< Битие 24 >
1 А когато Авраам беше стар, напреднал във възраст, и Господ беше благословил Авраама във всичко,
Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà,
2 рече Авраам на най-стария слуга в дома си, който беше настоятел на всичкия му имот: Тури, моля, ръката си под бедрото ми;
Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi.
3 и ще те закълна в Господа, Бог на небето и Бог на земята, че няма да вземеш жена за сина ми от дъщерите на ханаанците, между които живея;
Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé.
4 но да отидеш в отечеството ми, при рода ми, и от там да вземеш жена за сина ми Исаака.
Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”
5 А слугата му рече: Може да не иска жената да дойде след мене в тая земя; трябва ли да заведа сина ти в оная земя, отгдето си излязъл?
Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
6 Но Авраам му каза: Пази се да не върнеш сина ми там.
Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
7 Господ, небесният Бог, Който ме изведе из бащиния ми дом и от родната ми земя, и Който ми говори, и Който ми се закле, казвайки: На твоето потомство ще дам тая земя; Той ще изпрати ангела си пред тебе и ще вземеш жена за сина ми оттам.
“Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
8 Но, ако жената не иска да дойде след тебе, тогава ти ще бъдеш свободен от това мое заклеване; само да не върнеш сина ми там.
Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
9 Тогава слугата тури ръката си под бедрото на господаря си Авраама и му се закле за това нещо.
Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
10 И тъй, слугата взе десет от камилите на господаря си и тръгна, като носеше в ръцете си от всички богатства на господаря си; стана и отиде в Месопотамия, в Нахоровия град.
Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori,
11 И надвечер, когато жените излизат да си наливат вода, той накара камилите да коленичат вън от града при водния кладенец.
ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.
12 Тогава каза: Господи, Боже на господаря ми Авраама, дай ми, моля, добър успех днес и покажи благост към господаря ми Авраама.
Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi.
13 Ето, аз стоя при извора на водата, и дъщерите на града излизат да си наливат вода.
Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.
14 Нека момата, на която река: Я наведи водоноса си да пия; и тя рече: Пий, и ще напоя и камилите ти; -тя нека е оная, която си отредил за слугата си Исаака; от това ще позная, че си показал милост към господаря ми.
Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘Mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”
15 Докато той още говореше, ето Ревека излизаше с водоноса си на рамото си; тя бе се родила на Ватуила, син на Мелха, жената на Авраамовия брат Нахор.
Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
16 Момата беше твърде красива на глед, девица, която никой мъж не беше познал; тя, като слезе на извора, напълни водоноса си и се изкачи.
Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.
17 А слугата се завтече да я посрещне и рече: Я дай ми да пия малко вода от водоноса ти.
Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”
18 А тя рече: Пий, господарю; и бърже сне водоноса си на ръката си, и му даде да пие.
Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.
19 И като му даде доволно да пие, рече: И за камилите ти ще налея догде се напоят.
Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.”
20 И като изля бърже водоноса си в поилото, завтече се на кладенеца да налее още и наля за всичките му камили.
Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
21 А човекът я наблюдаваше внимателно и мълчеше, за да узнае дали Господ бе направил пътуването му успешно или не.
Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Olúwa ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
22 Като напоиха камилите, човекът взе една златна обица, тежка половин сикъл, и две гривни за ръцете й, тежки десет сикли злато, и рече:
Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá.
23 Чия си дъщеря? - я ми кажи. Има ли в къщата на баща ти място за нас да пренощуваме?
Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
24 А тя му рече: Аз съм дъщеря на Ватуила, син на Мелха, когото тя е родила на Нахора.
Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi.”
25 Рече му още: Има у нас и слама, и храна доволно, и място за пренощуване.
Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”
26 Тогава човекът се наведе, та се поклони на Господа.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa,
27 И рече: Благословен да бъде Господ, Бог на господаря ми Авраама, Който не лиши господаря ми от милостта си и верността си, като отправи Господ пътя ми в дома на братята на господаря ми.
wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
28 А момата се завтече, та разказа тия неща на майка си.
Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.
29 И Ревека имаше брат на име Лаван; и Лаван се завтече вън при човека на извора.
Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.
30 Защото, като видя обицата и гривните на ръцете на сестра си и чу думите на сестра си Ревека, която казваше: Така ми говори човекът; той отиде при човека; и, ето, той стоеше при камилите до извора.
Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi.
31 И рече му: Влез, ти, благословен от Господа; защо стоиш вън? Защото приготвих къщата и място за камилите.
Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”
32 И тъй, човекът влезе вкъщи; а Лаван разтовари камилите му и даде слама и храна за камилите, и вода за умиване неговите нозе и нозете на хората, които бяха с него.
Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn.
33 И сложиха пред него да яде; но той рече: Не искам да ям, догде не кажа думата си. А Лаван рече: Казвай.
Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.” Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”
34 Тогава той каза: Аз съм слуга на Авраама.
Nítorí náà, ó wí pé, “Ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi.
35 Господ е благословил господаря ми премного, та стана велик; дал му е овци и говеда, сребро и злато, слуги и слугини, камили и осли.
Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
36 И Сара, жената на господаря ми, роди син на господаря ми, когато беше вече остаряла; и на него той даде всичко, що има.
Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní.
37 И господарят ми, като ме закле, рече: Да не вземеш за сина ми жена от дъщерите на ханаанците, в чиято земя живея.
Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé,
38 Но да отидеш в бащиния ми дом и в рода ми, и от там да вземеш жена за сина ми.
ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’
39 И рекох на господаря ми: Може да не иска жената да дойде след мене.
“Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ń kọ́?’
40 Но той ми каза: Господ, пред Когото ходя, ще изпрати ангела си с тебе и ще направи пътуването ти успешно; и ще вземеш жена за сина ми от рода ми и от бащиния ми дом.
“Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi.
41 Само тогава ще бъдеш свободен от заклеването ми, когато отидеш при рода ми; и, ако не ти я дадат, тогава ще бъдеш свободен от заклеването ми.
Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’
42 И като пристигнах днес на извора, рекох: Господи, Боже на господаря ми Авраама, моля, ако правиш пътуването ми, по което ходя, успешно,
“Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí.
43 ето, аз стоя при водния извор; момата, която излезе да налее вода, и аз й река: Я ми дай да пия малко вода от водоноса ти,
Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,”
44 и тя ми рече: И ти пий, и ще налея и за камилите ти, - тя нека е жената, която Господ е отредил за сина на господаря ми.
tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’
45 Докато още говорех в сърцето си, ето, Ревека излезе с водоноса на рамото си. И като слезе на извора и наля, рекох й: Я ми дай да пия.
“Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’
46 И тя бързо сне водоноса от рамото си и рече: Пий и ще напоя и камилите ти. И тъй, аз пих, а тя напои и камилите.
“Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.
47 Тогава я попитах, казвайки: Чия си дъщеря? А тя рече: Аз съм дъщеря на Ватуила, Нахоровия син, когото му роди Мелха. Тогава турих обицата на лицето й и гривните на ръцете й.
“Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’ “Ó sì wí fún mi pé, ‘Ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’ “Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́.
48 И наведох се, та се поклоних на Господа и благослових Господа, Бога на господаря ми Авраама, Който ме доведе по правия път, за да взема за сина на господаря ми братовата му дъщеря.
Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀.
49 Сега, прочее, ако искате да постъпите любезно и верно спрямо господаря ми, кажете ми; и, ако не, пак ми кажете, за да се обърна надясно или наляво.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”
50 А Лаван и Ватуил в отговор рекоха: От Господа стана това; ние не можем да ти речем ни зло, ни добро.
Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.
51 Ето Ревека пред тебе; вземи я и си иди; нека бъде жена на сина на господаря ти, както Господ е говорил.
Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”
52 Като чу думите им, Авраамовият слуга се поклони на Господа до земята.
Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa.
53 И слугата извади сребърни и златни накити и облекла, та ги даде на Ревека; така също даде скъпи дарове на брат й и на майка й.
Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú.
54 Подир това, той и хората, които бяха с него, ядоха, пиха и пренощуваха; и като станаха сутринта, слугата рече: Изпратете ме при господаря ми.
Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà. Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”
55 А брат й и майка й казаха: Нека поседи момата с нас известно време, най-малко десетина дни, после нека иде.
Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”
56 Но той им каза: Не ме спирайте, тъй като Господ е направил пътуването ми успешно; изпратете ме да ида при господаря си.
Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”
57 А те рекоха: Да повикаме момата и да я попитаме, какво ще каже.
Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í.”
58 И тъй, повикаха Ревека и рекоха й: Отиваш ли с тоя човек? А тя рече: Отивам.
Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”
59 И така, изпратиха сестра си Ревека с бавачката й и Авраамовия слуга с хората му.
Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ.
60 И благословиха Ревека, като й рекоха: Сестро наша, да се родят от тебе хиляди по десет хиляди и потомството ти да завладее портата на ненавистниците си.
Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé, “Ìwọ ni arábìnrin wa ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”
61 И Ревека и слугите й станаха, възседнаха камилите и отидоха след човека. Така, слугата взе Ревека и си замина.
Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
62 А Исаак идеше от Вир-лахайрои, защото живееше в южната земя.
Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé.
63 И като излезе Исаак, за да размишлява на полето привечер, повдигна очи и видя; и, ето камили се приближаваха.
Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá.
64 Също и Ревека повдигна очи и видя Исаака; и слезна от камилата.
Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ,
65 Защото беше рекла на слугата: Кой е оня човек, който иде през полето насреща ни? И слугата беше казал: Това е господарят ми. Затова тя взе покривалото си и се покри.
ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?” Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
66 И слугата разказа на Исаака всичко, което бе извършил.
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
67 Тогава Исаак въведе Ревека в шатъра на майка си Сара и я взе, и тя му стана жена, и той я обикна. Така Исаак се утеши след смъртта на майка си.
Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.