< Исая 9 >

1 Но на измъчената земя не ще има мрак Както в предишните времена, Когато Той унижи земята Завулон и земята Нефталим; Но в послешните времена ще я направи славна- Нея, която по пътя към езерото, оттатък Иордан, Галилея на народите.
Síbẹ̀síbẹ̀, kò ní sí ìpòrúru kankan mọ́ fún àwọn tí ó wà nínú ìbànújẹ́. Nígbà kan rí ó rẹ ilẹ̀ Sebuluni sílẹ̀ àti ilẹ̀ Naftali pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ iwájú, yóò bu ọ̀wọ̀ fún Galili ti àwọn aláìkọlà, ní ọ̀nà Òkun, ní ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ Jordani.
2 Людете, които ходеха в тъмнина, видяха голяма светлина; На ония, които седяха в земя на мрачна сянка Изгря им светлина.
Àwọn ènìyàn tí ń rìn nínú òkùnkùn ti rí ìmọ́lẹ̀ ńlá; lórí àwọn tí ń gbé nínú ilẹ̀ òjìji ikú, ní ara wọn ni ìmọ́lẹ̀ mọ́ sí.
3 Умножил си народа, Увеличил си радостта му; Радват се пред Тебе както се радват във време на жътва, Както се радват, когато делят користи.
Ìwọ ti sọ orílẹ̀-èdè di ńlá; wọ́n sì yọ̀ níwájú rẹ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ti í yọ ayọ̀ ìkórè, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ti í yọ̀ nígbà tí à ń pín ìkógun.
4 Защото Ти си строшил, както в деня на Мадиама, Тежкия им хомот, тоягата за плещите им, И бичът на угнетителя им.
Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí a ṣẹ́gun Midiani, ìwọ ti fọ́ ọ túútúú àjàgà ti ń pa wọ́n lẹ́rù, ọ̀pá tí ó dábùú èjìká wọn, ọ̀gọ aninilára wọn.
5 Защото всяка чизма на обутия ратник в шума И облеклата валяни в кръв, Ще бъдат за изгаряне и гориво за огън.
Gbogbo bàtà jagunjagun tí a ti lò lójú ogun àti gbogbo ẹ̀wù tí a yí nínú ẹ̀jẹ̀, ni yóò wà fún ìjóná, àti ohun èlò iná dídá.
6 Защото ни се роди Дете, Син ни се даде; И управлението ще бъде на рамото Му; И името Му ще бъде: Чудесен, Съветник, Бог могъщ, Отец на вечността, Княз на мира.
Nítorí a bí ọmọ kan fún wa, a fi ọmọkùnrin kan fún wa, ìjọba yóò sì wà ní èjìká rẹ̀. A ó sì máa pè é ní Ìyanu Olùdámọ̀ràn, Ọlọ́run Alágbára, Baba ayérayé, Ọmọ ọba aládé Àlàáfíà.
7 Управлението Му и мирът непрастанно ще се увеличават На Давидовия престол и на неговото царство, За да го утвърди и поддържа, Чрез правосъдие и чрез правда, от сега и до века. Ревността на Господа на Силите ще извърши това.
Ní ti gbígbòòrò Ìjọba rẹ̀ àti àlàáfíà rẹ̀ ni kì yóò ní ìpẹ̀kun. Yóò jẹ ọba lórí ìtẹ́ Dafidi àti lórí ẹ̀kún un rẹ̀ gbogbo, nípa ìfìdímúlẹ̀ àti ìgbéró rẹ̀, pẹ̀lú òtítọ́ àti òdodo láti ìgbà náà lọ àti títí láéláé. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
8 Господ изпрати слово на Якова; И то свърхлетя и върху Израиля.
Olúwa ti dojú iṣẹ́ kan kọ Jakọbu; yóò sì wá sórí Israẹli.
9 И всичките люде ще го познаят, Дори до Ефрем и жителите на Самария, Които гордо и с надменно сърце казват:
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì mọ̀ ọ́n— Efraimu àti gbogbo olùgbé Samaria— tí ó sọ pẹ̀lú ìgbéraga àti gààrù àyà pé.
10 Кирпичите паднаха, но ние ще съзидаме с дялани камъни; Черниците се изсякоха, но ще ги заменим с кедри.
Àwọn bíríkì ti wó lulẹ̀ ṣùgbọ́n a ó tún un kọ́ pẹ̀lú òkúta dídán, a ti gé àwọn igi sikamore lulẹ̀ ṣùgbọ́n igi kedari ní a ó fi dípò wọn.
11 Затова Господ ще подигне отгоре му ония, които се противиха против Расина, И ще възбуди неприятелите му,
Ṣùgbọ́n Olúwa fún àwọn ọ̀tá Resini ní agbára láti dojúkọ wọ́n ó sì ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè.
12 Сирийците отпред, и филистимците отдире, - И те ще изядат Израиля с отворени уста. При все това, гневът Му не се отвърна, Но ръката Му е още простряна.
Àwọn ará Aramu láti ìlà-oòrùn àti Filistini láti ìwọ̀-oòrùn. Wọ́n sì fi gbogbo ẹnu jẹ Israẹli run. Ní gbogbo èyí ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ nà jáde síbẹ̀.
13 Но пак людете не се връщат към Този, Който ги поразява, Нито търсят Господа на Силите.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tí ì yípadà sí ẹni náà tí ó lù wọ́n bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
14 Затова Господ ще отсече от Израиля в един ден И глава и опашка, палмов клон и тръстика.
Nítorí náà ni Olúwa yóò ṣe ké àti orí àti ìrù kúrò ní Israẹli, àti ọ̀wá ọ̀pẹ àti koríko odò ní ọjọ́ kan ṣoṣo,
15 (Старецът и почтеният мъж, той е глава; А пророкът, който поучава лъжи, той е опашка).
àwọn àgbàgbà, àti àwọn gbajúmọ̀ ní orí, àwọn wòlíì tí ń kọ́ni ní irọ́ ni ìrù.
16 Защото водителите на тия люде ги заблуждават, И водените от тях загиват.
Àwọn tí ó ń tọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣì wọ́n lọ́nà, àwọn tí a sì tọ́ ni a ń sin sí ìparun.
17 Затова Господ не ще се зарадва за юношите им, Нито ще се смили за сирачетата и вдовиците им; Понеже те всички са нечестиви и злодейци, И всички уста говорят безумие. При все това, гневът Му не се отвърна, Но ръката Му е още простряна.
Nítorí náà, Olúwa kì yóò dunnú sí àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tàbí kí ó káàánú àwọn aláìní baba àti opó, nítorí pé gbogbo wọn jẹ́ ìkà àti aláìmọ Ọlọ́run, ibi ni ó ti ẹnu wọn jáde. Síbẹ̀, fún gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò ọwọ́ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.
18 Защото беззаконието изгаря като огън, Който пояжда глоговете и тръните; Да! Той пламти в горските гъсталаци, И те се издигат като тежки облаци дим.
Nítòótọ́ ìwà búburú ń jóni bí iná, yóò jó ẹ̀wọ̀n àti ẹ̀gún run, yóò sì rán nínú pàǹtí igbó, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi gòkè lọ bí ọ̀wọ́n èéfín ti í gòkè.
19 От гнева на Господа на Силите земята изгоря И людете ще бъдат като гориво за огън; Никой не жали брата си.
Nípasẹ̀ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ilẹ̀ náà yóò di gbígbẹ àwọn ènìyàn yóò sì di ohun ìdáná, ẹnìkan kì yóò sì dá arákùnrin rẹ̀ sí.
20 Човек ще граби отдясно, но ще остане гладен; И ще яде наляво, но не ще са насити! Всеки от тях ще яде месата на своята мишца,
Ní apá ọ̀tún wọn yóò jẹrun, síbẹ̀ ebi yóò sì máa pa wọ́n, ní apá òsì, wọn yóò jẹ, ṣùgbọ́n, kò ní tẹ́ wọn lọ́rùn. Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò sì máa jẹ ẹran-ara apá rẹ̀.
21 Манасия Ефрема, и Ефрем Манасия, И то заедно ще бъдат против Юда. При все това, гневът Му не се отвърна, Но ръката Му е още простряна.
Manase yóò máa jẹ Efraimu, nígbà tí Efraimu yóò jẹ Manase wọn yóò parapọ̀ dojúkọ Juda. Síbẹ̀síbẹ̀, ìbínú un rẹ̀ kò yí kúrò Ọwọ́ọ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.

< Исая 9 >