< Ездра 8 >
1 А ето началниците на бащините им домове, ето и родословието, на ония, които възлязоха с мене от Вавилон в царуването на цар Артаксеркса.
Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:
2 От Финеесовите потомци, Гирсон; от Итамаровите потомци, Даниил; от Давидовите потомци, Хатус.
nínú àwọn ọmọ Finehasi: Gerṣomu; nínú àwọn ọmọ Itamari: Daniẹli; nínú àwọn ọmọ Dafidi: Hattusi,
3 От потомците на Сехания, из Фаросовите потомци, Захария, и с него се преброиха по родословието на мъжките сто и петдесет души.
nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah; nínú àwọn ọmọ Paroṣi: Sekariah, àti pé àádọ́jọ ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;
4 От Фаат-моавовите потомци, Зараиевият син Елиоинай, и с него двеста души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu: Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
5 От Сеханиевите потомци, Яазииловият син, и с него триста души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Sattu: Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
6 От Адиновите потомци, Ионатановият син Евед, и с него петдесет души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Adini: Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
7 От Еламовите потомци, Готолиевият син Исаия, и с него седемдесет души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Elamu: Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
8 От Сефатиевите потомци, Михаиловият син Зевадия, и с него осемдесет души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Ṣefatia: Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
9 От Иоавовите потомци, Ехииловият син Авдия, и с него двеста и осемдесет души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Joabu: Obadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó lé nígba ó dín méjì ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
10 От Селомитовите потомци, Иосифиевият син, и с него сто и шестдесет души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Bani: Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
11 От Винаевите потомци, Захария Виваевият син, и с него двадесет и осем души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Bebai: Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;
12 От Азгадовите потомци, Иоанан Акатановият син, и с него сто и десет души от мъжки пол
nínú àwọn ọmọ Asgadi: Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
13 От послешните, Адоникамовите потомци, следните, чиито имена са: Елифалет, Еиил и Семаия, и с тях седемдесет души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Adonikami: àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú wọn;
14 А от Вагуевите потомци, Утай и Завуд, и с тях седемдесет души от мъжки пол.
nínú àwọn ọmọ Bigfai: Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú wọn.
15 Тия събрах при реката, която тече към Аава, и там се разположихме в стан три дни; а като прегледах людете и свещениците, не намерих там ни един от потомците на Левия.
Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀.
16 Тогава пратих за по-видните човеци Елиезера, Ариила, Семаия, Елнатана, Ярива, Елнатана, Натана, Захария и Месулама, и за благоразумните мъже Иоярива и Елнатана,
Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,
17 и дадоха им поръчка до началника на мястото Касифия, Идо; и казах им какво да казват на Идо и на братята му нетинимите на мястото Касифия, да ни изпратят служители за дома на нашия Бог.
mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa.
18 И понеже добрата ръка на нашия Бог беше над нас, те ни доведоха един разумен човек от потомците на Маалия, син на Левия, син на Израиля; също и Саравия със синовете му и братята му, осемнадесет души;
Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjìdínlógún.
19 и Асавия, и с него Исаия от Марариевите потомци, братята му и синовете им, двадесет души;
Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin.
20 и от нетинимите, които Давид и първенците бяха определили за прислуга на левитите, двеста и двадесет нетиними. Всички тия бяха споменати по име.
Wọ́n sì tún mú ogún lé nígba àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
21 Тогава прогласих пост там при реката Аава, за да се смирим пред нашия Бог, и да просим от Него добър път за нас, за чадата ни, и за всичкия ни имот.
Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa.
22 Защото ме беше срам да поискам от царя войници и конници, за да ни помогнат против неприятели по пътя; понеже бяхме говорили на царя казвайки: Ръката на нашия Бог е за добро над всички, които Го търсят, а силата Му и гневът Му са против всички, които Го оставят.
Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
23 Постихме, прочее, и молихме се на нашия Бог за това, и Той ни послуша.
Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.
24 Тогава отделиха дванадесет от главните свещеници - Саравия, Асавия, и с тях десет от братята им
Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,
25 и претеглих им среброто, златото и вещите, които царят, съветниците му и първенците му, и целият Израил, който се намираше там, бяха дали в принос за дома на нашия Бог;
mo sì fi òsùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.
26 претеглих, прочее, в ръката им шестстотин и петдесет таланти сребро, сто таланта сребърни вещи, сто таланта злато,
Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀ta lé láàádọ́ta tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà,
27 двадесет златни паници, хиляда драхми на тегло, и два съда от добра лъскава мед, скъпоценни като злато.
ogún ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.
28 И рекох им: Вие сте свети Господу, и вещите са свети; защото среброто и златото са доброволен принос на Господа Бога на бащите ви;
Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.
29 внимавайте, прочее, и пазете ги докле ги претеглите пред по-първите от свещениците и левитите и началниците на Израилевите бащини домове в Ерусалим, в стаите на Господния дом.
Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òsùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.”
30 И тъй, свещениците и левитите приеха среброто, златото и вещите в размер на това тегло, за да ги донесат в Ерусалим в дома на нашия Бог.
Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.
31 Тогава на дванадесетия ден от първия месец станахме от реката Аава, за да отидем; и ръката на нашия Бог бе над нас за добро, та ни избави от неприятелска ръка и от причакващи по пътя.
Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa.
32 И като стигнахме в Ерусалим, седяхме там три дни.
Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.
33 А на четвъртия ден, в дома на нашия Бог, среброто, златото и вещите се претеглиха в ръката на Меримота, син на свещеник Урия, с когото бе Елеазар Финеесовият син, и с тях левитите Иозавад, Исусовият син и Ноадия, Венуевият син,
Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
34 всичко се предаде под брой и по тегло; и цялото тегло се записа в същото време.
Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.
35 Завърналите се от плен, които бяха дошли от заточение, принесоха всеизгаряния на Израилевия Бог, дванадесет юнци за целия Израил, деветдесет и шест овена, седемдесет и седем агнета, и дванадесет козела в принос за грях, всички тия във всеизгаряния на Господа.
Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tàdínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa.
36 И предадоха царските поръчки на царските сатрапи и на областните управители отсам реката; и те помагаха на людете и на Божия дом.
Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.