< Битие 44 >
1 После заповяда на домакина си, казвайки: Напълни чувалите на човеците с храна, колкото могат да поберат, тури парите на всекиго в чувала му
Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
2 и тури чашата ми, сребърната чаша, отгоре в чувала на най-младия, с парите за житото му. И той стори според това, което рече Иосиф.
Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
3 На утринта, щом съмна, изпратиха човеците и ослите им.
Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
4 А когато бяха излезли из града и не бяха се отдалечили много, Иосиф рече на домакина си: Стани, тичай след човеците и, като ги стигнеш, кажи им: Защо върнахте зло за добро?
Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
5 Не е ли тая чашата с която пие господарят ми, и с която даже гадае? Зле постъпихте като сторихте това.
Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
6 И човекът, като ги настигна, каза им тия думи.
Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
7 А те му рекоха: Защо говори господарят ни такива думи? Не дай, Боже, слугите ти да сторят такова нещо.
Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
8 Ето, ние ти върнахме от Ханаанската земя, парите които намерихме отгоре в чувалите си; и как бихме откраднали сребро или злато из дома на господаря ти?
A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
9 Този от слугите ти, у когото се намери, нека умре, тоже и ние нека бъдем роби на господаря си.
Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
10 А той рече: Нека бъде според както казахте: У когото се намери, той ще ми бъде роб, а вие не ще бъдете виновни.
Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
11 Тогава те бързо снеха чувалите си на земята, и всеки отвори чувала си.
Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
12 И той претърси, като почна от най-стария и свърши с най-младия; и чашата се намери във Вениаминовия чувал.
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
13 Тогава раздраха дрехите си, натовариха всеки осела си, и се върнаха в града.
Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
14 И дойдоха Юда и братята му в дома на Иосифа, гдето той още се намираше, и паднаха пред него на земята.
Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
15 И рече им Иосиф: Какво е това що сторихте? Не знаете ли, че човек, като мене, може да гадае безпогрешно?
Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
16 Тогава Юда каза: Що да речем на господаря си? що да говорим? или как да се оправдаем? Бог откри неправдата на слугите ти; ето, роби сме на господаря си, и ние и оня у когото се намери чашата.
Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
17 Но Иосиф рече: Не дай, Боже, да сторя това: Оня, у когото се намери чашата, той ще ми бъде роб; а вие си идете с мир при баща си.
Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
18 Тогава Юда се приближи до него и рече: Моля ти се, господарю мой, позволи на слугата си да каже една дума на господаря си, като слушаш ти; и да не пламне гневът ти против слугата ти, защото ти си като Фараон.
Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
19 Господарят ми попита слугите си, казвайки: Имате ли баща или брат?
Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
20 И рекохме на господаря ми: Имаме стар баща и малко дете на старостта му, и неговият брат умря, тъй че само той остана от майка си, и баща му го обича.
Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
21 И ти рече на слугите си: Доведете ми го, за да го видя с очите си.
“Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
22 И ние казахме на господаря ми: Детето не може да остави баща си, защото, ако остави баща си, той ще умре.
A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
23 А ти рече на слугите си: Ако не слезе с вас най-малкият ви брат, няма вече да видите лицето ми.
Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
24 И като отидохме при слугата ти, баща ни, разказахме му това, което беше казал моят господар.
Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
25 А когато баща ни рече: Идете пак, купете ни малко храна,
“Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
26 ние казахме: Не можем да слезем. Ако най-младият ни брат е с нас, тогава ще слезем, защото не можем да видим лицето на човека, ако най-младият ни брат не е с нас.
Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
27 И слугата ти, баща ни, ни каза: Вие знаете, че жена ми ми роди два сина:
“Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
28 Единият излезе от мене и си рекох: Навярно звяр го е разкъсал; и до сега не съм го видял;
Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
29 и ако ми отнемете и тоя, и му се случи нещастие, ще свалите бялата ми коса със скръб в гроба. (Sheol )
Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol )
30 И сега, когато отидем при слугата ти, баща ни, и детето не е с нас, то, понеже животът му е свързан с неговия живот,
“Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
31 като види, че няма детето, ще умре; и слугите ти ще свалят бялата коса на слугата ти, баща ни, със скръб в гроба. (Sheol )
Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol )
32 Защото слугата ти стана поръчител пред баща си за детето, като казах: Ако не ти го доведа, тогава ще бъда за винаги виновен пред баща си.
Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
33 Сега, прочее, моля ти се, вместо детето нека остане слугата ти роб на господаря ми, а детето нека отиде с братята си.
“Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
34 Защото, как да отида аз при баща си, ако детето не е с мене? Да не би да видя злото, което ще сполети баща ми.
Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”