< Ездра 7 >

1 След тия събития, в царуването на персийския цар Артаксеркс, дойде Ездра син на Сараия, син на Азария, син на Хелкия,
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
2 син на Селума, син на Садока син на Ахитова,
ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
3 син на Амария, син на Азария син на Мараиота,
ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
4 син на Зария, син на Озия, син на Вукия,
ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
5 син на Ависуя, син на Финееса, син на Елеазара, син на първосвещеника Аарон.
ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
6 Тоя Ездра възлезе от Вавилон; и бе книжник вещ в Моисеевия закон, който Господ Израилевият Бог бе дал; и царят му даде всичко що поискаше, понеже ръката на Господа неговия Бог беше над него за добро.
Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
7 Също и някои от израилтяните и от свещениците, и певците, вратарите и нетинимите възлязоха в Ерусалим в седмата година на цар Артаксеркса.
Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
8 Ездра стигна в Ерусалим в петия месец от седмата година на царя.
Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
9 Защото на първия ден, от първия месец, той тръгна от Вавилон, и на първия ден от петия месец, стигна в Ерусалим, понеже добрата ръка на неговия Бог беше с него.
Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
10 Защото Ездра бе утвърдил сърцето си да изучава Господния закон и да го изпълнява, и да учи в Израиля повеления и съдби.
Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
11 А ето препис от писмото, което цар Артаксеркс даде на свещеник Ездра, книжника, книжника вещ в думите на Господните заповеди и в повеленията Му към Израиля:
Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
12 Артаксеркс, цар на царете, към свещеник Ездра, книжника вещ в закона на небесния Бог, съвършен мир, и прочее.
Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
13 Издавам указ щото всички, които са от Израилевите люде, и от свещениците и левитите, в царството ми, които биха пожелали доброволно да идат в Ерусалим, да отидат с тебе.
Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
14 Тъй като си изпратен от царя и от седмината му съветника да изпиташ за Юда и Ерусалим според закона на твоя Бог, който е в ръката ти,
Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
15 и да занесеш среброто и златото, което царят и съветниците му доброволно принасят на Израилевия Бог, Чието обиталище е в Ерусалим,
Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
16 както и всичкото сребро и злато, което ти би събрал от цялата Вавилонска област, заедно с доброволните приноси на людете и на свещениците, които биха принасяли доброволно за дома на своя Бог в Ерусалим,
pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
17 затова, купи веднага с тия пари юнци, овни, агнета, с хлебните им приноси и възлиянията им, и принеси ги върху олтара на дома на вашия Бог, Който е в Ерусалим.
Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
18 И каквото се види угодно на тебе и на братята ти да сторите с останалото сребро и злато, сторете според волята на вашия Бог.
Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
19 И съдовете, които ти са дадени за службата на дома на твоя Бог, предай ги пред ерусалимския Бог.
Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
20 И каквото повече би потрябвало за дома на твоя Бог, което стане нужда да изразходваш, изразходвай го от царската съкровищница.
Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
21 И аз, аз цар Артаксеркс, издавам указ до всичките хазнатари, които са отвъд реката, щото всичко, което ли поискал от вас свещеник Ездра, книжникът вещ в закона на небесния Бог, да се дава веднага,
Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
22 до сто таланта сребро, до сто кара жито, до сто вати вино, до сто вати дървено масло, и неопределено количество сол.
tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
23 Каквото и да е заповядано от небесния Бог, нека се направи за дома на небесния Бог, да не би да дойде гняв върху царството на царя и на синовете му.
Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
24 При това ви известяваме относно свещениците, левитите, певците, вратарите, нетинимите и слугите на тоя Божий дом, че на никого от тях не ще бъде законно да се наложи данък, мито, или пътна повинност.
Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
25 И ти, Ездра, според мъдростта, която имаш от твоя Бог, постави управници и съдии, които да съдят всичките люде намиращи се отвъд реката, и те всички да са такива, които знаят законите на твоя Бог; и поучавайте всеки, който не ги знае.
Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
26 И против всеки, който не пази законите на твоя Бог и царския закон, нека се изпълнява незабавно против него присъдата, било за смърт, за заточение, за конфискуване на имот, или за затвор.
Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
27 Благословен да бъда Господ, Бог на нашите бащи, Който е турил такава мисъл в сърцето на царя, да прослави дома на Господа, Който е в Ерусалим,
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
28 и е направил да намери милост пред царя и съветниците му, и пред всичките силни първенци на царя! Така, понеже ръката на Господа моя Бог беше над мене за добро, аз се ободрих, и събрах от Израиля някои по-видни човеци, за да възлязат заедно с мене.
Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.

< Ездра 7 >