< Осия 12 >
1 Ефрем се храни с вятър, и гони източния вятър; Непрестанно умножава лъжите и насилието; Правят завет с Асирийците, И занасят дървено масло в Египет!
Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
2 Още, Господ има спор с Юда, И ще накаже Якова според постъпките му, Според делата му ще му въздаде.
Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
3 В утробата той хвана петата на брата си, и като мъж се бори с Бога;
Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
4 Да! бори се с ангел, и преодоля С плач и молба към него. Бог го намери във Ветил, и там говори с нас,
Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
5 Да! Иеова Бог на Силите, Чието паметно име е Иеова.
àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
6 За това, обърни се към твоя Бог, Пази милост и правосъдие, И винаги се надявай на твоя Бог.
Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
7 Ефрем е търговец; Неверни къпони има в ръката му; Той обича да мами.
Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
8 И Ефрем си рече: Наистина аз се обогатих, Придобих си имот; Досежно всичките ми трудове няма да се намери в мене беззаконие, Което да се счита за грях.
Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
9 А аз съм Господ твой Бог от времето, когато беше ти в Египетската земя; Пак ще те заселя в шатри Като в празнични дни.
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
10 Говорих още и чрез пророците, И явих им много видения; И чрез думите на пророците служих си с уподобления.
Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
11 Ето, в Галаад има беззаконие; Станаха съвсем суетни; В Глагал жертват юнци; И жертвениците им са многобройни като куповете тор В браздите на нивите.
Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
12 А Яков побягна в Сирийското поле; Израил е работил за жена, И за жена е пазил овци,
Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
13 Чрез пророк Господ възведе Израиля от Египет; И чрез пророк той биде опазен.
Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
14 Ефрем разгневи Бога много горчиво; За това, ще оставя върху него проляната от него кръв, И неговият Господ ще възвърне укора му върху самия него.
Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.