< Исая 45 >
1 Така казва Господ на помазаника Си, На Кира, когото Аз държа за дясната ръка, За да покоря народи пред него, И да разпаша кръста на царе, За да отворя вратите пред него. Та да не затворят портите:
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
2 Аз ще ходя пред тебе И ще изравня неравните места; И ще разбия медните врати, И ще строша железните лостове;
Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
3 Ще ти дам съкровища пазени в тъмнина, И богатства скрити в скривалища, За да познаеш, че Аз съм Господ, Израилевият Бог, Който те призовавам по името ти.
Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
4 Заради Якова служителят Ми И Израиля избрания Ми Призовах те по името ти, Дадох ти почтено име, ако и да Ме не познаваш,
Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
5 Аз съм Господ, и няма друг; Няма бог освен Мене; Аз те описах, ако и да Ме не познаваш,
Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
6 За да познаят от изгрева на слънцето и от запад, Че освен Мене няма никой, Че Аз съм Господ, и няма друг.
tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
7 Аз създавам светлината и творя тъмнината; Правя мир, творя и зло! Аз Господ съм, Който правя всичко това.
Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
8 Роси, небе, от горе, И нека излеят облаците правда; Нека се отвори земята, за да се роди спасение, И за да изникне същевременно правда; Аз Господ създадох това.
“Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
9 Горко на онзи, който се препира със Създателя си! Черепка от земните черепки! Ще рече ли калта на този, който й дава образ: Що правиш? Или изделието ти да рече за тебе: Няма ръце?
“Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ ()
10 Горко на онзи, който казва на баща си: Какво раждаш? Или на жена му: Какво добиваш?
Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
11 Така казва Господ, Светият на Израиля и неговият Създател: Допитай се до Мене за бъдещето; За синовете Ми и за делото на ръцете Ми заповядайте Ми.
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
12 Аз създадох земята, и сътворих човека на нея; Аз, да! Моите ръце разпростряха небето, Аз дадох заповед на цялото му множество.
Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
13 Аз издигнах него с правда, И ще оправям всичките му пътища; Той ще съгради града Ми и ще пусне пленниците Ми, Без откуп или подаръци, казва Господ на Силите.
Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
14 Така казва Господ: Печалбата от труда на Египет и търговията на Етиопия. И на високите мъже савците, Ще минат към тебе и твои ще бъдат; Ще те дирят; в окови ще заминат; И като ти се поклонят ще ти се помолят, казвайки: Само между тебе е Бог, и няма друг, Друг бог няма.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
15 Наистина Ти си Бог, Който се криеш, Боже Израилев, Спасителю
Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
16 Те всички ще се посрамят и смутят; Те всички ще си отидат засрамени, които работят идоли.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
17 А Израил ще се спаси чрез Господа с вечно спасение; Вие няма да се посрамите нито да се смутите до вечни времена.
Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
18 Защото така казва Господ, Който сътвори небето, (Твоя Бог, Който създаде земята, направи я, и я утвърди, Който не я сътвори пустиня, но я създаде, за да се населява): Аз съм Господ, и няма друг.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
19 Не съм говорил в тайно, от място в тъмна земя; Не съм рекъл на Якововото потомство: Търсете Ме напразно. Аз Господ говоря правда, възвестявам правота.
Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
20 Съберете се та дойдете, Приближете се, всички вие избягали от народите; Нямат разум ония, които издигат дървените си идоли, И се молят на бог, който не може да спаси.
“Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
21 Изявете и приведете ги; Да нека се съветват заедно; Кой е прогласил това от древността? Кой го е изявил от отдавнашното време? Не аз ли Господ? и освен Мене няма друг бог, Освен мене няма бог праведен и спасител.
Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
22 Към Мене погледнете и спасени бъдете всички земни краища; Защото Аз съм Бог, и няма друг.
“Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
23 В Себе си Се заклех, (Праведна дума излезе из устата Ми, и няма да се повърне), Че пред Мене ще се преклони всяко коляно, Всеки език ще се закълне в Мене.
Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
24 Само в Господа, ще рече някой за Мене, Има правда и сила; При Него ще дойдат човеците, А всички, които се разгневиха на Него, ще се засрамят
Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
25 Чрез Господа ще се оправдае И с Него ще се хвали цялото Израилево потомство.
Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.