< Евреи 12 >
1 Следователно и ние, като сме обиколени от такъв голям облак свидетели, нека отхвърлим всяка тегота и греха, който лесно ни сплита, и с търпение нека тичаме на предлежащето пред нас поприще,
Nítorí náà bí a ti fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ tí o kún fún àwọn ẹlẹ́rìí tó báyìí yí wa ká, ẹ jẹ́ kí a pa ohun ìdíwọ́ gbogbo tì sí apá kan, àti ẹ̀ṣẹ̀ tí o rọrùn láti di mọ́ wa, kí a sì máa fi sùúrù súré ìje tí a gbé ka iwájú wa,
2 като гледаме на Исуса начинателя и усъвършителя на вярата ни, Който, заради предстоящата Нему радост, издържа кръст, като презря срама и седна отдясно на Божия престол.
kí a máa wo Jesu Olùpilẹ̀ṣẹ̀ àti aláṣepé ìgbàgbọ́ wa; ẹni nítorí ayọ̀ tí a gbé ka iwájú rẹ, tí o faradà àgbélébùú láìka ìtìjú sí, tí ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún ìtẹ́ Ọlọ́run.
3 Защото размислете за Този, Който издържа от грешните такова противоречие против Себе Си, та да ви не дотегва и да не ставате малодушни,
Máa ro ti ẹni tí ó faradà irú ìsọ̀rọ̀-òdì yìí láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ si ara rẹ̀, kí ẹ má ba á rẹ̀wẹ̀sì ni ọkàn yín, kí àárẹ̀ si mu yín.
4 Не сте се още съпротивили до кръв в борбата си против греха.
Ẹ̀yin kò sá à tí ì kọ ojú ìjà si ẹ̀ṣẹ̀ títí dé títa ẹ̀jẹ̀ yín sílẹ̀ nínú ìjàkadì yín.
5 И сте забравили увещанието, което ви съветва като синове: "Сине мой, не презирай наказанието на Господа, Нито да ослабваш, когато те изобличава Той;
Ẹ̀yin sì ti gbàgbé ọ̀rọ̀ ìyànjú tí ó n ba yin sọ̀rọ̀ bí ọmọ pé, “Ọmọ mi, ma ṣe aláìnání ìbáwí Olúwa, kí o má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì nígbà tí a bá ń ti ọwọ́ rẹ̀ ba ọ wí,
6 Защото Господ наказва този, когото люби, И бие всеки син, когото приема",
nítorí pé ẹni ti Olúwa fẹ́, òun ni i bá wí, a sì máa na olúkúlùkù ọmọ tí òun tẹ́wọ́gbà.”
7 Ако търпите наказание, Бог се обхожда с вас като със синове; защото кой е тоя син, когото баща му не наказва?
Ẹ máa ní sùúrù lábẹ́ ìbáwí, Ọlọ́run bá wa lò bí ọmọ ni; nítorí pé ọmọ wo ni ń bẹ ti baba kì í bá wí?
8 Но ако сте без наказание, на което всички са били определени да участвуват, тогава сте незаконно родени, а не синове.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ba wà láìsí ìbáwí, nínú èyí tí gbogbo ènìyàn ti jẹ alábápín, ǹjẹ́ ọmọ àlè ni yín, ẹ kì í sì ṣe ọmọ.
9 Освен това, имали сме бащи по плът, които са ни наказвали, и сме ги почитали; не щем ли повече да се покоряваме на Отца на духовете ни и да живеем?
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwa ni baba wa nípa ti ara tí o ń tọ́ wa, àwa sì ń bu ọlá fún wọn: kò ha yẹ kí a kúkú tẹríba fún Baba àwọn ẹ̀mí, kí a sì yè?
10 Защото те за малко време са ни наказвали, според както им е било угодно, а Той
Nítorí wọ́n tọ́ wa fún ọjọ́ díẹ̀ bí o bá ti dára lójú wọn; ṣùgbọ́n Òun tọ́ wa fún èrè wa, kí àwa lè ṣe alábápín ìwà mímọ́ rẹ̀.
11 Никое наказание не се вижда на времето да е за радост, а е тежко; но после принася правда като мирен плод за тия, които са се обучавали чрез него.
Gbogbo ìbáwí kò dàbí ohun ayọ̀ nísinsin yìí bí kò ṣe ìbànújẹ́; ṣùgbọ́n níkẹyìn yóò so èso àlàáfíà fún àwọn tí a tọ́ nípa rẹ̀, àní èso òdodo.
12 Затова "укрепете немощните ръце и отслабналите колена",
Nítorí náà, ẹ na ọwọ́ tí ó rọ, àti eékún àìlera,
13 и направете за нозете си прави пътища, за да не се изкълчи куцото, но напротив, да изцелее.
“Kí ẹ sì ṣe ipa ọ̀nà tí ó tọ́ fún ẹsẹ̀ yin,” kí èyí tí ó rọ má bá a kúrò lórí ike ṣùgbọ́n kí a kúkú wò ó sàn.
14 Търсете мир с всички и онова освещение, без което никой няма да види Господа.
Ẹ máa lépa àlàáfíà pẹ̀lú ènìyàn gbogbo, àti ìwà mímọ́, láìsí èyí yìí kò sí ẹni tí yóò rí Olúwa.
15 И внимавайте, да не би някой да не достигне до Божията благодат; да не би да поникне някой горчив корен, та да ви смущава, и мнозинството да се зарази от него;
Ẹ máa kíyèsára kí ẹnikẹ́ni má ṣe kùnà Oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run; kí gbòǹgbò ìkorò kan máa ba hù sókè kí ó sì yọ yín lẹ́nu, ọ̀pọ̀lọpọ̀ a sì ti ipa rẹ̀ di àìmọ́.
16 да не би някой да е блудник или нечестив, както Исав, който за едно ястие продаде първородството си;
Kí o má bá à si àgbèrè kan tàbí aláìwà-bí-Ọlọ́run bi Esau, ẹni tí o tìtorí òkèlè oúnjẹ kan ta ogún ìbí rẹ̀.
17 понеже знаете, че даже когато искаше по-после да наследи благословението, той бе отхвърлен, при все че го потърси със сълзи, защото не намери място за промяна на ума у баща си.
Nítorí ẹ̀yin mọ pé lẹ́yìn náà, nígbà tí ó fẹ́ láti jogún ìbùkún náà, a kọ̀ ọ́, nítorí kò ri ààyè ìrònúpìwàdà, bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi omijé wa a gidigidi.
18 Защото вие не сте пристъпили до планина осезаема и пламнала в огън, нито до тъмнина и буря,
Nítorí ẹ̀yin kò wá òkè tí a lè fi ọwọ́ kàn, àti ti iná ti ń jó, àti ti ìṣúdudu àti òkùnkùn, àti ìjì.
19 нито до тръбен звук и глас на думи; такъв, щото ония, които го чуха, се примолиха да им се не говори вече дума;
Àti ìró ìpè, àti ohùn ọ̀rọ̀, èyí tí àwọn tí o gbọ́ bẹ̀bẹ̀ pé, kí a má ṣe sọ ọ̀rọ̀ sí i fún wọn mọ́,
20 (защото не можаха да изтърпят онова, що им се заповядваше: "Даже животно, ако се допре до планината, ще се убие с камъни";
nítorí pé wọn kò lè gba ohun tí ó paláṣẹ, “Bí o tilẹ̀ jẹ ẹranko ni ó fi ara kan òkè náà, a ó sọ ọ́ ni òkúta.”
21 и толкоз страшна беше гледката, щото Моисей рече: "Много съм уплашен и разтреперан");
Ìran náà sì lẹ́rù to bẹ́ẹ̀ tí Mose wí pé, “Ẹ̀rù ba mi gidigidi mo sì wárìrì.”
22 но пристъпихме до хълма Сион, до града на живия Бог, небесния Ерусалим, и при десетки хиляди тържествуващи ангели,
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wá sí òkè Sioni, àti sí ìlú Ọlọ́run alààyè, ti Jerusalẹmu ti ọ̀run, àti si ẹgbẹ́ àwọn angẹli àìníye,
23 при събора на първородните, които са записани на небесата, при Бога, Съдията на всички, при духовете на усъвършенствуваните праведници,
si àjọ ńlá tí ìjọ àkọ́bí tí a ti kọ orúkọ wọn ni ọ̀run, àti sọ́dọ̀ Ọlọ́run onídàájọ́ gbogbo ènìyàn, àti sọ́dọ̀ àwọn ẹ̀mí olóòtítọ́ ènìyàn tí a ṣe ni àṣepé,
24 при Исуса, Посредника на новия завет, и при поръсената кръв, която говори по-добри неща от Авеловата.
àti sọ́dọ̀ Jesu alárinà májẹ̀mú tuntun, àti si ibi ẹ̀jẹ̀ ìbùwọ́n ni, ti ń sọ̀rọ̀ ohun tí ó dára ju ti Abeli lọ.
25 Внимавайте, да не презрете този, Който говори; защото, ако ония не избегнаха наказанието, като презряха този, който ги предупреждаваше на земята, то колко повече не щем избегна ние, ако се отървем от Този, Който предупреждава от небесата!
Kíyèsi i, kí ẹ má ṣe kọ̀ ẹni tí ń kìlọ̀. Nítorí bí àwọn wọ̀nyí kò bá bọ́ nígbà tí wọn kọ̀ ẹni ti ń kìlọ̀ ni ayé, mélòó mélòó ni àwa kì yóò bọ́, bí àwa ba pẹ̀yìndà sí ẹni tí ń kìlọ̀ láti ọ̀run wá,
26 Чийто глас разтърси тогава земята; а сега Той се обеща, казвайки: "Още веднъж Аз ще разтърся не само земята, но и небето".
ohùn ẹni tí ó mi ayé nígbà náà, ṣùgbọ́n nísinsin yìí o ti ṣe ìlérí, wí pé, “Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi ki yóò mi kìkì ayé nìkan, ṣùgbọ́n ọ̀run pẹ̀lú.”
27 А това "още еднаж" означава премахването на ония неща, които се клатят, като направени неща, за да останат тия, които не се клатят.
Àti ọ̀rọ̀ yìí, “Lẹ́ẹ̀kan sí i,” ìtumọ̀ rẹ̀ ni, mímú àwọn ohun wọ̀nyí ti a ń mì kúrò, bí ohun tí a ti dá, kí àwọn ohun tí a kò lè mì lè wà síbẹ̀.
28 Затова, понеже приемаме царство, което не се клати, нека бъдем благодарни, и така да служим благоугодно Богу с благоговение и страхопочитание;
Nítorí náà bí àwa tí ń gbà ilẹ̀ ọba ti a kò lè mì, ẹ jẹ́ kí a dá ọpẹ́ nípa èyí ti a fi lè máa sin Ọlọ́run ni ìtẹ́wọ́gbà pẹ̀lú ọ̀wọ̀ àti ìbẹ̀rù rẹ̀.
29 защото нашият Бог е огън, който пояжда.
Nítorí pé, “Ọlọ́run wa, iná ti ń jó ni run ni.”