kì yóò dẹtí sí wọn nígbà tí wọ́n bá ké pè mí ní ìgbà ìpọ́njú.
15 Какво право има любезната Ми в Моя дом, Като е блудствувала с мнозина, И е престанало да се принася от тебе светото месо? Когато струваш зло, тогава се веселиш.
“Kí ni olùfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹmpili mi, bí òun àti àwọn mìíràn ṣe ń hu oríṣìíríṣìí ìwà àrékérekè? Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀? Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ búburú rẹ̀, nígbà náà jẹ́ kí inú rẹ̀ kí ó dùn.”
16 Господ те нарече Маслина вечнозелена, красива, доброплодна; Но с шум на силно вълнение запали огън върху нея, И клоните й се строшиха.
Olúwa pè ọ́ ní igi olifi pẹ̀lú èso rẹ tí ó dára ní ojú. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líle ọ̀wọ́-iná ni yóò sun ún tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì di gígé kúrò.
17 Защото Господ на Силите, Който те е насадил, Изрече зло против тебе, Поради злото, което Израилевият дом и Юдовият дом Си избраха да извършат Като ме разгневиха с каденето си на Ваала.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Israẹli àti Juda ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí si Baali.
18 Но Господ ми откри това, та го познах; И тогава Ти ми показа делата им.
Nítorí Olúwa fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.
19 Но аз бях като питомно агне, водено на клане, И не знаех, че бяха скроили замисли против мене, казвайки: Нека свалим дървото с плода му, И нека го отсечем от земята на живите, За да се не помни вече името му.
Mo ti dàbí ọ̀dọ́-àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; n kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé: “Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀; jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè, kí a má lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”
20 Но, о, Господи на Силите, Който съдиш праведно, Който изпитваш вътрешностите и сърцето, Нека видя Твоето въздаяние върху тях! Защото на Тебе поверих делото си.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn, jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn; nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.
21 Затова, така казва Господ за анатотските мъже, Които искат да отнемат живота ти, и казват: Да не пророкуваш в името Господно, Да не би да умреш от ръцете ни,
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Anatoti tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’
22 Прочее, така казва Господ на Силите: Ето, Аз ще ги накажа; Юношите ще измрат чрез нож, Синовете им и дъщерите им ще измрат от глад,
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fì ìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
23 И няма да останат от тях; Защото ще докарам зло върху анатотските мъже В годината, когато ги накажа.
Kò ní ṣẹ́kù ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Anatoti ní ọdún ìbẹ̀wò wọn.’”

< Еремия 11 >